Alaafin Oyo: Bá wo ni òrékelẹ́wà Adedoja tó gbàmì ẹ̀yẹ ''Miss Oyo 2020'' ṣe jẹ́ sí Alaafin?

Ọmọbabinrin Adedoja Adeyemi

Oríṣun àwòrán, Instagram/princessadedojaadeyermi

Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 1

Ọpọ lo mọ oniruuru arẹwa mọ Oba Lamidi Olayiwola Adeyemi, Alaafin Oyo.

Amọ, bi awọn arẹwa Olori ṣe rọgba yi Iku Baba ka naa ni Eleduwa fi awọn ọmọ to rẹwa ta baba lọrẹ.

Laipẹ yii ni Ọmọbabinrin Adedoja Adeyemi gba ami ẹyẹ arinrin oge gẹgẹ bi ọdọbinrin to rẹwa julọ nipinlẹ Oyo.

Adedoja, ẹni ọdun mẹrinlelogun gba la awọn oludije mii ti wa lati ẹkun mẹrinla ipinlẹ mọlẹ lati gba ami ẹyẹ naa.

Ọmọbabinrin Adedoja gba ẹbun ọkọ ayọkẹlẹ Toyota Camry lọ ile atawọn ẹbun miiran.

Skip Instagram post
Allow Instagram content?

This article contains content provided by Instagram. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read Instagram cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.

Warning: Third party content may contain adverts

End of Instagram post

Adedoja to kẹkọọ gboye nipa itan nile iwe fsaiti ipinlẹ Oṣun, UNIOSUN ti lọ si aafin Oyo fun adura lati ẹnu baba lẹyin to pegede tan nibi idije to ti kopa.

Ọmọbabinrin Adedoja n kẹkọọ lọwọ bayii lati gboye ẹkeji ni fasiti ilu Eko, UNILAG lori ilẹ Afirika.

Oun ni oludari ẹgbẹ kan to n ṣeranwọ fawọn ọmọ to ba ni arun foni ku fọla n de tawọn oloyinbo maa n pe ni SS.