Sunday Igboho on Yoruba Nation: Kò sí ẹni tó lè ní kí a má wá sí Èkó, iwọ́de òní pẹ̀lẹ́ kùtù la fẹ́ ṣe

Ajijàngbara ilẹ̀ Yorùbá, Sunday Adeyemo tí ọ̀pọ̀ mọ sí Sunday Igboho ti tún tẹpẹlẹ mọ pé kò sí ẹnikẹ́ni tó le dá òun atawọn ẹmẹwa rẹ dúró láti má wá sí ìlú Èkó fún iwọ́de Yorùbá Nation.
Igboho sọ èyí di mímọ láti ẹnu agbẹnusọ rẹ̀ Olayomi Koiki.
O fi dáhùn àhesọ tó ń lọ pé alága ẹgbẹ́ awakọ̀ ẹ̀ka tí ìpínlẹ̀ Eko Musilimu Akinsanya tí gbogbo ènìyàn mọ̀ sí MC Oluomo sọ pé òun yóò dena ẹnikẹ́ni tó bá jáde fún iwọ́de ìjìjàngbara ilẹ̀ Yorùbá kankan ní Ìpínlẹ̀ Eko.
- Ìròyìn ikú nípa Prophet SK Abiara; Ẹlẹ́jẹ̀ ni, ohun tí ẹbí Abiara sọ fún oníròyìn náà rèé
- Kò lè sí ààbò fún iléèwé kankan àfi tí ìjọba bá wá iṣẹ́ fáwọn tó ń jí ọmọ gbé - Gumi
- Lẹ́yìn ìjà tò gbẹ̀mí èèyàn bíi mẹ́ta, Makinde sè ìfilọ́lẹ̀ ìgbìmọ̀ àlákòóso Amọtẹkun
- Gómìnà ṣàbẹ̀wò sí àwọn tí ọlọ́pàá yìnbon lù l'Enugu, Ọ̀gá ọlọ́pàá ní ìwádìí gbọdọ̀ wáyé kíákíá
- Àlàyé rè é lórí bí o ṣe lè gbá owó ìrànwọ́ N50bn COVID-19 tí CBN gbé jáde
- Father's Day fa gbas-gbos láàrin Mercy Aigbe àti ọkọ rẹ̀ tẹ́lẹ̀, Gentry, ọkọ́ ní òun le tú àwọn àṣírí ìwà nọ̀bì rẹ̀ síta
Iwọ́de náà tí yóò wáyé ní ọjọ́ kẹta oṣù keje ni wọn ni yóò gbéra sọ láti ibùdókọ̀ Ojota.
Koiki sọ nínú fọ́nrán tó fi síta fi ṣàlàyé pé irú iwọ́de bẹ́ẹ̀ tí wáyé ní àwọn ìpínlẹ̀ Yorùbá tó kù, ó fi kún un pé iwọ́de òní pẹ̀lẹ́ kùtù náà kò kìí ṣe láti dá ètò ìlú ru tàbí rú omi àlàáfíà tó wà ní Ìpínlẹ̀ Eko.
Koiki ni: " A ń fi àsìkò yìí fi ọ̀rọ̀ ransẹ́ sì gómìnà Ìpínlẹ̀ Èkó Babajide Sanwó-Olú. Kò sí nǹkan tó kàn wá pẹlu ẹlòmíràn tó ní kí a má wá sí ìpínlẹ̀ Eko.

Oríṣun àwòrán, Sanwoolu, Igboho
Igboho ni "Sanwó-Olú ni alaṣẹ àti Alákóso ọ̀rọ̀ àbò nítorí náà a ń sọ fún pé a ń bọ̀ nípìnlẹ̀ Eko".
O fi kun un pe awọn ti lọ sí Ogun, Ondo, Osun, àti Ekiti ní ìrọ́wọ́rọsẹ̀ sì ni gbogbo rẹ̀ lọ, "nítorí náà kò sì ẹni tí ó lè sọ pé kí a má wá sí Eko".
- Timothy Obadare ìránṣẹ́ Ọlọ́run to fọ́ lójú ìta ṣùgbọ́n tó ríran jù ọ́pọ́ wòlíì lọ
- Ẹ ṣeun, ẹ kú àdúrótì mi! Ẹ wo ọ̀rọ̀ tí Tope Alabi padà sọ nípa awuyewuye tó wáyé lóri orin Oniduro Mi
- Ọwọ́ tẹ ọmọdébìnrín tó jí ara rẹ̀ gbẹ́ nítorí ìyá rẹ̀ ní kó lọ kọ́ ẹ̀kọ́ láti ṣe dókítà
- Dino Melaye fi ọkọ Rolls Royce bùgá lórí Instagram, ni oníṣòwò ọkọ́ bá ní kó wá san gbèsè owó ọkọ̀ tó jẹ́ òun
- Ẹ wo ohun tí a mọ̀ nípa bí agbébọn ṣe gbẹ̀mí sọ̀rọ̀sọ̀rọ̀, Titus Badejo Ejanla ní ìlú Ibadan













