Leah Sharibu: Ẹbí ní ìjọba Buhari kò ní àwáwí láti máṣe gba ìdáǹdè akẹ́kọ̀ọ́bìnrin náà

Oríṣun àwòrán, @Frank_Obiora
Iya to bi Leah Sharibu, ọmọbinrin ti Boko Haram ji gbe lati ọdun meji le diẹ sẹyin, ti dubulẹ aisan lọjọ Keresimesi, to si ti n gba itọju nile iwosan.
Bẹẹ ba gbagbe, ọjọ Kakandinlogun osu Keji ọdun 2018 ni Boko Haram ji akẹkọbinrin aadọfa ko lọ nile ẹkọ girama obinrin to wa nilu Dapci nipinlẹ Yobe.
Bi o tilẹ jẹ pe Boko Haram fun awọn akẹkọọ yoku nidande amọ Leah Sharibu, tii se ọmọ ọdun mẹrinla nigba naa, nikan ni wọn ko tu silẹ.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Gbàjarè! Ràkúnmí làwọn agbébọn ń lò láti gbé àdó ikú wọ òkè ọya - Arewa figbe ta
- Bí 2020 ṣe ń lọ sópin, Alapinni Oosa wúre ọdún fún ọmọ Yorùbá
- A ti yí orin ọdún ń lọ sópin sí èdè Igbo àti Hausa - Mama Fasoyin
- Àkójọpọ̀ àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tó dára àti èyí tó burú tó wáyé ní 2020
- Ẹ wo àwọn ìlúmọ̀ọ́ká ọmọ Nàíjíríà tó jáde láyé lọ́dún 2020
- Wo ọ̀pọ̀ mílíọ̀nù fóónù tí Whatsapp kò ní bá ṣiṣẹ́ mọ́ lọ́dún 2021
- Ẹ wo àwọn èèkàn eléré ìdárayá tó bá ọdún 2020 lọ
Gẹgẹ bi iwe iroyin Punch ti sọ, igba akọkọ kọ ree ti iya Leah yoo wolẹ aisan lọjọ ọdun Keresi nitori bo ti se naa ree lọdun 2018 ati 2019.
Agbẹnusọ fun idile naa, Gloria Puldu sisọ loju rẹ pe keresi kẹta ree ti Leah yoo se ni ahamọ ajinigbe.
O wa n rọ ijọba lati se amusẹ ileri rẹ lati gba idande Leah ni ahamọ Boko Haram.
O ni ko si awawi fun ijọba lori bi ko se le gba itusilẹ akẹkọọbinrin naa, niwọn igba to gba idande awọn akẹkọọkunrin Kankara laarin ọjọ mẹfa pere.










