Missing Alpha Jet: Ayédèrú fídíò ni Boko Haram fi léde lórí ọkọ̀ òfúrufú ọmọgun Alpha Jet tó pòórá -NAF

Oríṣun àwòrán, NAF
Awọn onimọ nipa eto abo ti sọrọ lori baalu ileeṣẹ ọmọ ogun ofurufu to poora ni Maiduguri, eyii ti ikọ ẹgbẹ agbesumọmi Boko Haram sọ pe awọn lo jaa bọ.
Ninu atẹjada kan ti ileesẹ ọmọ ogun fi lede, wọn ni ofege ni fidio ti Boko Haram gbe jade lori bi wọn ṣe ja baalu naa bọ.
Wọn ni ko si ootọ kankan ninu fidio naa, ati pe ki awọn ọmọ Naijiria ma ṣe ka fidio naa si.
- Èèmọ̀! West Brom fi omi àbùkù wẹ̀ fún Chelsea lọ́sàn án gangan nílé wọn
- Ìwádìí rèé lórí ìdí tílé ẹjọ́ fi gba onídùróó Wòlìí Genesis lọ́gbà ẹ̀wọ̀n
- Kí ló fa ìjà rọ̀fọ̀rọ́fọ̀ láàrin Toyin Abraham àti olólùfẹ́ rẹ̀ lórí ayélujára?
- Ọ̀pọ̀ ọmọ Yorùbá ń ṣèdárò Yinka Odumakin tó di olóògbé
- Mo kọ láti gba lẹtà ọgá ọlọpàá, kí wọn má fi bọǹbù pa mí bíi Dele Giwa - Igboho
Ṣaaju ni ileeṣẹ ọmọ ogun ofurufu, NAF, ti kọkọ kede pe baalu naa, to ni nọmba idanimọ NAF 745 ti poora, ati pe iwadii ti bẹrẹ lati mọ bo ṣe rin.
Onimọ kan nipa eto abo, Audu Bulama Bukarti to n ṣe iwadii nipa eto abo l'Afrika sọ fun BBC pe, fidio ti Boko Haram gbe jade ko le jẹ otitọ nitori bi wọn ṣe ge fidio naa nigba mẹta ọtọtọ.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Onimọ naa wa ni o ṣeeṣe ki Boko Haram mọ ibi ti baalu naa ja si, ki wọn si tete de agbegbe naa lati ya fidio rẹ lasiko ti awọn ọmọ ologun ṣi n wa lọwọ.
Audu fi kun pe ewu n bẹ loko longẹ Naijiria to ba jẹ pe lootọ, ọkọ baalu ti ileeṣẹ ologun n wa ni eyii ti Boko Haram sọ pe awọn ja lulẹ.
Content is not available
View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.End of Facebook post, 1
O fi kun pe "ko ni jẹ iyalẹnu to ba jẹ pe Boko Haram lo ja balu naa bọ nitori misaili kan ti ikọ naa yin loṣu to kọja balẹ si aarin ilu Maiduguri, eyii to mu ẹmi eeyan mẹrindilogun lọ, lara awọn ti ọmọ wẹwẹ mẹsan an wa."
O pari ọrọ rẹ pe ijọba Naijiria ni lati gba pe awọn ọmọ ẹgbẹgun Boko Haram ni ohun ija oloro lọwọ, ki ijọba si ṣe ohun to yẹ lati ri pe awọn ọmọ ogun rẹ naa ni ohun ija to lagbara lati koju awọn ọmọ ogun Boko Haram ọhun.
- Àwọn ọ̀nà tá gbà rèé tí orílẹ̀èdè Oduduwa yóò fi tẹ̀ wá lọ́wọ́ - Gani Adams
- Sunday Igboho kò ṣẹ̀ sófin, lórí bó ṣe kọ láti gba ìwé ìpé Ọ̀gá Ọlọ́páà - YCE
- Ọ̀daràn darandaran pàdà sí Igangan, wọ́n gé ọwọ ọ̀gá ilé ẹ̀kọ́
- "Ikọ̀ Àmọ̀tẹ́kùn, ẹ ṣe pẹ̀lẹ́, ilẹ̀ ń yọ̀"
- Ọ̀pọ̀ Sunday Igboho, Nnamdi Kanu ní yóò díde torí ìpànìyàn ojoojúmọ́
Ki lo ti ṣẹlẹ sẹyin?
Ó ṣeéṣe kí ọkọ̀ òfúrúfú ọmọgun Alpha Jet tó pòórá tí já - NAF

