Tunde Braimoh: Itẹ́ òkú ní Vault Garden ní wọ́n sin Aṣòfin náà sí ní ìlànà ẹ̀sìn Musulumi

Braimo

Oríṣun àwòrán, @GiwaMoore

Awaye ku ko sin, ọrun ma kanju, gbogbo wa la n bọ.

Irọlẹ ọjọ ni wọn fi ilẹ bo oku asofin Tunde Braimoh ni asiri nilu Eko ni deedee aago meji ọsan.

Itẹ oku Vault Garden, to wa ni Awoyaya lẹba Mayfair Garden ni adugbo Lekki nilu Eko ni wọn sin asofin Braimoh si.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Bi o tilẹ jẹ pe ọpọ ẹbi, ọrẹ, ojulumọ ati alajọse nidi oselu lo ti peju sile rẹ lati daro iku rẹ, amọ ẹtahoro wọn lo bawọn peju sibi ti wọn ti sin oku rẹ.

Eyi ko si sẹyin ofin tita kete sira ẹni to wa nita, awọn to si peju sin asofin naa ko pe mẹwa niye.

Tunde Braimoh

Oríṣun àwòrán, @Toosaino

Awọn abanikẹdun ti yabo ile Tunde Braimoh, aṣofin ipinlẹ Eko to jade laye lowurọ ọjọ Ẹti.

Abẹwo BBC Yoruba sile oloogbe ṣafihan awọn ololufẹ rẹ, to n sọrọ tẹdun-tẹdun pe alaanu kan ṣoṣo to ku fun awọn ni wọn fi da wọn loro.

Àkọlé fídíò, Hon Buraimoh:Wọ́n fí ikú rẹ dáwà loro ní-abanikẹdun

Bo tilẹ jẹ pe a ko le fidi iru iku to pa oloogbe ọhun mulẹ, amọ o ta si akọroyin BBC Yoruba l'eti pe, ibudo itọju alarun Coronavirus to wa ni adugbo Yaba, ni Braimoh ku si.

Awọn abanikẹdun nile Braimoh

Ko ti i pe oṣu kan ti aṣofin to n ṣoju ẹkun idibo Kosofe, nile aṣofin agba Naijiria, Bayo Osinowo jade laye.

Asofin Braimoh lo n soju ẹkun idibo Kosofe keji nile asofin ipinlẹ Eko.

Awọn abanikẹdun nile Braimoh

Bakan naa ni asofin Buraimoh ti se alaga ijọba ibilẹ Kosofe ri, to si tun jẹ aṣoju ṣofin fagbegbe Ketu.

Ni nnkan bi oṣu meji si asiko yii, ni Braimoh ko ba pe ẹni ọgọta ọdun loke eepẹ.

Awọn abanikẹdun nile Braimoh

Koda ninu awọn to ṣeto isinku, to si gbalejo Gomina Eko, Babajide Sanwoolu nile aṣofin agba, Adebayo Osinowo ta mọ si Pepperito, lasiko to jade laye ni Braimoh wa.

Eyi lo mu ki awọn kan ma sọ pe, o ṣeeṣe ki o ti ko arun Covid-19 ṣugbọn a ko ti fidi ọrọ yi mulẹ.

Aworan aṣofin Braimoh lasiko ti Gomina Babajide Sanwoolu ṣabẹwo si mọlẹbi aṣofin agba Adebayo Osinowo to papoda

Oríṣun àwòrán, Other

Àkọlé àwòrán, Aworan aṣofin Braimoh lasiko ti Gomina Babajide Sanwoolu ṣabẹwo si mọlẹbi aṣofin agba Adebayo Osinowo to papoda

Gẹgẹ bi mọlẹbi rẹ kan to fi idi isẹlẹ naa mulẹ ti wi, idaji aarọ ọjọ Ẹti oni ni asofin naa tẹri gbasọ, ko si tii si ẹni to lee fi idi ohun to ṣokunfa iku rẹ mulẹ.

Alaga agbegbe idagbasoke Ikosi Isheri nilu Eko, Ọmọọba Samiat Abolade Bada ti wa n daro iku rẹ eyi to n fi idi iku oloogbe naa mulẹ fun ọpọ eeyan.