Osun Deputy Chief of Staff Fraud: Agbẹjọ́rò Binuyo ní ìbanilórúkọjẹ́ ní wọ́n fí ẹ̀sùn gbájúẹ̀ ṣé fún

Owo beba Naira

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Àkọlé àwòrán, Owoẹyẹ ni oun ko mọ ohun ti oun n se mọ, ti wọn si fi oogun gba owo to le ni miliọ̀nu lọna mejidinlogoji naira lọwọ oun.

Agbẹjọro fun igbakeji olori oṣiṣẹ lọọfisi gomina ipinlẹ Osun, Abdullah Binuyọ, ti fesi si iroyin to gbode pe awọn ọlọpaa ti fẹsun gbajuẹ kan an oun.

Wahab Ismail, to jẹ agbẹjọro Binuyo, ti wa fi atẹjade sọwọ si BBC Yoruba lori ọrọ yii, to si ni wọn fẹ ba orukọ onibara oun jẹ ni pẹlu iroyin yii.

Saaju asiko yii ni awọn iwe iroyin kan ti gbe iroyin pe, ọfisi ọga agba ọlọpaa Naijiria ti pe Abdullahi Binuyo lẹjọ, lori ẹsun mẹrin to da lori iwa gbajuẹ ati iwe yiyi.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

O ni ko si ootọ ninu ẹsun naa, to ni igbakeji olori osisẹ lọọfisi gomina l‘Osun gbimọran pẹlu awọn eeyan kan, lati lu arakunrin Tunde Ajalani ni gbajuẹ owo to to $120,000.

Àkọlé fídíò, Goitre Patients: Àwọn èèyàn tó ní àrùn gẹ̀gẹ̀ ní ọ̀pọ̀ ìkórira àti ìdẹ́yẹsí ní àwọn ń kojú

Wahab ni ''Ọrọ naa jẹ ọrọ iwa agabagebe ti awọn to gbe jade ko si na tan . Wọn mọọmọ fẹ fi tabuku Binuyo ni''

O ṣalaye pe, bo tilẹ jẹ pe lootọ ni Binuyo mọ si idunadura to waye laarin awọn to ṣe owo to fori sanpọn naa, wọn ko le mu labẹ ofin pe o jẹbi.

O fi kun pe, iye owo ti wọn n sọ ọhun kii ṣe ẹgbẹrun lọna ọgọfa dọla, bi kii ṣe pe ẹgbẹrun lọna ọgọrun dọla nii ṣe.

Ọga ọlọpaa abubakar

Oríṣun àwòrán, Twitter/nigeria police

Agbẹjọrọ naa tun sọ pe, lati nkan bii ọdun kan sẹyin ni awọn ti da owo naa pada, ti awọn agbẹjọro rẹ ati ọlọpaa naa jẹri si.

O wa pari ọrọ rẹ pe, awọn yoo tọ ipasẹ ofin lati tako ibanilorukọjẹ ti wọn fẹ ṣe fun Binuyo yii.

Labẹ ofin orilẹede Naijiria, awọn ẹsun ti wọn fi kan Binuyo jẹ eleyi ti ijiya wa fun labẹ ofin, to ni ṣe pẹlu iwa jibiti ati awọn ẹsẹ miran.