Sheik Gumi, Banditry in Nigeria: Ọ̀run àpáàdì ń dúró de gbogbo ẹ̀yin aláìní ìrònúpìwàdà- Fani Kayode sí Gumi

Oríṣun àwòrán, others
Ọ̀run àpáàdì ń dúró de gbogbo ẹ̀yin aláìní ìrònúnupiwada - Fani Kayode sí Gunmi
Mínísíta ìrìnà òfurufú nígbà kan rí Femi Fani-Kayode tí bẹnu àtẹ́lu ọ̀rọ̀ tí Sheik Ahmad Gumi tó ń sọ pé kí ìjọba àpapọ̀ bá àwọn ọ̀daràn ajínigbé pawó ni gbólóhùn kàkà kí wọ́n pawọ́n dànù.
O ni laipẹ laijina ni onikaluku maa jere iṣẹ ọwọ rẹ ni eyi to maa jẹ ki awon kan wọ ọrun apaadi ni.
- Pipa ní wọ́n gbọ́dọ̀ pa àwọn agbébọn tí wọ́n ń jí àwọn ènìyàn gbé, ẹ da ọ̀rọ̀ Sheik Gumi nù -Aisha Yesufu
- Ẹranko àìmọ́ kan wọ Nàìjíríà, ó pa ènìyàn mẹ́rin ní Benue- ilé iṣẹ́ ọmọogun ni ìròyìn òfegè ni
- Kò sí ìpínlẹ̀ tí ijọba mi kò tíì fọwọ́ bà sí rere- Ààrẹ Muhammadu Buhari
- A ti fi páńpẹ́ ọba mú ènìyàn mẹ́ta lórí ìpànìyàn tó wáyé ní Iwo Road, Ibadan - Ọlọ́pàá
- Alága ìjọba ìbílẹ̀ Eti-Osa, Eko tí jádé láyé lẹ́yìn tó ṣe àìsàn
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ ẹni ọdún 40 tó fipá bá ìyá ọdún 60 lòpọ̀ ní ìpínlẹ̀ Ogun
Nínú Ìfọ̀rọ̀wànilẹ́nuwò kan lọ́jọ́ Ajé lọ tí sọ pé kò sí ilé ìwé tí yóò ní àlàáfíà àfi tí ìjọba bá dúnadúrà pẹ̀lú àwọn jàndùkú.
Ó ṣàpèjúwe ọ̀daràn bí àwọn tí wọ́n ń fìyà jẹ ti ó sì kìlọ̀ fún ìjọba láti má dábà á pípa wọ́n.
Lásìkò to ń fèsì si ọ̀rọ̀ Gumi Fani-Kayode bẹnu atẹ́ lu ọ̀rọ̀ ọkùnrin náà tí ó sì gba àwọn ọlọ́pàá níyànjú láti pá àwọn ọ̀daràn tí wọ́n mú yìí dànù.
Femi Fani Kayode ni: "Ẹ tẹ́ti sí ọkùnrin tí kò ní ọkàn ènìyàn tó ń gbèti àwọn ají ọmọ gbé àti apànìyàn. Ènìyàn burúkú, ẹranko àti aláìnírònúpiwàdà" lójú òpó Facebook.
"Gbogbo àwọn olùtàjẹ̀sílé, agbesùmọ̀mí àti àwọn agbénipawo yẹn ló yẹ kí wọ́n pá dànù kí wọ́n sì rán wọn lọ sí ọ̀run àpáàdì.
