Insecurity in Nigeria: Arewa ní owó ìdáǹdè ìjínigbé ni agbébọn fi ń ra ohun ìjà olóró

Awọn ohun ija oloro

Oríṣun àwòrán, Facebook/Nigeria Police Force

Ẹgbẹ apapọ awọn ọmọ bibi ẹkun ariwa Naijiria, Arewa, ti n ke gbajare ninu ọdun tuntun lori eto aabo to dojude loke ọya.

Alaga apapọ fẹgbẹ Arewa, Oloye Audu Ogbeh lo ke gbajare bẹẹ ninu atẹjade kan to fisita.

Ogbeh ni Rakunmi ati lawọn janduku n lo bayii lati gbe awọn ado iku ati ibọn ajabaalu walẹ wọ Naijiria wa, lati awọn ẹnu bode to wa lapa ariwa orilẹede yii.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Ninu atẹjade naa to pe akọle rẹ ni 'Awọn ẹnu bode wa ati aifararọ eto aabo', tun sisọ loju rẹ pe lati awọn orilẹede to mule ti Naijiria ni wọn ti n ko awọn ohun ija oloro naa wa.

Àkọlé fídíò, Adejare Adeboye: Olúwa yóò dá gbogbo ohun ta sọnù ní 2020 padà ní ilọ́po méje fún wa

Ogbeh, ẹni ti ko darukọ awọn orilẹede to mule ti wa naa, wa fikun pe ipinlẹ Sokoto ati Zamfara lawọn ti gbọ nipa iroyin yii, nitori awọn lo ba ilẹ Niger paala.

Alaga ẹgbẹ Arewa naa ni ojuse ẹgbẹ naa ni lati fi ọrọ yi to ijọba apapọ atawọn agbofinro leti, ki wọn le gbe igbesẹ to tọ nitori o n bọ, o n bọ, awọn laa dẹ de.

Bakan naa lo sisọ loju rẹ pe, owo ti awọn ajinigbe naa ba gba lọwọ mọlẹbi ẹni ti wọn mu nigbekun, ni wọn fi n ra awọn ohun ija oloro naa.

Àkọlé fídíò, Èmi nìkàn kọ́ ni mó n ṣe àkójọ orin- Fasoyin

O wa parọwa pe kawọn agbofinro maa bẹrẹ si yẹ ara awọn Rakunmi to n wọ ẹnu bode wa wo finnifinni, nitori eyi yoo se ilẹ Naijiria loore pupọ.

Ẹgbẹ Arewa wa n kọminu pe iye awọn agbegbọn yii lo n di pupọ si lojoojumọ, ko si ni pẹ ki wọn to ni awọn ohun ija oloro to yanranti lọwọ, ju awọn agbofinro lọ.