Buhari,N895 extra budget: Buhari ní kí ilé aṣòfin àgbà buwọ́lu N895b gẹ́gẹ́ bíi àfikún owó ètò ìṣúná ọdún 2021

Oríṣun àwòrán, others
Buhari ń bèrè N895b àfikún owó ètò ìṣúná ọdún 2021 láti ra abẹ́rẹ́ Covid-19 àti ohun ìjà ogun
Aarẹ Muhammadu Buhari ti ke si ile igbimọ aṣofin agba lati buwọlu wo ti iye rẹ le ni biliọnu mẹjọ naira gẹgẹ bii afikun oeo eto iṣuna ọdun 2021.
Aarẹ ile naa, Ahmed lawan lo kede bẹẹ lasiko to n ka iwe ti Buhari fi ṣọwọ si ile ọhun lẹyin ti igbimọ aṣejọba Buhari ti kọkọ buwọlu owo ọhun ṣaaju.
Lara owo ọhun ni wọn sọ pe awọn yoo lo lati ra awọn ohun ija fun ileeṣẹ ọmọ ogun lọna ati gbogun awọn ọmọ ẹgbesumọmi atawọn janduku.
- Ṣé lóòtọ́ ni olè kan wọlè fipá bá ìyá 80 lòpọ̀ nípìnlẹ̀ Ondo?
- Alága ìjọba ìbílẹ̀ Eti-Osa, Eko tí jádé láyé lẹ́yìn tó ṣe àìsàn
- Ẹranko àìmọ́ kan wọ Nàìjíríà, ó pa ènìyàn mẹ́rin ní Benue- ilé iṣẹ́ ọmọogun ni ìròyìn òfegè ni
- Pipa ní wọ́n gbọ́dọ̀ pa àwọn agbébọn tí wọ́n ń jí àwọn ènìyàn gbé, ẹ da ọ̀rọ̀ Sheik Gumi nù -Aisha Yesufu
- Ẹ̀bùn owó, oúnjẹ, aṣọ àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ ní ìkókó mú wọlè fún ẹbí Kemisola Ogunniyi ní Ondo
Ijọba apapọ yoo tun lo lara owo naa lati ra abẹrẹ ajẹsara Covid-19 atawọn irinṣẹ miran ni ẹka eto ilera Naijiria.
Lẹta ọhun ka pe "Inu mi dun lati kọwe si yin pe ki ẹ buwọlu afikun owo eto iṣuna ti ọdun 2021."
"Iye owo ti a n bere fun ni N895,842,465,917.00."
Yatọ si abẹrẹ Covid-19 ati ohun ija fun ileeṣẹ ọmọ ogun ti ijọba apapọ fẹ ra, wọn ni awọn yoo tun lo lara owo naa lati ṣe itọju awọn eeyan bii ẹgbẹrun lọna aaḍota to ni arun kogboogun HIV/AIDS labẹ eto NCAPS.
Gẹgẹ bi iwe naa ṣe sọ, ileeṣẹ ọmọ ogun nilo awọn ohun ija igbalode lati koju awọn janduku, bakan naa ni ijọba fẹ ṣeto awọn afẹfẹ eemi gaasi kakiri Naijiria.
Aarẹ Buhari sọ pe yatọ si owo yii, awọn inawo kan ṣi wa ti ijọba fẹ ṣe, ṣugbọn awọn yoo ko gbogbo rẹ sinu eto iṣuna ọdun to n bọ eyii ti awọn yoo gbe wa siwaju ile naa titi oṣu Kẹsan an ọdun yii.
Lẹyin naa lo bere fun atilẹyin awọn ọmọ ile aṣofin naa lati tete buwọlu afikun eto iṣuna ọhun ki iṣẹ le bẹrẹ ni kankan.
Bayii, ijoko ile Igbimọ Asofin ti waye lati ka ibeere Buhari lẹẹkeji ni ana nile igbimọ Asofin ni Abuja.
Ohun to ku naa ni ki awọn ọmọ ile igbimọ Asofin ka a lẹẹkẹta ki wọn si fẹnuko lori boya wọn fi ọwọ sii tabi bẹẹkọ.
- 'Òògùn ìtọ́jú egbò ni Musa pe àgbo tó fún mi, àmọ́ èèyàn mẹ́wàá ti kú lẹ́yìn tí wọ́n lò ó'
- Àwọn lọ́balọ́ba nílẹ̀ Yoruba dalẹ̀ wa lórí àwọn ọmọ OPC mẹ́ta tí wọ́n tímólé láìṣẹ̀ lórí ọ̀rọ̀ Iskilu Wakili - Ẹgbẹ́ OPC
- Ilé ẹjọ́ ECOWAS pàṣẹ fún Naijiria láti gbẹ́sẹ̀ kúrò lórí òfin tó fi de Twitter
- Ta ló gbé ìròyìn ikú ẹlẹ́jẹ̀ nípa Wòlìí SK Abiara, kí ní wọ́n sì ṣe fún un?
