AGF Abdulrasaq Abdulganiyu, Bàbá gómìnà Abdulrahman Abdulrazaq tí ìpínlẹ̀ Kwara ti dágbéré fáyé l'Abuja

Oríṣun àwòrán, others
Owurọ oni, ọjọ Abamẹta ni baba to bi gomina ipinẹ Kwara, Abdulrahman Abdurasaq, jade laye.
Ọṣu Kọkanla, ọdun 1927 ni wọn bi baba naa, Abdulganiyu Abdulrasaq to ku si Ilu Abuja lẹni ọdun mẹtalelaadọrun.
Ilu Onitsha, nipinlẹ Anambra ni wọn bi baba naa si lọdun 1927.

Oríṣun àwòrán, others
Itan sọ pe o jẹ ọkan lara awọn akẹkọọ ipinlẹ ni Fasiti ilu Ibadan lọdun 1948, nibi to ti kẹkọ imọ ofin.
O di agbẹjọro agba (SAN) lọdun 1985.
Wo awọn nkan mii to gbe ile aye ṣe ki ọlọjọ to de
Nigba aye rẹ, o ti fi igba kan jẹ aṣoju orilẹ-ede Naijiria si orilẹ-ede Cote d'Ivoire laarin ọdun 1962 si ọdun 1964.
O jẹ ọkan lara igbimọ alakoso Naijiria lọdun 1964 si 1966, gẹgẹ bi Minisita fun Eto irinna.

Oríṣun àwòrán, others
Lẹyin naa lo jẹ kọmiṣọnna eto ẹnawo akọkọ fun ipinlẹ Kwara, nigba ti ijọba Yakubu Gowon da ipinlẹ naa silẹ l'ọdun 1967.
O tun jẹ kọmiṣọnna fun eto ilera, ati igbaye-gbadun ara ilu.
O tun jẹ Alaga igbimọ to n risi eto igbaniwọle awọn akẹkọọ sile ẹkọ imọ ofin Nigeria, Nigeria Body of Benchers.
Ko tan sibẹ o, baba naa ni iroyin tun sọ pe o jẹ agbẹjọro akọkọ lati iha Ariwa Naijiria.
O tun jẹ Aarẹ ileeṣẹ to n mojuto paṣipaarọ ipin idokowo Naijiria laarin ọdun 2000 si 2003, ati igbakeji aarẹ ileeṣẹ naa laarin ọdun 1983 si 2000.

Oríṣun àwòrán, others
Ẹwẹ, o jẹ oye Mutawali ilu Ilorin, Tafida ilu Zazzau nipinlẹ Kaduna.
Iyawo rẹ to jẹ ẹni aadọrun ọdun, Raliat AbdulRasaq, ati ọmọ ati ọmọ-ọmọ lo fi silẹ saye lọ.
- Ò kéré tán N1million là ń ná lórí alárùn Coronavirus kọ̀ọ̀kan; àlàyé rèé- Ìjọba Eko
- Obìnrin àti ọmọdé tó há sábẹ́ ilé tó wó ní Ebute Meta ti ń gba ìtọ́jú, LASEMA ń ṣàyẹ̀wò ilé náà lọ́wọ́
- Ọlọ́pàá kan sọ pé òun ní láti ṣàyẹ̀wò ìlédíìí ǹkan oṣù Arabìnrin kan kó tó lè kọjá
- Ọwọ́ tẹ àwọn ọlọ́pàá tó fìyà jẹ obìnrin kan lọ́nà àìtọ́ n'Ibadan
- 'Kìí ṣe pé ìjánu Ọkọ̀ tó pa Tolulope Arotile já, ìwádìí wà lọ́wọ́ ọlọ́pàá'














