Sheik Gumi: Iléeṣẹ́ Ológun Nàìjíríà kìlọ̀ fún Sheikh Gumi pé kó ṣọ́ ẹnu rẹ̀ lórí àwọn agbébọn

Gumi

Oríṣun àwòrán, Others

Ileeṣẹ ologun lorilẹede Naijiria ti ṣekilọ fun gbajumọ asaaju ẹsin musulumi ni, Sheikh Ahmad Abubakar Gumi pe ko ṣọ ẹnu rẹ lori ọrọ awọn agbebọn lorilẹeede Naijiria.

Ileeṣẹ ologun fesi si ọrọ kan ti gbajumọ alfa musulumi kanSheikh Gum sọ lori eto mohumaworan kan.

Sheikh Gumi sọrọ kan Laipẹ yii lori eto mohunmaworan kan pe awọn kan wa to n lẹdi apo pọ tabi ṣe agbodegba fawọn agbebọn naa.

Gumi ni ijakulẹ ijọba lo bi wahala agbebọn ati pe pupọ wọn gan ni ko dagba to awọn ti wọn ji gbe lọ.

O ni awọn agbebọn kii jini gbe pa bikose lati pawo sapo.

Àkọlé fídíò, Alhaja Rukayat Batimoluwasi Oniwaka: Orin Wákà la fi ń ṣe Wáàsí, o tó ọdún 70 tí mo tí bẹ̀

Alukoro ileeṣẹ ọmọogun oriilẹ, Onyema Nwachukwu ṣalaye ninu atẹjade kan pe irõ pata ni Gumi n pa mọ awọn ologun lati ba a lorukọ jẹ.

O ni lootọ awọn amunibuni lee wa laarin awọn ologun sugbọn ileeṣẹ ologun ko ni faye gba awọn agbẹyinbẹbọjẹ laarun wọn, ọmọogun ti ọwọ ba wa tẹ yoo gba idalẹbi rẹ ni ibamu pẹlu ofin ologun ile Naijiria.

O wa rọ awọn majẹkobajẹ lawujọ pe wọn maṣe sọ ara wọn di odaluru letu to le tun fẹ wahala abo to wa nilẹnloju sii.

Pipa ní wọ́n gbọ́dọ̀ pa àwọn agbébọn tí wọ́n ń jí àwọn ènìyàn gbé, ẹ da ọ̀rọ̀ Sheik Gumi nù -Aisha Yesufu

Gbajugbaja ajafẹtọ ọmọniyan ni Naijiria, Aisha Yesufu ti sọ wi pe awọn oṣiṣẹ alaabọ ni aṣẹ lati pa awọn agbebọn ti wọn n ji awọn eniyan gbe paapaa awọn akẹkọọ.

Gumi ati Yesufu

Oríṣun àwòrán, Others

Yesufu to sọrọ naa loju opo ayelujara rẹ ni awọn agbebọn ti ṣekupa ọpọlọpọ eniyan, ti wọn si ti sọ di alairile gbe, nitori naa ijọba nilo ati pa wọn run.

O sọ ọrọ yii tako ọrọ ti Ilumooka àlfá ẹṣin Islam kan to tun máa n ba awọn àgbesunmọmi at'awọn ajinigbe sọrọ pẹlẹ kutu, Sheik Gumi to ni ki i ṣe pipa awọn agbebọn ni ọna abayọ si eeto aabo to dẹnukọlẹ ni Naijiria.

Gumi lasiko to n ba ileeṣẹ iroyin Punch sọrọ ni o to egberun lọnà ọgọrun agbebon lo wa ni iha Ariwa Iwo Oorun Naijiria nikan.

O ni pipa awọn agbegbọn yoo ba nkan jẹ si ni nitori awọn agbebọn naa ko ka iwe, nitori naa ẹni to ba pa wọn, pipa ni wọn yoo ma a pa awọn ti wọn ba jigbe.

Àkọlé fídíò, Fulani attack, Ajowa Ondo: Àwọn Bororo yìí ti kọ́kọ́ ń dàná ní Ajọwa tẹ́lẹ̀, ọmọ mi 5 di

Amọ, Yesufu ni awọn ọdaran ni awọn agbegbọn, ti Ọlrun si lọwọ si pe ki wọn fi iya jẹ awọn aṣeka ni awujọ.

''Ẹ gbọdọ pa awọn agbebọn nitori wọn ti pa ọpọlọpọ eniyan, ti wọn si ti ba ile ati ọna jẹ kaakiri orilẹ-ede Naijiria''

''Ọlọrun sọ wi pe ki a ma jẹ ẹlẹṣẹ tabi ọbayejẹ, bakan naa lo si sọ pe ki a ma kẹyin si wọn tabi ṣe bi ẹni pe wọn ko si ni aye.''

''Nitori naa awọn ẹsọ alaabo gbọdọ ṣekọlu si awọn agbebọn naa ati gbogbo awọn ọbalaye to n pa awọnb eniyan kaakiri''

Alfa Gumi yìí ni dandan, o di igba ti ijọba ba ba awọn Fulani darandaran sọrọ, ko lè sí ileewe kankan ti abo rẹ daju.

Àkọlé fídíò, End SARS: Kemi jáde níle láti lọ bá mi ra oògùn ni mo gbọ́ pé ọlọ́pàá ti gbée- Ìyá Kemisol