Olusegun Obasanjo àti Sheikh Gumi ṣe ìpaàdé lórí ètò àbò Naijiria tó mẹ́hẹ l'Abeokuta

Oríṣun àwòrán, OOPL
Aarẹ Naijiria tẹlẹ, Olusegun Obasanjo ati gbajugbaja ẹlẹsin Musulumi Sheikh Ahmad Gumi ti ke si ijọba apapọ lati ṣe agbekalẹ ile ẹjọ pataki ti yoo maa gbọ ẹjọ awọn janduku, awọn ajinigbe atawọn to n lo ibọn lai gba aṣẹ.
Wọn tun sọ pe ki ijọba ṣe atunsẹ igbeaye awọn ọdaran ti wọn ba ronupiwada, ki wọn si fun wọn ni ẹkọ ati iṣẹ ti wọn yoo maa ṣe dipo iwa ọdaran.
Obasanjo ati Gumi lo fi ọrọ naa lede ninu atẹjade ti awọn mejeji buwọlu lẹyin ipade ti wọn ṣe nile Obasanjo to wa niluu Abeokuta.
Ninu atẹjade naa to ni koko mọkanlelogun ni wọn tun ti rọ ijọba apapọ lati fi ọrọ eto abo Naijiria to mẹhẹ to ajọ ilẹ Afrika leti iyẹn, ECOWAS.
Obasanjo ki Gumi fun akitiyan rẹ lori eto abo loye ọya, bẹẹ naa ni Gumi gbe oṣuba kara fun Aarẹ tẹlẹri ọhun fun awọn ipa to ti sa sẹyin ki Naijiria le dara.

Oríṣun àwòrán, oopl
Bakan naa ni wọn tun gba ijọba ni imọran lati maa dabo bo awọn amí to ba n fi ọrọ awọn ajanduku naa to ijọba leti, ko si tun maa ṣe iwuri fun wọn.
Lara awọn koko naa ni "ki ijọba maa fi iya to tọ jẹ awọn ọdaju ọdaran, ko ma si fi oju aanu wo gbogbo awọn to n gbe ibọn kiri lai gba aṣẹ to yẹ."
"Ki ijọba tun ṣe agbekalẹ awọn ile ẹjọ pataki ti yoo maa gbọ ẹjọ awọn janduku, ajinigbe, awọn to n gba owo itusilẹ lọwọ ẹbi awọn ti wọn ji gbe, atawọn to n gbe ibọn kiri lọna aitọ."

Oríṣun àwòrán, oopl
Atẹjade naa pari pẹlu imọran pe ojuṣe gbogbo ọmọ Naijiria ni eto abo jẹ.
Lẹyin naa lo ni awọn memeji ti fẹnuko lati wa ọna abayọ si eto abo Naijiria to mẹhẹ, ati pe Sheik Gumi ti fi iwe pe Obasanjo lati bẹ ilu Kaduna wo lati tẹsiwaju ninu ijiroro wọn.
- Kí ló kan Ẹyin àti Ehoro nínú ìtàn àti ayẹyẹ ọdún Àjíǹde Jésú Krístì?
- Kí ló fa ìjà rọ̀fọ̀rọ́fọ̀ láàrin Toyin Abraham àti olólùfẹ́ rẹ̀ lórí ayélujára?
- Irọ́ ni o, kìí ṣe Boko Haram ló já ọkọ̀ òfúrufú ọmọgun Alpha Jet bọ́ - NAF
- Mo kọ láti gba lẹtà ọgá ọlọpàá, kí wọn má fi bọǹbù pa mí bíi Dele Giwa - Igboho
- Wo ohun mẹ́wàá tó yẹ kí o mọ̀ nípa Yinka Odunmakin, agbẹnusọ Afenifere tó dágbére fáyé
- Genesis Global: Sáká lara Woli Israel Ogundipe dá, kìí ṣe àìlera ló mú kí wọn fi sílẹ̀ lẹ́wọ̀n














