2nd wave Covid-19 in Nigeria: Ìjọba ìpínlẹ̀ Eko ti f'òfin de ìpéjọpọ̀ tó bá ju àádọ́ta (50) èèyàn lọ torí coronavirus

Oríṣun àwòrán, Twitter/Babajide Sanwo-Olu
Bi ina ko ba tan laṣọ, ẹjẹ kii tan leekanna lọrọ ajakalẹ arun covid-19 da bayii nipinlẹ Eko.
Lẹyin ti arun naa n fi ojoojumọ pọ si ni Naijiria papaa julọ nipinlẹ Eko, Gomina Babajide Sanwo-Olu ti kede pe ijọba ti fofin de ipejọpọ to ba ti ju aadọta eeyan lọ bayii kaakiri ipinlẹ naa.
Sanwo-Olu fọrọ yii lede ninu atẹjade kan to fi sita lọjọ Aiku.
- Èmi kọ́ ni mó dá ara mi, ẹ yé fi ọyàn bú mi mọ́- Damilola Adegboro
- Igboho vs Fulani: Báyìí ni nǹkan ṣé ń lọ nílé Sunday Igboho lónìí
- Sunday Igboho yarí, ó fohùn ránsẹ́ sáwọn èèyàn tó ń pẹ̀gàn rẹ̀
- Ṣé o tọ̀nà kí ilé ìtura máa fi 'Camera' sí iyàrá ìbùsùn àwọn àlejò?
- Wo bí àṣeyọrí iṣẹ́ abẹ ṣe wáyé lórí àwọn ìbejì tó lẹ́ pọ̀
- A jọ ṣe ìyàwó pọ̀, a jọ bímọ ní ọjọ́ kan náà, a tún jọ máa ń ṣàìsàn pọ̀ ni
Amọ, gomina ṣalaye ninu atẹjade ọhun pe ofin naa ko kan awọn ile ijọsin nipinlẹ Eko ti ijọba ti sọ fun tẹlẹ pe ki wọn ma ju idaji awọn olujọsin to n maa n jọsin tẹlẹ lọ ninu gbọngan ti wọn n lo.
''Inu ijọba ipinlẹ Eko ko dun si bi ọpọ eeyan ti n tapa si ilana ati dena ajakalẹ coronavirus,'' Sanwo-Olu lo bẹẹ.
Gomina Sanwo-Olu sọ pe ọpọ awọn eeyan to ni gbọngan ayẹyẹ lo ti n tapa si awọn alakalẹ ofin lori ati dena covid-19.
''Eyi ni lati kilọ gbogbo awọn to ba n ṣe iruẹ lati ki ọwọ ọmọ wọn bọṣọ, bi bẹẹ kọ, wọn o fi oju wina ofin,'' Sanwo-Olu kilọ.
Sanwo-ọlu ṣalaye pe ''gẹgẹ bi ofin ti Aarẹ Muhammadu Buhari buwọlu, ẹnikẹni ti aje iwa ibajẹ yii ba ṣi mọ lori yoo san owo itanran tabi ko ṣẹwọn oṣu mẹfa tabi ko ṣewọn ko si tun sanwo itanran.

Oríṣun àwòrán, Babajide Sanwo-Olu
Gomina ni gbogbo olugbe ipinlẹ Eko lo gbọdọ maa tẹle alakalẹ ati dena ajakalẹ arun coronavirus bayii.
- Ẹ yé ṣí ìhòhò ara yín síta lórí ayélujára torí ‘Silhouette Challenge’ - Adeboye
- Òfin kónílé-ó-gbélé gbòde nílùú Igangan lórí ẹ̀rù pé Fulani le k'ógun wá lẹ́yìn àbẹ̀wò Igboho
- Wo ọ̀nà márùn ún tí o fi lè rí owó láti fi ṣòwò lọ̀dún 2021 pẹlu ìrọ̀rùn
- ''Èmi àti òkú ìyá mí ni a jọ ń gbé fún ọdún mẹ́wàá ''
- Ṣé lóòtọ́ ní àwọn jàǹdùkú jó ìlé 200 àti ọ̀kọ́ 29 ní Ibadan?















