Olusegun Obasanjo: Nàìjíríà yóò ṣẹ́gun ìpèníjà àbò tó mẹ́hẹ láìpẹ́

Oríṣun àwòrán, Obasanjo
Aarẹ nigbakanri lorilẹede Naijiria, Oloye Oluṣẹgun Ọbasanjọ ti fi da awọn ọmọ Naijiria loju pe, gbọnmọ-gbọnmọ abo to mẹhẹ bayii yoo di itan laipẹ.
Ọbasanjọ ṣalaye pe ẹpọn agbo ni ọrọ Naijiria ati ipenija abo to n koju rẹ lọwọ bayii; O ni mimi lo n mi, ko le jabọ.
O ni bo pẹ bo ya imọlẹ yoo tan, ti idẹrun yoo si de pẹlu gbogbo itajẹsilẹ to n waye yii.
Oloye Ọbasanjọ ni digbi ni igbagbọ oun duro pe orilẹede Naijiria yoo ṣẹgun ipenija abo to mẹhẹ to n ba a finra lọwọ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Yekeen Ajileye, ọ̀gá mi nínú iṣẹ́ tíátà ṣẹ̀ mí, ó ṣẹ ẹlẹ́dàá mi - Abija
- Ẹ̀yin tí Baba Ijesha bá ọmọ tàbí àbúrò yín lòpọ̀ láìtọ́, ẹ fi ẹjọ́ ṣùn mí - Princess Comedian
- Gbogbo abiyamọ aye ẹ gba wá, wọ́n ti fẹ́ tú Baba Ijesha silẹ - Iyabo Ojo figbe ta
- Obìnrin ẹlẹ́sẹ̀ kan tó ń kirí omi rí àánú gbà lọ́wọ́ ìjọba Eko
- Olórùka ti gba òrùka, n kò sí lórí àtẹ mọ́, ẹ má sanwó láti fẹ́ mi - Oluwo figbeta
- To bá ń gbé l‘Eko, wo ohun tó ṣe láti bọ́ lọ́wọ́ olè àti ọ̀daràn - Amẹ́ríkà
- Irọ́ ni o! A kò fa Mary Daniels, obìnrin ẹlẹ́sẹ̀ kan fáwọn ọlọ́pàá fún ìwádìí - Ìjọba Eko
- Mo nífẹ̀ẹ́ ọkọ mi si lẹ́yìn ikú rẹ̀ ju ojú ayé rẹ̀ lọ - Florence Ajimobi
- Nǹkán yan, wọ́n ń ṣe ìkówójọ fún Olorì Damilola láti fi gba ilé l‘Eko
- Ìwàásù Baba Adeboye ló sọ mí di Kristẹni - Funke Etti
- Wo oore tí Ramadan n ṣe fún àwọn ẹlẹ́sìn mìíràn tó n gbà á
- Ìdí tí mo fi bú sẹ́kún nílé aṣòfin àgbà rèé - Smart Adeyemi
Nibi eto ifẹyinti fun Biṣọbu agba ijọ onitẹbọmi lorilẹede Naijiria, Nigeria Baptist Convention, Ẹniọwọ Samuel Ayọkunle lagba oṣelu naa ti sọ eyi.
Oloye Olusẹgun Obasanjo ni bopẹ boya, orilẹede Naijiria yoo bori awọn iṣoro rẹ gbogbo.
Aarẹ Naijiria nigbakanri naa wa fi kun pe igbagbọ oun ko figbakan yẹ ninu orilẹede, oun si yi ri oye pe ohun gbogbo to le koko bayii m bọ wa dẹrọ laipẹ.

N kò gbọ́ rárá pé àwọn ènìyàn kan ń pariwo fún ìpinya Nàìjíríà - Obasanjo

Oríṣun àwòrán, Obasanjo
Ààrẹ tẹ́lẹ̀ ní Nàìjíríà, Olusegun Obasanjo sọ pé òun kò ri gbọ́ pé àwọn ènìyàn kán kígbe pé àwọn fẹ́ ìpinyà orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn IPOB àti àwọn tó n bèèrè fún orílẹ̀-èdè Oduduwa wà lára àwọn tó n pè fún ìpinyà Nàìjíríà, sùgbọ́n ààrẹ àná ní òun kò mọ̀.
Lásìkò tó n ṣe ìfọ̀rọ̀wérọ̀ pẹ̀lú àwọn oníròyìn ní Sokoto, ni Obasanjo ti dáhùn ìbèérè tí akọròyìn kan bi i láti sọ sí ọ̀rọ̀ ìpinyà ti àwọn ọmọ Nàìjíríà kan ń pè fún.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ikú Jelili kó lọ lásán, iṣẹ́ bọ́ lọ́wọ́ Jonathan ọlọ́pàá tó ṣekúpa ní Quilox
- Ọjọ́ ìsinmi òni ro! Agbébọn ṣé ikọlù sílé ìjọ́sìn ní Kaduna, wọ́n jí ọ̀pọ̀ olùjọ́sìn gbé lọ
- Ẹgbẹ́ òṣèré tíátà TAMPAN sọ̀rọ̀ sókè lórí ẹ̀ṣùn bíbá ọmọdé lòpọ̀ tí wọn fi kan Baba Ijesha
- Kí ló fa ìjà láàárín Eedris Abdulkareem àti Festus Keyamo?
- Ẹgbẹ́ Oduduwa Republic Agitators ní ìwọ́de alágbára ń bọ̀ l‘Osun
- Pásítọ̀ pín ounjẹ iṣínu àwẹ̀ Ramadan fún àwọn Músùlùmí
- Kábíyèsí Ooni ti forí jin Sunday Igboho lẹ́yìn tó túúbá- Ààfin Ile Ife
- Àwọn ọ̀nà tá gbà rèé tí orílẹ̀èdè Oduduwa yóò fi tẹ̀ wá lọ́wọ́ - Gani Adams
Nínú ìdáhùn rẹ̀, ààrẹ àná ní " ìpinyà? mí o gbọ́ ǹkankan nípa ìpínyà tàbí pé àwọn kán ń pè fún un ni Nàìjíríà."
Obasanjo ti rìnrìnajo lọ sí Sokoto láti ọjọ́ Satide, níbi to tí lọ ṣe ìfilọlẹ̀ afárá olókè towo rẹ tó bílíọ̀nù mẹ́ta àti mílíọ̀nù lọ́nà irinwó nàìrà, tó sì tún sàbẹ̀wò sí àwọn iṣẹ́ àkànṣe mííràn ní ìpínlẹ̀ náà.
















