Hijrah: Gómínà ìpínlẹ̀ Kano àti Oyo fi ọjọ́ ajé àti Iṣẹgun sílẹ̀ fún ìṣìnmi ọdún Hijrah

Gómínà ìpínlẹ̀ Kano àti Oyo fi ọjọ́ ajé àti Iṣẹgun sílẹ̀ fún ìṣìnmi ọdún Hijrah

Ipinlẹ Kano ati Oyo naa ti mú ọjọ ọtọọtọ fun awọn ara lati simi sile fun ayẹyẹ ọdun Hijrah.

Gomina ipinlẹ Kano Abdullahi Umar Ganduje ya ọjọ aje, ọjọ kẹsan osu kẹjọ gẹgẹ bi ọjọ isinmi lẹnu iṣẹ ni ipinlẹ naa.

Ganduje rọ awọn ara ilu lati gba adura fun orilede Naijiria lati gbaa lọwọ iṣoro eto abo to mẹhẹ.

Àkọlé fídíò, Taye Osinowo Olaosebikafi Iyabo Ojo, Mide Martins, Jaye Kuti, Afeez Owo àtàwọn míì dárà ap

Gẹgẹ bi atẹjade ti kọmisọna ọrọ to n lọ ni ipinlẹ naa fọwọsi Malam Muhammed Garba ṣalaye pe isinmi naa ni lati ṣe ayajọ ọdun tuntu ninu Islam 1443 AH.

Ganduje ki awọn musulumi ku orire ọdun tuntun ti o si pe fun idupẹ ati idakẹrọrọ.

Bakan naa lo rọ awọn eniyan ipinlẹ naa lati ran ijọba lọwọ ki wọn si gbiyanju lati ran ara wọn lọwọ fun igbeaye rere.

Ẹwẹ, Gomina ipinlẹ Oyo ti ni ki awọn ara ilu simi si ile wọn lọjọ Isegun ni ọjọ kẹwaa, osu kẹjọ lati ṣe ayẹyẹ ọdun Islam tuntun

Akọwe ijọba Olubamiwo Adeosun lo fi atéjade naa sita lọjọ Eti

Gẹgẹ bi o ṣe sọ Makinde rọ awọn Musulumi lati lo asiko naa fun adura, isọkan, alafia ati idagbasoke orilede Naijiria.