Oríṣun àwòrán, NAF
Ilé iṣẹ́ ọmọ ogun ojú òfurufú ti ni ìwòyé ìwádìí àwọn fi hàn pé, ọkọ̀ òfurufú Alpha Jet (NAF475) tó pòórá kúrò lójú ìwòràn ilé iṣẹ́ náà, seese ko ti ja lulẹ.
Awọn ọmọ ikọ̀ ologun ojú òfurufú méjì lo wà nínú ọkọ ofurufu naa eyi to poora loju ofurufu lọjọru.
Kò sí àrídájú ǹkan tí ó fa ìṣẹ̀lẹ̀ yìí tàbi ibi tí àwọn ologun méjì náà já sí.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Gbàjarè! Ọ̀gá ọlọ́pàá fi ìwé ìpè àti géńdé 15 ránṣẹ́ wá mú mi - Sunday Igboho pariwo
- Ọ̀pọ̀ Sunday Igboho, Nnamdi Kanu ní yóò díde torí ìpànìyàn ojoojúmọ́
- Wo ìdí tí wọ́n fi n pé ayájọ́ ọjọ́ òní ni 'Good Friday'
- Alágbe ni olórin, ọ̀rọ̀ Wasiu Ayinde tó fẹ́ kí Yorùbá du ipò ààrẹ kò tó pọ́n - Gani Adams
- Oluwo, tí wọ́n bá rán ọmọ níṣẹ́ ẹrú, kó fi t'ọmọ jẹ - Gani Adams
- April Fool lásán ni o! N kò fi iṣẹ́ tíátà sílẹ̀ láti ṣe òṣèlú - Muyiwa Ademola
- Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá Oyo fèsì sí ẹ̀ṣùn Aláàfin àti Gani Adams pé ó ń tú afurasí sílẹ̀
- Òkùtà wọ agbe ṣíṣe, alágbe kò rí àánú gbà mọ́, ariwo sọ
- Rògbòdìyàn gbòde lọ́jà Bodija torí aṣọ́bodè tó fi tipá kó àpò ìrẹsì tírélà méje lọ
- Àwọn òṣèré tó ti bàjẹ́ láti ilé, ló kó ìbàjẹ́ wọ agbo tiata débi a'ṣọ ìhòòhò - Dele Odule
- Omijé ẹkún ṣàn níbi ìsìnkú sájẹ́ǹtì ọlọ́pàá táwọn tọ́ọ̀gì òṣèlú pa l'Ekiti
Awọn awakọ̀ òfurufú náà ni Ọgagun ofurufu John Abolarinwa àti Ebiakpo Chapele.
Content is not available
View content on FacebookBBC kò mọ̀ nípa àwọn ohun tí ó wà ní àwọn ojú òpó tí ó wà ní ìta.End of Facebook post, 2
Adarí ìpolongo àti ọ̀rọ̀ tó n lọ fún ilé iṣé ọmọ ogun ofurufu, Edward Gabkwet, lo sisọ loju ọrọ naa ninu àtẹ̀jáde kan to fisita.
O sàlàyé pé, gbogbo àwọn ikọ ọmọ ogun, tó fí mọ́ àwọn ọmọ ogun orí ilẹ̀, ló n ṣaayan lọ́wọ́lọ́wọ́ bayii lati ṣe àwárí àti ìdóòlà ẹ́mí àwọn ènìyàn náà.
Wọ́n fi kún pé, pẹ̀lú bi ǹkan ṣe lọ yìí, kò sí ǹkan ti kò le ṣẹlẹ̀ sùgbọ́n àwọn ni ìrètí pé ó yẹ kí wọ́n rí àwọn méjì náà láti dóòlà wọn.

Oríṣun àwòrán, NAF
Ọ̀sán ọjọ́bọ ọjọ́ kíní, oṣù kẹrin ọdún 2021 ni NAF kéde pé àwọn kò rí Alpha Jet mọ́ láti aago márún kọjá ìṣẹ́jú mẹ́jọ lọ́jọ́rú.

















