Coronavirus: Àwọn alárùn coronavirus ṣe ìwọ́de ní Gombe, wọ́n ní ìjọba n febi pa wọ́n

Oríṣun àwòrán, Twitter
Nṣe ni awọn alarun coronavirus tu si ita ọkan lara awọn ibudo ti wọn ti n tọju aarun naa nipinlẹ Gombe lati fi ẹhonu han lọjọ Iṣẹgun.
Wọn fi ẹsun kan awọn alaṣẹ pe wọn kofun awọn ni oogun tabi itọju, ati pe ounjẹ paapa ko si ka'nu.
Sugbọn sa, kọmisana eto ilera nipinlẹ naa, Ahmed Gana sọ fun BBC pe awọn eeyan naa ko fi apẹẹrẹ aarun naa han ni wọn ko ṣe nilo oogun.
Bakan naa ni awọn alaṣẹ sọ pe ko si nkan to jọ pe awọn ko fun wọn ni ounjẹ daada.
- Wo àwọn to ti rí ìwòsàn lọ́wọ́ àrùn coronavirus àti ibi tí wọ́n ti wá káàkiri Nàìjíríà
- Mẹ́rin nínú àwọn mọ́kànlá tó ń bọ̀ láti Sokoto tí wón mú l'Oyo ló ní Coronavirus
- Iye ìgbà tí Sani Abacha tí fi owó ransẹ si Nàìjíríà láti ọrun
- Ìlúmọọká akọròyìn NTA Nàìjíríà, Ayinde Soaga lùgbàdì Covid 19
- Báyìí ni àwọn agbófinró ṣe dá ìrìnkèrindò ọkọ̀ dúró lẹ́nu ibodè Nasarawa sí Abuja
Wọn pada bẹ awọn eeyan naa lati pada si ibudo naa, ṣugbọn wọn sọ pe ẹru n ba wọn nitori bi awọn alarun naa ṣe darapọ mọ awọn ara abule to jade wa a woran ohun to n ṣẹlẹ.

Oríṣun àwòrán, Twitter
Ijọba Gombe sọ pe aimọkan lo mu ki awọn eeyan naa ṣe iwọde. Wọn si rọawọn to ba jade wa a woran iwọde naa lati ya ara wọn si ọtọ fun ọjọ
mẹrinla.
Eeyan bi ọgọrun lo ni aarun naa lọwọlọwọ ni Gombe.
Ọwọ́ tẹ báàlẹ̀, Ṣinkó mẹ́tàdínlógún tó ń jí kùsà wà ní ìpínlẹ̀ Ọ̀ṣun
Awọ awọn agbofinro ti tẹ awọn ọmọ orilẹede China mẹtadinlogun kan ti wọn n ji kusa wa ni ipinlẹ Ọṣun
Ikọ alaabo ajumọṣe ti ijọba ipinlẹ Osun ṣẹṣẹ da silẹ lo he awọn eeyan naa lagbegbe Ileṣa ati Ifẹ ni ipinlẹ Ọṣun.
Bakan naa lọwọ awọn agbofin ikọ naa tun tẹ awọn mẹwaa miran pẹluu wọn ti wọn jẹ ọmọ agbegbe naa.ati baalẹ agbegbe ọhun.
Ọgbẹni Abdullahi Binuyọ to jẹ igbakeji adari awọn oṣiṣẹ lọfiisi gomina ipinlẹ Ọṣun ṣalaye pe ko si ijọba ti yoo kawọgbera maa woran nigba ti awọn eeyan kan yoo maa ba ọrs ajumọni rẹ jẹ tabi jii ko.
O fi kun pe awọn ajikusa wa naa ti ba odo ọṣun jẹ pẹlu oniruru awọn eroja to jẹ majele fun agọ ara.

