Àwọn afurasí ọlọ́pàá lu akẹ́kọ̀ọ́ pa ní Kwara, òbí gbarata

Lẹyin osu mẹta gbako ti awọn ọlọpaa mẹta kan ṣokunfa iku akẹkọọ ile-ẹkọ gbogbonise Kwara kan, Abdulqoyum Ishola, akẹkọọ mii tun ti ṣagbako irufẹ iṣẹlẹ ọhun.
Lọtẹ yii, Sulyman Ayeyemi ni orukọ akẹkọọ naa, ẹni ọdun mẹtadinlogun, to jẹ akẹkọọ ile-ẹkọ gbogbonise ipinlẹ Kwara ni Ilorin.
Iwadii BBC News Yoruba fihan pe, lọjọ Kẹfa oṣu Kẹsan-an ni iya oloogbe naa, Alhaja Fausat Ayeyemi ati awọn abanikẹdun yabo olu Ileeṣẹ ọlọpaa ni Ilorin ti wọn si n gbara yilẹ pẹlu omije loju.
Ẹkun ti arabinrin naa n sun ni wi pe awọn ọlọpaa pa ohun lọmọ, wọn o jẹ ki ohun jere ọmọ toun tọ, o ni wọn pa a lasiko to ti yege to si n gbaradi lati lọ sin orilẹ-ede baba rẹ gẹgẹ bi agunbanirọ.
Bi obinrin naa se n kebosi, lo n bọ aṣọ kuro lọrun ara rẹ, ṣugbọn awọn abanikẹdun n sare da aṣọ bo o pada.

Ki ni ohun to ṣẹlẹ?

BBC News Yoruba lanfani lati ba agbẹjọro arabinrin naa ti oun naa wa nibẹ ni gbolohun, o si ṣalaye bi ọrọ naa ṣe waye.
Agbẹjọro Bakare ṣalaye pe, Sulyman jẹ ẹni ọdun mẹtadinlọgbọn, ọmọ bibi ilu Ajasẹ-Ipo ni ipinlẹ Kwara.
O ni ọmọ naa jẹ akẹkọọ ile ẹkọ gbogbonise Kwara, pe o si ti yege, o si n gbaradi láti sin orilẹ-ede baba rẹ ni osu Kiini ọdun 2025.
Agbẹjọro naa ni ọrọ owo lo pa Sulyman ati ọrẹ rẹ pọ, o sọ pe agbegbe Tankẹ ni wọn jọ n gbe ṣugbọn ọrẹ rẹ mẹjọ lọ si Ileesẹ ọlọpaa ni agbegbe Ganmo pe Sulyman jẹ ohun lowo nitori pe o mọ ọlọpaa nibẹ.
O ni "awọn ọlọpaa Ganmo naa, gbera wa si Tankẹ pẹlu kẹkẹ Marwa, wọn si mu oloogbe naa labẹ afara nibẹ.
"O sẹlẹ wi pe ariyanjiyan sẹlẹ laarin wọn nítorí pe o n beere bi wọn ṣe jẹ, ṣugbọn awọn tọrọ naa soju wọn sọ pe, wọn bẹrẹ si n lu u bi ejo aijẹ, titi ko fi le rin mọ, lẹyin naa ni wọn wọ ọ sinu kẹkẹ Marwa.
"Ohun ti a gbọ lẹyin eyi ni pe, o ti ku, nigba ti o daku mọ wọn lọwọ ni wọn gbe lọ sile iwosan gbogbo ni ilu Ilorin nibi ti wọn ti fìdí ẹ mulẹ pe o ti ku.
O ni gbogbo ẹri ni awọn ni lọwọ to fi mọ fọnran bi wọn ṣe lu u. O fi kun-un pe ohun ti o sẹlẹ jẹ ipaniyan ti awọn o si fẹ ki wọn fi ọwọ bo o mọlẹ.
Ohun tí ọlọ́pàá sọ lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà
Ni alẹ ọjọ Kẹjọ, osu Kẹsan-an ni agbẹnusọ ọlọpaa fun ipinlẹ Kwara, DSP Ejirẹ Adetoun Adeyemi, fidi iṣẹlẹ naa mulẹ ninu atẹjade to buwọlu to si fi lede.
O ni Ileesẹ ọlọpaa Kwara gbọ nipa iṣẹlẹ to jasi iku arakunrin Suleiman Olayinka, ẹni ọdun mẹtadinlọgbọn.
Adetoun sọ pe ẹsun irẹnijẹ ati yiyẹ adehun ni wọn fi kan-an oloogbe naa.
O ni lọgan si ni wọn ran awọn ọlọpaa jade fun iwadii lori ẹsun naa.
O ṣalaye pe gbogbo ọlọpaa ti ọrọ naa kan ni wọn ti wa lati mọle bayii fun iwadii to peye lori iku arakunrin naa.
Agbẹnusọ naa sọ pe bi iwadii ṣe n lọ naa ni Ileesẹ ọlọpaa yoo maa fi to araalu leti.















