Wo ìdí tí EFCC fi fẹ́ wádìí ilé aṣòfin ìpínlẹ̀ Ogun láti ọdun 2015 dí àsìkò yìí

Oríṣun àwòrán, others
Ajọ to n gbogun ti iwa ibajẹ ni Naijiria, EFCC, ti ṣetan wadii ile aṣofin ipinlẹ Ogun, lori ẹsun inakuna.
Awọn iwe iroyin abẹle jabọ iroyin pe EFCC ti kọ iwe si ile aṣofin naa, lati beere fun akọsilẹ nipa gbogbo awọn eto isuna ati awọn owo ti wọn gba laarin ọdun 2015 di akoko yii.
Lori eto kan, Sunday Morning Live on FM, ti waye lori redio ipinlẹ Ogun, ni ẹni to jẹ olori ile aṣofin ipinlẹ naa, Olakunle Oluomo, ti fidirẹ mulẹ pe lootọ ni awọn gba lẹta lati ọdọ EFCC.
O sọ pe lasiko ti awọn oṣiṣẹ ile ẹjọ wa ni ẹnu iyanṣẹlodi ni lẹta naa de.
- Ìyàwó kẹrin gún ọkọ rẹ̀ lọ́bẹ pa torí ó fún obìnrin míì lóyún
- Wọ́n ti rí Ọ̀pá Àṣẹ ilé aṣòfin ìpínlẹ̀ Ogun tí àwọn jàndùkú jí gbé nípinlẹ̀ Eko o!
- Ẹ fójú lóúnjẹ níbi African Drum Festival 2019
- Mo kú tì, nítorí pé àsìkò mi kòì tó láti padà sí ọ̀run- Kunle Ologundudu
- Mọ̀ si i nípa ìtàn eégún Gelede àti pàtàkì eégún náà sí àwọn obìnrin nílẹ̀ Yoruba
- Timothy Obadare ìránṣẹ́ Ọlọ́run to fọ́ lójú ìta ṣùgbọ́n tó ríran jù ọ́pọ́ wòlíì lọ
Gẹgẹ bi o sẹ sọ, o ni o ṣeeṣe ko jẹ aṣofin kan lo kọ iwe ẹsun si ajọ naa.
Botilẹ jẹ pe Oluomo ko darukọ aṣofin naa, iroyin sọ pe Aṣofin Dare Kadiri, to ti fi igba kan jẹ Igbakeji olori ile, amọ ti wọn yọ nipo, ti fi igba kan fi ẹsun kan Oluomo pe oun ṣe eto inawo ile ni nkan aṣiri.
Ẹsun to fi kan nigba naa ni pe nitori oun n beere fun akoyawọ ni wọn ṣe yọ oun ni ipo.
Oluomo sọ pe "oun ko si ni ipo adari ile laarin ọdun 2015 si 2019 ti wọn n beere fun.
O ṣalaye pe ọwọ ijọba ipinlẹ ni awọn aṣofin ti n gba owo; owo oṣu ati ajẹmọnu, ti ko si si owo mii to tun n wọ apo wọn.
O ni oun si ti paṣẹ fun awọn oṣiṣẹ ile ẹjọ lati tete ṣe akojọpọ awọn iwe ti EFCC n beere fun, nitori pe ile aṣofin naa ko ni ẹbọ ni ẹru rẹ.
- Fola Alade, 'Architect' tó ya àwòrán ọ̀pọ̀ ilé àti ọ́fíísì tí Naijiria ní ti kú!
- ''Oyún oṣù méjì ní Kemisola Ogunniyi gbé dé ọgbà ẹ̀wọ̀n, a sì ṣe ìtọ́jú rẹ̀ dáradára''
- Ajínigbe sún gbàgbé láwọn 15 nínú àwọn 156 tí wọ́n jí gbé ní Tegina bá sálọ
- Ṣé lóòtọ́ ni àwọn ọmọ ogun òfurufú Nàìjíríà ṣèèṣì pa máàlú 1,000 ní Nasarawa?
- Ẹ wo bí olówó 'billionaire', Usifo Ataga ṣe kú ikú òjijì ní Eko