Oríṣun àwòrán, osun state government
O ni yat s si pe wọn yoo foju wina ofin, awọn ti wọn mu naa yoo tun san owo gba maa binu fun ijọba.
Ọkan lara awọn ọmọ orilẹede China naa to le sọ ede Oyinbo ṣalaye pe nitoun, oun ko mọ pe wọn n ji kusa wa ni nitori pe ireti oun ni pe wọn ni iwe aṣẹ iwakusa latọdọ ijọba.
Osun Coronavirus: Coronavirus ti gbẹ̀mí èèyàn mìí ní ìpínlẹ̀ Osun

Oríṣun àwòrán, Adegboyega oyetola
Eeyan kan ti jẹ Ọlọrun nipe nitori arun Coronavirus ni ipinlẹ Osun, nigba ti ẹni to kọkọ ni arun ọhun ati awọn oṣiṣẹ eto ilera mẹta mii ri iwosan gba.
Kọmiṣọnna eto ilera ni ipinlẹ naa, Rafiu Isamotu sọ pe oloogbe ọhun to jẹ ọmọ aadọrin ọdun din diẹ gbẹmi mi ni ile iwosan ijọba Asubiaro, ni ilu Osogbo.
Isamotu ni ijọba gba esi ayẹwo ẹni akọkọ naa ati awọn oṣiṣẹ eto ilera to ri iwosan lalẹ ọjọ Ẹti.
O ni ilu London ni ẹni akọkọ to ni arun ọhun ni Osun ti wa, ṣugbọn ara rẹ ti da ṣaka bayii lẹyin to lo ọjọ mejidinlogoji nibi to ti gba itọju.
Lọwọ yi, eeyan mẹjọ ni àrùn Covid-19 n ba fínra ni Osun.
Ìjọba Osun dẹkùn lọrun àṣẹ konile ó gbélé
Koko ohun mẹ́wàá tí Gomina Oyetola báwọn èèyàn Ìpínlẹ̀ Osun sọ
Ìjọba Ìpínlẹ̀ Osun tí dẹkùn àṣẹ konile ó gbé lé ọlọsẹ méjì ni ọrùn àwọn èèyàn jákèjádò Ìpínlẹ̀ náà.
Ìjọba Ìpínlẹ̀ Osun ṣàlàyé pé, àwọn aráàlú yóò ní anfaani lati rin yíká ìpínlẹ̀ náà bẹ̀rẹ̀ láti aago mẹ́fà àárọ̀ si marun irọlẹ, láti ọjọ́ Ajé sì Ọjọ́bọ ọsọọsẹ.
Nígbà tó ń ṣàlàyé ìdí tí ìjọba Ìpínlẹ̀ Osun fi gbé ìgbésẹ náà, gomina Adegboyega Oyetola, nínú ọ̀rọ̀ tó bá àwọn èèyàn Ìpínlẹ̀ náà sọ ṣàlàyé pé, didẹ okun lọrun àṣẹ konile ó gbélé náà yóò mú kó rọrùn fáwọn
aráàlú láti máa ṣíṣẹ oojọ wọn.
Oyetola fikùn pé àṣẹ ọhun, tí yóò bẹ̀rẹ̀ lọ́jọ́ Ajé ọjọ́ kẹrin oṣù karùn-ún, ní yóò tún mú kó rọrùn fún ìjọba láti darí Ìpínlẹ̀ náà bọ ṣe yẹ.
