Ibrahim Babangida: Mo rọ àwọn adarí wa láti jẹ́ àwòkaṣẹ́ rere fún aráàlú

Oríṣun àwòrán, Twitter
Adari ijọba ologun lorilẹede Niajiria tẹlẹri, ajagunfẹyinti Ibrahim Babangida ti rọ awọn ọmọ Naijiria lati ṣe suuru lori eto ọrọ aje to dẹnukọlẹ, eto ilera ati ebo aabo to mẹhẹ.
Ọgagun Babangida to n ba awọn ọmọ Naijiria sọrọ, ni ki wọn ranti pe, ko si ohun to ni ibẹrẹ ti ko lopin.
O ni ọdun 2020 wa pẹlu iṣoro ati awọn idojukọ to lera fun ọpọlọpọ eniyan ti kii ṣe Naijiria nikan, sugbọn kaakiri agbaye ni iṣẹlẹ naa ti waye.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ṣé lóòtọ́ọ́ ni Ọba Rilwan Akiolu padà sí ààfin lọ́jọ́ ọdún?
- Iléẹ̀kọ́ Deeper Life, ẹ san N100m owó gbà má bínú fún ọmọ mi, kẹ sì tọrọ àforíjìn - Òbí akẹ́kọ̀ọ́
- Àwọn òṣèré Yorùbá t'Élédùwà gbà fún àmọ́ tí wọn kìí ṣe ọmọ ilẹ̀ Yorùbá
- Dangote já mi kulẹ̀ lóri ọ̀rọ̀ ìfẹ́ àmọ́ ó kọ́ mi bá a ṣé lówó - Ọ̀rẹ́bìnrin Dangote lahùn
- Ẹ sunkún mọ níwọ̀n lórí àríwísí yín sí Buhari lọ́dún 2021 - Femi Adesina
- Mọ̀ si nípa Samuel Ajayi Crowther, bó ṣe pé àádóje ọdún tó jáye láyé
- Ọ̀lẹ adàrí, tí kò lóye, ló fìyà jẹ wá ní 2020 yàtọ̀ sí Coronavirus - Atiku Abubakar
'' Ohun to ṣẹlẹ si orilẹede Naiijiria ni ọdun 2020 kii ṣe si awa nikan, nitori arun Coronavirus naa ṣi n ja ranyin lagbaye, titi di wakati yii.
Nitori naa, gbogbo ẹkọ ti ẹ kọ ni ọdun 2020, ẹ gbọdọ mu lo ninu ọdun tuntun naa, ki o ma ba lọ lasan.
A rọ awọn eniyan lati mọ wi pe, idojukọ to lagbara ni arun Coronavirus, amọ ki wọn mu ni okunkundun, ki wọn le bori arun naa ni kiakia''
Bakan naa ni Babangida wa rọ awọn adari ni Naijiria lati jẹ awokọṣe fun awọn eniyan ti wọn jẹ adari fun.
Babangida ni ohun to buru jai ni ki aarẹ orilẹede kọ lati ba awọn ara ilu sọrọ lasiko ti nkan gbona janjan lara awọn eniyan.
Adari tẹlẹ fun ijọba ologun naa wa parọwa si awọn ọmọ Naijiria lati fọwọsowọpọ pẹlu ijọba, lati fopin si eto aabo to dẹnukọlẹ.
Ọ̀lẹ adàrí, tí kò lóye, ló fìyà jẹ wá ní 2020 yàtọ̀ sí Coronavirus - Atiku Abubakar
Igbakeji aarẹ lorilẹede Naijiria tẹlẹri, Atiku Abubakar ti sọ wi pe, kii ṣe arun Coronavirus nikan lo n ba Naijiria ja ni ọdun to kọja, amọ awọn adari ti ko ni imọ, ti wọn si tun ya ọlẹ, lo fi iya jẹ awọn ọmọ Naijiria.