Àwọn tí wọ́n ń gbẹnu wọn sọ̀rọ̀, tí wọ́n ń gbè tí wọ́n tí wọ́n sì ń bá sì bá wọ́n wá awawi pé nǹkan tí wọ́n ṣe dára nílò láti kojú nǹkan tó burú jáì, kódà ọrùn àápàádi ló yẹ́ wọ́n
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ ẹni ọdún 40 tó fipá bá ìyá ọdún 60 lòpọ̀ ní ìpínlẹ̀ Ogun
- A kò gbọ́ pé Sunday Igboho fẹ́ ṣe ìwọ́de ní ìpínlẹ̀ Eko- Kọmisọ́nnà ọlọ́pàá
- Lẹ́yìn ìjà tò gbẹ̀mí èèyàn bíi mẹ́ta, Makinde sè ìfilọ́lẹ̀ ìgbìmọ̀ àlákòóso Amọtẹkun
- Wo ìdí tí EFCC fi fẹ́ wádìí ilé aṣòfin ìpínlẹ̀ Ogun láti ọdun 2015 dí àsìkò yìí
- Àlàyé rè é lórí bí o ṣe lè gbá owó ìrànwọ́ N50bn COVID-19 tí CBN gbé jáde
- Father's Day fa gbas-gbos láàrin Mercy Aigbe àti ọkọ rẹ̀ tẹ́lẹ̀, Gentry, ọkọ́ ní òun le tú àwọn àṣírí ìwà nọ̀bì rẹ̀ síta

Oríṣun àwòrán, Facebook/Dr Ahmad Abubakar Mahmud Gumi
Ó yẹ kí ìjọba wá ǹkan fi tan àwọn ajínigbépawó, ǹkan bíi owó, iṣẹ́ àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ
Kò lè sí ààbò fún iléẹ̀kọ́ kankan àfi tí ìjọba bá wá iṣẹ́ fáwọn tó ń jí ọmọ gbé - Gumi
Ilumooka ààfáà ẹṣin Islam kan to tun máa n ba awọn àgbesunmọmi at'awọn ajinigbe sọrọ pẹlẹ kutu, Sheik Gumi ti ni o to egberun lọnà ọgọrun agbebon lo wa ni iha Ariwa Iwo Oorun Naijiria nikan.
Gumi ni kii ṣe pe wọn n doju kọ ẹsin kankan, o ni ka ma tun gbagbe pe wọn o kawe yala lọnà lilọ ileewe ni tabi labẹ ile.
"Wọn kan n rin kiri pelu maalu ni ti wọn sì saadede ri iṣẹ tó lee pawo wọlé fún wọn".
- Ẹ wo ǹkan tí a mọ̀ nípa Sheik Gumi tó ń dúnà-dúrá pẹ̀lú àwọn agbébọn ní Nàìjírìá
- Sheik Gumi fèsì padà sí iléeṣẹ́ ọmọogun Nàìjíríà tó kì í nílọ̀ lórí ọ̀rọ̀ kòbákùngbé
- A ti rí ọmọ ilé kéú 11 míì nínú àwón tí agbébọn jí gbé ní ìpínlẹ̀ Niger
- 'A kò bomi sí ara tàbí lọ balùwẹ̀ fún odidi ọjọ́ 56 tí a fi wà ní páńpẹ́ àwọn ajínígbé'
- Lẹ́yìn ìjà tò gbẹ̀mí èèyàn bíi mẹ́ta, Makinde sè ìfilọ́lẹ̀ ìgbìmọ̀ àlákòóso Amọtẹkun
Amọ Gumi ni pẹlu ibanisọrọ, kikọni ni ẹkọ, at'awọn nkan taa le fi tan èèyàn bíi iṣẹ ati bẹẹ bẹẹ lọ, won a fi iṣẹ yìí silẹ.
Gumi ni awọn agbebọn to n ji awon akẹ́kọ̀ọ́ gbe gẹgẹ bí ẹ ṣe n gbọ lọtun ati losi banuje pe oun n ba awọn duna dura lai ni ọwọ ìjọba àpapọ̀ nínú.
Aafaa yìí ni dandan, o di igba ti ijọba ba ba awọn Fulani darandaran sọrọ, ko lè sí ileewe kankan ti abo rẹ daju.
O sọrọ yii nigba to ba iwe iroyin Punch sọrọ lori akitiyan to n jade lati doola awọn ọmọ ileewe Tegina Islamic School ni ipinle Niger.
"Awọn ajinigbepawo ọhun n beere fún ìgbà mílíọ̀nù naira ti wọn si pada din in ku si aadojo mílíọ̀nù naira".
Gumi ni pẹlu bi akitiyan láti doola wọn ṣe pọ to, awọn ajinigbe ohun duro lori ọrọ wọn fún owo ti wọn beere fun.