Àmọ́ ó ní kó ni sì lílọ bibọ ọkọ àti èrò láti ìpínlẹ̀ kan si òmíràn lásìkò yii, tí wọn yóò sì gbé àwọn ẹnu bode ìpínlẹ̀ Osun tí pá.
Gomina Ìpínlẹ̀ Osun, Adegboyega Oyetola bá àwọn èèyàn Ìpínlẹ̀ náà sọ̀rọ̀ ni irọlẹ Ọjọ́bọ.
Àkànṣe eto naa si lọ dá lórí igbele àrùn Covid-19 àti akoso Ìpínlẹ̀ Osun.
Kókó mẹ́wàá tó sì jẹyọ rèé nínú ọ̀rọ̀ tó bá àwọn èèyàn Ìpínlẹ̀ ọ̀hún sọ.
- Alẹ́ ọjọ́ Aiku ni òfin konile ó gbélé to wá nilẹ yóò wa sopin
- Láti ọjọ́ Ajé, ọjọ́ kẹrin oṣù karùn-ún, ìjọba yóò dẹkùn lọrun àṣẹ konile ó gbélé, tí àwọn aráàlú yóò sì ní anfaani lati rin láàárín ìlú bẹ̀rẹ̀ láti aago mẹ́fà àárọ̀ si márùn-ún irọlẹ.
- Láàárín ọjọ́ Ajé sì Ọjọ́bọ si ni àwọn èèyàn ní anfaani lati lọ si ẹnu isẹ Ajé wọn, tí ìjọba náà yóò sì leè ṣíṣẹ ìlú.
- Òfin to de ìpéjọpọ̀ sì wá síbẹ̀. Kò sí gbọdọ si ìpéjọpọ̀ ọpọ èrò ni àwọn ilé ìjọsìn gbogbo, tàbí nílé ìwé, agbo òṣèlú àti níbi kibi.
- Bákan náà, Oyetola ni gbogbo àwọn ọjà si lọ gbọ́dọ̀ wà ní títì pa.
- Àwọn ibùdó itaja si lo gbọ́dọ̀ pèsè ọ̀sẹ̀ ifọwọ àti omi fáwọn onibara wọn
- Ibùdó itaja ìgbàlódé taa mọ si Supermarket, kò gbọ́dọ̀ ni ju èèyàn mẹ́wàá lọ ní ẹẹkannaa
- Gbogbo ààlà ibodè Ìpínlẹ̀ Osun pẹlu awọn Ìpínlẹ̀ tó mule tíì ní yóò sì wà ní títì pá, tí kò sì ní si lílọ bibọ ọkọ àti èrò àyàfi àwọn ọkọ akẹru tó ń kó oogun, oúnjẹ, èròjà epo rọbi àti ohun ọ̀gbìn nìkan ni yóò rí
- Àwọn ọlọkọ èrò yóò leè ṣíṣẹ ni aarin ìgboro láti ọjọ́ Ajé si Ọjọ́bọ ni ọsọọṣẹ, bẹ̀rẹ̀ láti aago mẹ́fà àárọ̀ si márùn-ún irọlẹ, tí wọ́n ko si gbọdọ gbé ju èrò méjì si ìlà ijoko kọ̀ọ̀kan lọ nínú ọkọ wọn.
- Gomina Oyetola wa kadi ọ̀rọ̀ rẹ nilẹ pé ọlọkada kan kò gbọ́dọ̀ gbé ju èrò kan ṣoṣo lọ, tí àwọn onikẹkẹ Maruwa kò sì gbọ́dọ̀ gbé ju èrò méjì lọ sí ẹyin ọkọ wọn nígbà tí kò gbọ́dọ̀ sì èrò kankan ní ijoko iwájú.

