Foluke Daramola Salako sọ̀rọ̀ nipa iku Pa Kasumu
Ẹ gbọ́ ǹkan ti àwọn òṣèré tíátà sọ nípa Pa Kasumu

Oríṣun àwòrán, Others
Gbájú gbaja eléré tíátà Adebayo Salami ti gbogbo ènìyàn mọ̀ sí ọ̀gá Bello lóti fi ìkíní ránṣẹ́ lori ikú ọ̀kan lára wọ́n to di olóògbé, Kayode Odumosu ti gbogbo ènìyàn mọ si Pa Kasumu.
Pa Kasumu to di olóògbé ni ọjọ́ kini oṣù kẹta lẹ́yìn àìsàn fún ìgbà díẹ̀ pe ọdún mẹ́rìndínláàdọrin ko to da gbere faye.
Nígbà ti Salami ń sọ̀rọ, ó sàlàyé pé ènìyàn to ṣee mú yangan ni Pa Kasumu nígbà ayé rẹ̀, o si tún jẹ́ ẹni ti o máa ń tèlé òfin àti ìlànà iṣẹ́ rẹ.
- Pa Kasumu,gbajúgbajà òṣèré tíátà Yorùbá jáde láyé
- A dúpẹ́ o! Lẹ́yìn àyẹ̀wò, kò sí alárùn Coronavirus ní Nàíjíríà, sáká lara wa dá - Mínísítà
- "Àbámọ̀ ló gbẹ̀yìn bí mo ṣe yípadà láti obìnrin sí ọkùnrin, ń kò bá tí ṣe bẹ́ẹ̀"
- Obìnrin tó ń ṣiṣẹ́ ẹrú ní Oman tó bá fẹ́ òmìnira, yóò bá ọ̀gá rẹ̀ ṣùn - obìnrin méjì tó ti oko ẹrú dé
- Kaduna tún gbàlejò ìkọlù àwọn agbébọn, àádọ́ta èèyàn míì rọ̀run ọ̀sán gangan
O ni agbà òṣèré yóò ṣe àfẹri Kayode Odumosu gidigidi bákan náà naa si ni àwọn alábaṣiṣẹ́pọ̀ rẹ.
Ọga Bello tẹsiwaju pe "O bani níńú jẹ́ sùgbọ́n ko sí ǹkan ti a le ṣe si àṣẹ ọlọrun, sáàjú àsìkò yìí ni a ti ń sáfẹri Pa Kasumu nítori o ti tó ọdun díẹ̀ sẹ́yìn ti ko ti le darapọ̀ mọ wa mọ láti ìgbà ti o ti ṣe aisan"
"Àdúrà mi ni pé ki ọlọrun tẹ si afẹ́fẹ́ rere ki o si tu àwọn ẹbi olóògbé nínú"
Toyin Adewale, Jaiye Kuti, Toyin Adegbola àti Yomi Fabiyi naa wà lára àwọn òṣère tí o ti ń ṣe elédè lẹ́yìn rẹ
Nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀, Fabiyi ni "Ẹni iyi àti ẹyẹ ni Pa Kasumu ti mo si ni ìfẹ́ rẹ̀ gídí, mo ń ṣelède lẹ́yìn rẹ̀ fún iṣẹ́ ribiribi to ṣe nínu iṣẹ́ tíatita."
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post, 1
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post, 2
Jaye Kuti náà ń daro
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post, 3
Toyin Adewale, ń ṣelede lẹ́yìn Pa Kasumu
This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of Instagram post, 4
Ní ti Toyin Adegbola, O ní "O dárọ Kayode Odumosu, kí Ọlọrun dẹlẹ fún kí o sì tẹ si afẹ́fẹ́ rere.
Foluke Daramola- Salako lo kéde ikú Pa Kasumu lori àtẹjiṣẹ́ instagram rẹ, gẹ́gẹ́ bo ṣe sọ, Kayode Odumosu ku ni ilé iwosan kan ni Abeokuta lásìkò àisan ranpẹ