O ni amọ awọn ti n ba wọn sọrọ ọpọlọ pe awọn ọmọ ileewe yii ko mọwọ mẹsẹ.
Gumi fi kun un pe lori ọrọ awọn akẹkọọ musulumi yìí, o ti fi aridaju hàn fun orilẹede pe awọn ajinigbe naa,
"ope niwọn wọn ni iriri igbaniwọ inu ẹgbẹ, wọn kan n wa owo lasan ni torinaa nkan to dara ni mo kaa sí".
- 'Kò sí ẹni tó lè ní kí a má wá sí Èkó, iwọ́de òní pẹ̀lẹ́ kùtù la fẹ́ ṣe'
- Ohun tó dára fún ètò ọ̀rọ̀ ajé wá ni láti yá owó fún ṣíṣe ojú pópó wá - Fashola
- Gómìnà ṣàbẹ̀wò sí àwọn tí ọlọ́pàá yìnbon lù l'Enugu, Ọ̀gá ọlọ́pàá ní ìwádìí gbọdọ̀ wáyé kíákíá
- Father's Day fa gbas-gbos láàrin Mercy Aigbe àti ọkọ rẹ̀ tẹ́lẹ̀, Gentry, ọkọ́ ní òun le tú àwọn àṣírí ìwà nọ̀bì rẹ̀ síta
"Amọ a nilo alabaṣiṣẹpọ, a sì nilo ìjọba lati ni oye nipa gbogbo eeyan. Emi nikan o le ṣe e".
Gumi tẹsiwaju pe gbogbo awọn tàwọn ti bá pade ti dawọ ijingbe duro ayafi ọkan ninu wọn to tun pada sinu èébì rẹ.
O ni o si so idi fún àwọn pe wọn pa oun ti lẹyin ti oun ro pe o yẹ ki idunadura waye.
Torí naa Gumi ni bi o ba ṣe ya si lati ba wọn sọrọ pọ, "awọn to ti pinu lati ko nkan ija silẹ, ẹo lo wọn lati tọju awọn to ku".
Bo tilẹ jẹ pe ijọba ipinlẹ Niger n gbiyanju lati doola awọn ọmọ naa amọ Gumi ni wọn o ní to lati ṣe eyi.
Lo ba ni àfi laa o, "awọn ijọba ko lagbara lati da abo bo awọn ileewe lalai kọkọ wa ọna ati fopin sí ijinigbe.
"Tẹẹ ba fẹ aabo láwọn ileewe, eo ṣe kọkọ bá àwọn ajinigbe joko sọrọ? Lẹyìn náà, eo le ka iye wọn. Bẹẹ bá kan n lo awọn ọmọ ogun fi ba wọn ja, yóò bá iṣẹ yín jẹ síi ni o tori tẹẹ ba bẹrẹ sí ní pa ọmọ wọn, ẹ ma gbagbe pé àwọn náà ni àwọn ọmọ tiwa nikawọ wọn".
- Ọwọ́ tẹ ọmọdébìnrín tó jí ara rẹ̀ gbẹ́ nítorí ìyá rẹ̀ ní kó lọ kọ́ ẹ̀kọ́ láti ṣe dókítà
- Ẹ ṣeun, ẹ kú àdúrótì mi! Ẹ wo ọ̀rọ̀ tí Tope Alabi padà sọ nípa awuyewuye tó wáyé lóri orin Oniduro Mi
- Dino Melaye fi ọkọ Rolls Royce bùgá lórí Instagram, ni oníṣòwò ọkọ́ bá ní kó wá san gbèsè owó ọkọ̀ tó jẹ́ òun
- Ẹ wo ohun tí a mọ̀ nípa bí agbébọn ṣe gbẹ̀mí sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀, Titus Badejo Ejanla ní ìlú Ibadan
- Àjọ JAMB ṣèlérí ìdánwò mìí fún àwọn tí NIN jákulẹ̀, ó tún fòfin de ibùdó CBT 25
- Ẹ wo bí olówó 'billionaire', Usifo Ataga ṣe kú ikú òjijì ní Eko


















