Gumi: Tani Sheik Gumi tó ń dúnà-dúùrá pẹ̀lú àwọn agbébọn ní Nàìjírìá?

Sheik Gumi

Oríṣun àwòrán, Google

Ọpọlọpọ eniyan lo tako bii Sheik Ahmad Abubakar Gumi ṣe dide gẹgẹ bi ẹni to n duna-dunra laarin ijọba ati awọn agbegbọn to n ji awọn eniyan gbe ni iha ariwa orilẹede Naijiria.

Eyi ko ṣẹyin bi Sheik Gumi lo di ilumooka lẹyin ti ijọba apapọ ni awọn nilo eniyan to mọ awọn agbebọn naa lati le ba wọn sọrọ.

Gumi lasiko to n ba awọn akọroyin sọrọ tako bi wọn ṣe n pe awọn agbẹbọn ni ọdaran,ko dara to ati wi pe awọn gan an ni ọdaran naa.

Bakan naa ni o fi lede wi pe awọn ọdọbinrin ọọdunrun ti wọn jigbe ni ileewe wọn ni Zamfara, ko si ni ọdọ awọn agbebọn ti oun ba sọrọ ni Kagara.

Sheik Gumi ni o tumọ si pe awọn ikọ agbebọn miran lo gbe awọn ọmọbinrin naa.

Àkọlé fídíò, Francis Olusola Alao: Wọ́n ti ti ọ̀rọ̀ òṣèlú bọ ọ̀rs Sunday Igboho, ṣùgbọ́n..- Oba Olugbọn

Ẹ wo ohun ti a mọ nipa iru eniyan ti Sheik Gumi jẹ.

  • Onimọ nipa ẹsin Islam ni Sheik Ahmad Gumi jẹ, oun si ni akọbi Shaykh Abubakar Gumi, ti wọn bi ni ilu Kano,
  • Oun ni Mufti ati Mufassir Mọsalasi gbogboogbo ni ilu Kaduna
Àkọlé fídíò, Femi Falana, Endsars: Awolowo kò fáààyè gba kí èèyàn máa yàgò fún Màálù nígboro
  • Fulani ni ni Gumi, to si jẹ onimọ ati ajagun tẹlẹ pẹlu ileeṣẹ ologun Naijiria,
  • Ọmọ ọdun mọkanlelọgọta ni Ahmad Abubakar Gumi, to si lo si ileewe Sadauna Memorial College ati fasiti rẹ ni Ahmadu Bello University to ti kọ iṣẹ gẹgẹ bi dokita,
Àkọlé fídíò, Mother tongue day 2021, Akomolede, YSAN: A ti parí iṣẹ́ lórí èdè ìperí Meta-Language Yorùb
  • Lẹyin naa lo darapọ mọ ileeṣẹ ọmọọogun Naijiria, Nigeria Defence Academy to si ṣiṣẹ de ipo Captain pẹlu ikọ ọmọogun Naijiria ko to fẹyinti lẹnu iṣẹ,
  • Oun lo fi apeja ọrọ ''My Vote, My Pride'' ni ọdun 2014.
Àkọlé fídíò, Regent Ondo: Láti 1978 tí Bàbá mi ti jẹ Oba ni mo ti ms pé máà jẹ adelé- Magaret Omonije I