- Coronavirus: Àwọn ohun tí a kò tíì mọ̀ nípa àrùn Covid-19
- Kí lo mọ̀ nípa fẹntilétọ̀, ohun èlò aṣèrànwọ́ èémí
- Ṣé òògùn Chloroquine lè dènà ààrùn Coronavirus bí?
- Coronavirus tún ti ṣe ọṣẹ́ lórí iṣẹ́ líla ojú ọ̀nà relùwe láti Eko sí Ibadan - Ìjọba àpapọ̀
- Àrùn Coronavirus fa'lẹ̀ya láwọn ìletò aláwọ̀dúdú ní Amẹ́ríkà

NCDC covid 19 updates (Breakout): Ìjọba àpapọ̀ ní kò tíì sí ọjọ́ fún ìwọlé àwọn akẹ́kọ̀ọ́

Oríṣun àwòrán, Unilag
A o le sọ igba ti awọn ileeẹkọ yoo wọle pada ni Naijiria-Ijọba
A ko ti le sọ igba tawọn ileeẹkọ yoo wọle.
Minisista abẹle feto ẹkọ ni Naijiria, Emeka Nwajiuba, lo sọ ọrọ yi lasiko to n bawọn akọroyin sọrọ nibi ti igbimọ aarẹ to n dari eto gbogbo nipa Covid-19 n jabọ farailu.
O ni toun ti pe aarẹ ni wọn yoo dẹwọ ofin konile o gbele ni Abuja,Eko ati ipiinlẹ Ogun,ileesẹ eto Eko ko ti le sọ ọjọ ti awọn ileeẹkọ yoo bẹrẹ pada jakejado Naijiria.
Ninu ọrọ rẹ, o ni ''aarẹ kuku sọ nipa dida eto ọrọ aje pada diẹ diẹ.Bi a ko ba yanju eyiun naa, a ko le sọ pato ọjọ ti eto ẹkọ yoo gberasọ pada.O gbọdọ wa ni ibamu pẹlu eto to wa nilẹ yi ni.A ko fẹ fi awọn ọmọ wa sinu ewu''
O fi kun pe ''ko si ile ẹkọ kankan to le da isẹ se laifi ti oun sẹlẹ lawujọ se''
Nigba ti wọn fi ibeere sọwọ si nipa bi awọn akẹkọ yoo se bọ si ipele mi,o ni ''idanwo ti yoo gbe wọn lọ kilasi mii yoo waye lẹyin tawọn ba ti ri aridaju pe wọn ti kẹkọ to yẹ''
"Fawọn to wa ni kilasi ti wọn yoo ti bọ si abala miran o fi kun pe awọn n se igbaradi fun wọn.
''Lọwọlọwọ bayi, ajọ Waec to n seto idanwo fawọn to fẹ jade ileewe girama kan sun ọjọ idanwo siwaju ni,wọn ko wọgile.Ki a ba le mu ọjọ ni wọn fi ni awọn sun siwaju titi di igba miran.

Oríṣun àwòrán, unilag
Awọn akẹkọ yoo se idanwọ nigba ti a ab ati ri pe a le mojuto wọn daada''
Orileede Naijiria nikan kọ ni awọn ijọba ti gbe igbesẹ ki awọn ileewe wa ni titi pa lasiko arun Coronavirus yi.
Botilejẹpe awọn orileede kan ti wọn ti n jajabọ lọwọ arun naa ti ni ki awọn ipele eto ẹkọ kan bẹrẹ isẹ pada diẹdiẹ.

Oríṣun àwòrán, unilag
Ẹwẹ, ajọ eto ẹkọ ni Abuja ti kilọ fawọn ileeẹkọ lati ma se bẹrẹ isẹ pada nitori pe awọn ko ti pasẹ eyi to faye gba iru igbesẹ bẹ.
Adele akọwe ajọ naa Umaru Marafa ninu atẹjade kan to fi sita lọjọ Isẹgun ni digbi ni asẹ pe ki awọn ileeẹkọ wa ni titi pa si wa ti yoo si ri bẹ titi di igba ti asẹ mi yoo fi waye.
When would schools reopen in Nigeria?: Èyí làwọn ohun tí ọ̀pọ̀ ọmọ Nàìjíríà ń retí ṣùgbọ́n tí ààrẹ Buhari dákẹ́ sí

Oríṣun àwòrán, Bashir ahmad
Aarẹ Muhammadu Buhari gbe ọrọ rẹ kalẹ lori ibi to fẹ gbe ọrọ gba lori eto gbigbogun ti arun Coronavirus lorilẹede Naijiria.
Ọpọlọpọ awọn ọmọ orilẹede Naijiria ni wọn fi ojusọna fun ohun ti aarẹ yoo sọ ninu ọrọ rẹ, ti o si ṣe okunfa bi ọpọ ọmọ Naijiria nile ati loko ṣe sun ti awọn ohun elo gbogbo ti wọn lee fi ṣe alabapade aarẹ lori ohun to fẹ ka.
Amọṣa, lẹyin-o-rẹyin awọn nnkan kan wa eleyi ti aarẹ ko mẹnule, eyi ti ọpọ si ti n reti boya yoo sọrọ lori rẹ.
Lara awọn nnkan yii ni ọrọ iku ọwọọwọ to n waye ni ilu Kano. Ko fẹẹ wọpọ ninu awọn ọmọ orilẹede Naijiria ti ko maa ṣe haahin lori bi iku naa ṣe n waye.
Ọpọ n woo pe boya Aarẹ Buhari yoo lo anfani ọrọ rẹ lati fi ọkan araalu balẹ lori ohun to n ṣẹlẹ gan an ni ipinlẹ Kano, ṣugbọn ninu ohun ti aarẹ ka, yatọ si pe o ni aṣẹ konile-o-gbele ọlọjọyipo yoo wa nikalẹ nibẹ, ko daju pe aarẹ gan an funrarẹ tii mọ ohunkohun nipa okunfa iku ọwọọwọ ni ilu Kano.

