Grace Oshiagwu: Afurasí ní abọ́ oúnjẹ kan, ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta náíra lòun ń gbà lóri àwọn tó pa l'Akinyele

Oríṣun àwòrán, oyo nsight.com
Ọkan lara awọn afunrasi mẹta ti ọwọ ọlọpaa ba fun ipaniyan ọwọọwọ to n waye lagbegbe Akinyẹle nilu Ibadan, ni ipinlẹ Oyo ti sọrọ sita.
O ṣalaye pe abọ ounjẹ kan ati ẹẹdẹgbẹta naira ni oun n gba lori ọkọọkan awọn eeyan mẹfa to pa lagbegbe naa.
Laarin oṣu kan, ko din leeyan marun un, ninu eyi ti alaboyun kan ati awọn akẹkọọ meji wa, ti wọn ti ṣa pa lagbegbe ọhun.
- Òní ló yẹ kí Ibidunni Ighodalo pé ogójì ọdún, Tope Alabi, Kenolly àtàwọn míì tí yóò kọrin níbẹ̀ rèé
- Ṣé ojúlówó ni Oogùn apakòkòrò 'Sanitizer' tó ń lò? Wo bóo ṣe lè mọ̀ ayédèrú
- Wo bí ètò ìsìnkú Tolulope Arotilẹ yóò ṣe lọ nílùú Abuja lọ́sẹ̀ tó ń bọ̀
- Lizzy Anjori ṣèyàwó, àwọn òṣèré púpọ̀ ṣọjọ́ ìbí f'ọ́mọ lọ́sẹ̀ yìí
Ni ọjọ Ẹti nileeṣẹ ọlọpaa fi oju awọn afurasi kan han lolu ileeṣẹ ọlọpaa ni ipinlẹ Ọyọ to wa lagbegbe Ẹlẹyẹle.
Arakunrin ẹni ọdun mọkandinlogun naa ṣalaye pe babalawo kan ti o jẹ ẹni aadọta ọdun lo n ran oun ni iṣẹ ibi naa.
O fi kun un pe ni gbogbo igba ti oun ba ti fẹ jade lọ paniyan ni babalawo naa maa n fun oun ni oogun ati ajẹsara ibilẹ gbogbo pẹlu ọfọ ati ayajọ ti oun yoo pe lati di afẹẹri ni ibi ti oun ti fẹ lọ ṣe ọṣẹ naa.

Oríṣun àwòrán, other
O ni, "ohun eelo ibulẹ ṣọfẹli ni mo maa fi n pa awọn eeyan ti mo ba fẹ pa, maa si ka ayajọ naa si ori onitọhun ni kete ti mo ba ti rii ti ẹjẹ n jade lara rẹ"
O ni aṣẹ ti baba fun oun ni lati maa rin yi awọn agbegbe ti oku naa ba wa ka ki oun to kọ ẹyin si wọn.
Afurasi naa ni ẹmi awọn eeyan naa yoo lọ ba babalawo ti o sọ pe o n ran oun yii, ṣugbọn ti baba ko si sọ idi ti o fẹ fi mu ki oun maa pa awọn eeyan naa.
Ati pe a maa ra ounjẹ fun oun yoo si tun fun oun ni ẹẹdẹgbẹta naira pẹlu.
Amọṣa, babalawo to n fẹsun kan naa ṣalaye pe irọ patapata lo n pa mọ oun.
O ni iṣẹ ni wọn mu u wa kọ lọdọ oun ti oun si ti kọkọ kọ ọ silẹ fun awọn iya rẹ to mu u wa ki oun to tun da ọrọ naa ro lati gba a si ẹkọṣẹ ifa ni ọdọ oun lọdun 2016.
Gẹgẹ bii kọmiṣọnna ọlọpaa ni ipinlẹ Ọyọ, Nwachukwu Ewonwu ṣe sọ, awọn afurasi naa ni wọn gbẹmi Barakat Bello ni ọjọ kinni oṣu kẹfa.
Nigba ti wọn pa Grace Oshiagwu ni ọjọ kẹtala, oṣu kẹfa, ti wọn si tun pa ọmọ ọdun marun un kan, Mojeed Tirimisiyu ni ọjọ kejilelogun, oṣu kẹfa ni agbegbe akinyẹle.














