Genesis Global: Ìwádìí rèé lórí ìdí tílé ẹjọ́ fi gba onídùróó Wòlìí Genesis lọ́gbà ẹ̀wọ̀n

Oríṣun àwòrán, Genesis Global
Ileẹjọ kọtẹmilọrun nipinlẹ Eko ti gba beeli adari ijọ CCC Genesis Global, Israel Ogundipe lẹyin oṣu mẹrin ni ọgba ẹwọn.
Woli Genesis ni wọn fi silẹ ni Ọjọ Kini, Oṣu Kẹrin, ọdun 2021 lasiko igbẹjọ rẹ to waye ni ọjọ naa.
Ileẹjọ giga nipinlẹ Eko lo ran an lọ si ẹwọn ọdun kan pe, o jẹbi ẹsun gbigba ohun ini Arabinrin Olaide Williams-Oni, towo rẹ to miliọnu mẹtadinlogun naira, pe ohun fẹ ba a ra ilẹ.
- Ẹ dáríjin àwọn jàndùkú tó bá ronúpìwàdà, kí ẹ sì fún wọn ní iṣẹ́ tí wọn yóò máa ṣe - Obasanjo, Gumi
- SERAP pe Ààrẹ Muhammadu Buhari lẹ́jọ́ lórí ₦3.8b owó ètò ìlera tó pòórá
- Mo ti padà sí ẹ̀sìn òwúrọ̀ mi o! Ẹ̀ gb'Ọ́lọ́hun tóbi - Yomi Fabiyi
- Kí ló kan Ẹyin àti Ehoro nínú ìtàn àti ayẹyẹ ọdún Àjíǹde Jésú Krístì?
- Ogún ódún ni mo wà nígbà tí mo kọ́kọ́ ṣe ìgbéyàwó, ṣùgbọ́n ó túká nítorí ìfẹ̀ tí mo ní síṣẹ́ orin - Don Jazzy
- Èèmọ̀! West Brom fi omi àbùkù wẹ̀ fún Chelsea lọ́sàn án gangan nílé wọn
- Ẹ̀tanú pé Olùṣọ́ Genesis kò fẹ́ Laide Williams-Oni ló ṣe rán an lọ́ sí ẹ̀wọ̀n ọdún kan - CCC Genesis Global
- Wo bi wọ́n ṣe n ṣe àmójútó ilé ìjọsìn Prophet Israel Oladele, CCC Genesis Global
- Báyìí ni ìsìn ṣe lọ lónìí nílé ìjọsìn CCC Genesis Global
- Ẹ̀yà ara bí ẹ̀mí mi ló kú - Joe Okei, ìyàwó olóògbé Yinka Odumakin
Woli Genesis ni ko fara mọ idajọ naa, ti wọn si tẹsiwaju lọ si ileẹjọ kotẹmilọrun.
Amọ wọn ti gba beeli rẹ pe ki o ma a wa fun igbẹjọ rẹ lati ile titi ti ileejọ kotẹmilọrun yoo ṣedajọ rẹ.
Se lootọ ni Genesis Global ní Diabetes ní wọ́n ṣe tusilẹ ní ẹ̀wọ̀n?

Oríṣun àwòrán, Twitter/Israel Ogundipe
Ọpọlọpọ iroyin lo ti jade lori bi Isreal Ogundipe ṣe gba itusilẹ lẹwọn lai tii lo akoko rẹ tan ni ọgba ẹwọn.
Awọn iwe iroyin kan gbe e pe, nitori ailera ara rẹ ni wọn ṣe fi silẹ ni ọgba ẹwọn.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Kí ló fa ìjà rọ̀fọ̀rọ́fọ̀ láàrin Toyin Abraham àti olólùfẹ́ rẹ̀ lórí ayélujára?
- Ọ̀pọ̀ ọmọ Yorùbá ń ṣèdárò Yinka Odumakin tó di olóògbé
- Mo kọ láti gba lẹtà ọgá ọlọpàá, kí wọn má fi bọǹbù pa mí bíi Dele Giwa - Igboho
- Ẹkún àti ìdárò gbòde bí ọja páàtì ní Agodi-Gate ní Ibadan ṣe jóná mọ́jú
- Àwọn ọ̀nà tá gbà rèé tí orílẹ̀èdè Oduduwa yóò fi tẹ̀ wá lọ́wọ́ - Gani Adams
- Ọ̀daràn darandaran pàdà sí Igangan, wọ́n gé ọwọ ọ̀gá ilé ẹ̀kọ́
Ati wi pe agbẹjọro rẹ, Babatunde Ogala (SAN) lasiko igbẹjọ wi pe, o ni aisan suga, ti ko si raye gba itọju to peye ni ọgba ẹwọn, ni wọn ṣe fi silẹ.
Amọ, agbẹnusọ ile ijọsin Celestial Church of Christ, Genesis Global, Gbolahan Ashorobi sọ fun BBC Yoruba pe ko si otitọ kankan nitori iroyin pe ilera rẹ ni ko dara to.
Ashorobi ni saka ni ara rẹ da, ko si ni aisan kankan to n ṣe e.
Kini idi ti ileejọ fi gba beeli Genesis Global?

Oríṣun àwòrán, Facebook/Genesis Global
Agbẹnusọ ile ijọsin, CCC Genesis Global, Gbolahan Ashorobi ni idi mẹta ni ileẹjọ fi silẹ, ki wọn to gba oniduro Wolii Ogundipe.
O ni idi akọkọ ni nitori igbagbọ ti wọn ni ninu rẹ wi pe ko le e salọ ki igbẹjọ rẹ to bẹrẹ ni ileẹjọ.
O salaye pe ileẹjọ fi silẹ nitori igba akọkọ niyii ti yoo ṣẹ si ofin ati wi pe, ilumọọka ni ti ko le e salọ ni ilu nitori gbogbo igba igbẹjọ rẹ, lo n lọ si ileẹjọ.
O tun fikun pe adajọ salaye wi pe ọpọlọpọ ẹjọ lo wa ni iwaju ileẹjọ kotẹmilọrun, nitori naa, wọn ko le e fi awọn ẹjọ to wa niwaju wọn silẹ ma a da ẹjọ Genesis Global.
Adajọ ni tawọn ko ba gba oniduro r bayii, o le e lo gbogbo ọjọ to yẹ ko lo ni ẹwọn tan, ki igbẹjọ to kan an nile ẹjọ Kotemilorun.
Agbẹnusọ fun ijọ Genesis fikun pe ni ileẹjọ salaye wi pe yoo jasi ifiyajẹni lori asan to ba jẹ wi pe, ileẹjọ ṣe iwadii wọn, ti wọn si ri pe o ti lo ọdun kan ni ẹwọn lai jẹbi.
Ashorobi ni nitori naa ni wọn ṣe gba beeli rẹ pẹlu oniduro meji, milọnu meji naira pẹlu awọn ohun ini ilẹ.
Bakan naa ni agbẹnusọ naa sọ wi pe, awọn alaṣẹ ijọ naa yoo ba awọn akọroyin sọrọ ni Ọjọ Isinmi, Ọjọ Kẹrin, Oṣu Kẹrin, ọdun 2021 lati se alaye ọrọ naa lẹkunrẹrẹ.



