Atiku Abubakar sọ eyi ninu isẹ ikini ku ọdun tuntun to fi ranṣẹ si awọn ọmọ Naijiria, ninu eyi to ti fi ariwirisi rẹ lede fun araye gbọ.
Atiku ni bi o tilẹ jẹ pe arun Coronavirus ba awọn eniyan finra lootọ, amọ ṣeni laanu pe ọpọlọpọ iṣoro naa lo duro ti awọn ọmọ Naijiria bii ajakalẹ arun.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Wo ọ̀pọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ táwọn òjíṣẹ́ Ọlọ́run sọ nípa ọdún 2021
- Ẹ sunkún mọ níwọ̀n lórí àríwísí yín sí Buhari lọ́dún 2021 - Femi Adesina
- Sowore tún kó sí àhámọ́ agbófinró torí ìwọ́de àìṣùn ọdún
- Àwọn kókó tó jẹyọ nínú ọ̀rọ̀ ọdún tí Buhari bá ọmọ Naijiria sọ
- Gbogbo ọjọ́ kérésì ni ìyá Leah Sharibu ń sàìsàn, ó tún ti wà nílé ìwòsàn
- Gbàjarè! Ràkúnmí làwọn agbébọn ń lò láti gbé àdó ikú wọ òkè ọya - Arewa figbe ta
O wa kesi awọn ọmọ Naijiria lati fọwọsowọpọ lati gbogun ti iwa jẹgudujẹra, igbesunmọmi ati awọn iwa ọdaran to ba awọn eniyan ja lorilẹede Naijiria, to fi mọ ọrọ aje to dẹnukọlẹ lorilẹede Naijiria.

Oríṣun àwòrán, AFP
Oludije sipo aarẹ lẹgbẹ oṣelu PDP lọdun 2019 naa wa rọ awọn eniyan, lati lo iṣọkan ti wọn gba laye lati gbogun ti arun Coronavirus naa, lati wa ọna abayọ si ipenija to n koju awọn ọmọ Naijiria.
''Pẹlu ayọ ni mo ki yin kaabọ si ọdun tuntun, ọdun 2021, ẹ si ku alaja ọdun to kọja to kun fun ibanujẹ ati irora''
- Bí 2020 ṣe ń lọ sópin, Alapinni Oosa wúre ọdún fún ọmọ Yorùbá
- A ti yí orin ọdún ń lọ sópin sí èdè Igbo àti Hausa - Mama Fasoyin
- Àkójọpọ̀ àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tó dára àti èyí tó burú tó wáyé ní 2020
- Ẹ wo àwọn ìlúmọ̀ọ́ká ọmọ Nàíjíríà tó jáde láyé lọ́dún 2020
- Wo ọ̀pọ̀ mílíọ̀nù fóónù tí Whatsapp kò ní bá ṣiṣẹ́ mọ́ lọ́dún 2021
- Ẹ wo àwọn èèkàn eléré ìdárayá tó bá ọdún 2020 lọ
''Bi a ti n wọ inu ọdun tuntun naa, mo ni igbagbọ pe arun Covid-19 naa yoo di ohun afiṣẹyin ti eegun fisọ, ti ko si ni gbooro mọ ni agbaye,''
''Igbagbọ mi ni pe oogun abẹrẹ ajẹsara naa yoo wa fun awọn ọmọ Naijiria laipẹ, eleyii ti yoo mu ki gbogbo agbaye pada si bi o ṣe wa tẹlẹ.''
''Mo gbadura fun ẹbi awọn ti ẹmi wọn ti lọ lati ipasẹ arun Covid-19 pe eedua yoo nu ẹkun wọn nu, ti a si fi ayọ rọpo sibẹ.''
''Bakan naa iya ati iṣẹ to n ba awọn ọmọ Naijiria finra niiṣe pẹlu awọn adari ti ko mu eto ọrọ aje munadoko ni Naijiria.''
Atiku Abubakar wa rọ awọn ọmọ Naijiria lati gba alaafia laaye, ki itẹsiwaju le ba orilẹede Naijiria.
