- Ẹ̀bùn owó, oúnjẹ, aṣọ àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ ní ìkókó mú wọlè fún ẹbí Kemisola Ogunniyi ní Ondo

Oríṣun àwòrán, @MBuhari
Kò sí ìpínlẹ̀ tí ijọba mi kò tíì fọwọ́ bà sí rere- Ààrẹ Muhammadu Buhari
Ààrẹ Muhammadu Buhari ni kò sí ìpínlẹ̀ kan ni Nàìjíríà tí ìjọba òun kò tíì fọwọ́ bà nípa isẹ àkànṣe amáyédẹrùn.
Buhari so èyí níbi ìpàgọ́ àwọn ẹ̀ka ọ̀dọ́ All Progressive Congress tó wáyé ní gbongan International Conference Centre, Abuja l'ọ́jọ́ Aje.
Lorí ètò ààbò, ààrẹ Buhari tí akọ̀wé ìjọbaa àpapọ̀, Boss Mustapha ṣojú fún ṣàlàyé pé ẹnikẹ́ni tí wọ́n bá ká ìbọn mọ́ lọ́wọ́ lọ́nà aitọ́ yóò fojú wina òfin.
Boss Mustapha rọ àwọn ọ̀dọ́ láti hùwà tí yóò mú itẹsiwaju bá orílẹ̀ èdè yìí àti àwọn tikara wọn.
"Aarẹ náà gbà pé lóòótọ́ orileede yìí ń kojú ìṣòro ètò àbò tó mẹ́hẹ, láti orí ìdí gùn jalè ojú pópó, ìjínigbé, ìgbésùmọ̀mí àwọn darandaran agbébọn to ń pá àwọn àgbẹ̀ àti àwọn tó ń pànìyàn ni ìhà ila-oorun Gúsù."
- Kò lè sí ààbò fún iléèwé kankan àfi tí ìjọba bá wá iṣẹ́ fáwọn tó ń jí ọmọ gbé - Gumi
- Àlàyé rè é lórí bí o ṣe lè gbá owó ìrànwọ́ N50bn COVID-19 tí CBN gbé jáde
- Ọmọ ogun ilẹ̀ Nàìjíríà ti dóòlà ẹ̀mí díẹ̀ nínú àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tí wọ́n jígbé ní ìpínlẹ̀ Kebbi
- Ajínigbe sún gbàgbé láwọn 15 nínú àwọn 156 tí wọ́n jí gbé ní Tegina bá sálọ
- Ẹ wo bí olówó 'billionaire', Usifo Ataga ṣe kú ikú òjijì ní Eko
- Ṣé lóòtọ́ ni àwọn ọmọ ogun òfurufú Nàìjíríà ṣèèṣì pa máàlú 1,000 ní Nasarawa?
- Ajínigbe sún gbàgbé láwọn 15 nínú àwọn 156 tí wọ́n jí gbé ní Tegina bá sálọ
Boss Mustapha fi wọn lọ́kàn balẹ pé ìjọba yìí yóò fòpin sí gbogbo pálapàla tó wà nílẹ̀ yìí pàápàá jùlọ lórí ètò àbò tó mẹ́hẹ.
Boss Mustapha ni: "Gbogbo èrò ìjọba, isẹ àkànṣe àti yiyan awọn eniyan sipo ni ìjọba yìí ṣe ní ìlànà ọgbọọgbà fún gbogbo ẹ̀yà.
"Kò sí ìhà ibikan ni orilẹ-ede yìí tí ìjọba kò tíì fọwọ́ bá ní ọ̀nà tó ni ìtumọ̀, yálà nípa ṣíṣe ohun amáyéderùn, ètò ọgbìn, tàbí bí nnkan ti ẹkùn kọọkan bá nílò ṣe ṣe pàtàkì sí.
- Wo ǹkan méje tí o lè má mọ̀ nípa Fola Alade to ya ilé '1004 Estate' tó dolóògbé
- Wo ìdí tí EFCC fi fẹ́ wádìí ilé aṣòfin ìpínlẹ̀ Ogun láti ọdun 2015 dí àsìkò yìí
- Father's Day fa gbas-gbos láàrin Mercy Aigbe àti ọkọ rẹ̀ tẹ́lẹ̀, Gentry, ọkọ́ ní òun le tú àwọn àṣírí ìwà nọ̀bì rẹ̀ síta
- Àlàyé rè é lórí bí o ṣe lè gbá owó ìrànwọ́ N50bn COVID-19 tí CBN gbé jáde
- Ọmọ ogun ilẹ̀ Nàìjíríà ti dóòlà ẹ̀mí díẹ̀ nínú àwọn akẹ́kọ̀ọ́ tí wọ́n jígbé ní ìpínlẹ̀ Kebbi
- Ìgbẹ́jọ́ Kemisola Ogunniyi kò wáyé lóní, ó tún dọ̀la, ṣùgbọ́n... - Agbẹjọ́rọ̀
