Oríṣun àwòrán, Bashir ahmad
Eyi ni awọn ohun miran ti Buhari ko mẹnuba ninu ọrọ rẹ.
1.Nigba wo lawọn akẹkọ yoo pada si ileewe?
2.Eeyan melo ni yoo maa wa ninu ọkọ Danfo atawọn bọọsi akero nigboro lasiko ti wọn ba dẹ ọwọ aṣẹ naa diẹ bẹrẹ lati ọjọ kẹrin oṣu karun un ọdun 2020.
3.Pẹlu bi oniruuru eeyan yoo ṣe maa gbe ibomu tiwọn ran bayii, bawo la ṣe ayederu mọ ati pe ṣe gbogbo awọn ibomu wọnyii ni yoo le ṣiṣẹ idaabobo lọwọ arun yii?
4.Bawọn lawọn ipinlẹ ti ko lee se ẹnubode wọn lasiko ti konile-o-gble- ọlọjọyipo le koko yoo ṣe wa lee se wọn bayii ti konile-o-gbele ti rọlẹ sii?
5.Ṣe titi ipinlẹ Kano pa yoo jẹ ki a lee mọ ohun gan an to n ṣekupa ọgọọrọ awọn eeyan ni ipinlẹ naa?
Awọn ibeere yii ati omilẹgbẹ miran lawọn ọmọ orilẹede Naijiria n beere bayii lori ikanni ayelujara gbogbo lati igba ti aarẹ ti gbe ọrs apilẹkọ rẹ jade.
Kókó mẹ́jọ tó jẹyọ nínú ọ̀rọ̀ Ààrẹ Buhari fáwọn ọmọ Nàìjíríà

Oríṣun àwòrán, Bashir Ahmad
Aarẹ Muhammadu Buhari ti buwọlu wiwa ọwọ ofin konile-o-gbele walẹ diẹ ni ipinlẹ Eko, Ogun ati Abuja bẹrẹ lati Ọjọ Aje, ọjọ kẹrin, oṣu karun ọdun 2020.
Aarẹ Orilẹede Naijiria, ni awọn gbe igbesẹ naa lẹyin ti igbimọ amuṣẹya ti ijọba apapọ gbe kalẹ lori ọrs Coronavirus mu aba naa wa ni ifẹgbẹkẹgbẹ pẹluu awọn gomina atawọn igbimọ miran gbogbo ti ijọba gbe kalẹ.
Ninu ọrọ to ba awọn ọmọ Naijiria sọ lalẹ ọjọ Aje ni Arẹ Buhari ti sọ eyi di mimọ.
O ni adinku yoo de ba ọwọ ofin konile-o-gbele ṣugbọn eto ayẹwo ati ṣisawari awọn to ṣeeṣe ko ni arun naa yoo tubọ gbopọn sii.
Eyi ni awọn ohun meje miran ti aarẹ Buhari sọrọ le lori ninu ọrọ rẹ.
- Awọn ileeṣẹ kan yoo bẹrẹ si ni ṣiṣẹ pada laarin agogo mẹsan owurọ si agogo mẹfa irọlẹ.
- Ofin konile-o-gbele yoo maa wa laarin agogo mẹjọ alẹ si agogo mẹfa irọlẹ.
- Ko ni si eto irinna lati ipinlẹ si ipinlẹ, afawọn ti iṣẹ wọn ba kan dandan.
- Irinna ipinlẹ yoo wa fun awọn to ba n ko ẹru ti araalu nilo nikan.
- Wiwọ ibomu(face mask) ti di ọranyan bayii ni ita gbangba, ko si gbọdọ si ipejọpọ ọlọpọ ero nibikibi.
- Ofin konile-o-gbele yoo ṣi wa nikalẹ ni ipinlẹ Eko, Ogun ati Abuja
- Ofin konile-o-gbele kogberegbe yoo tẹsiwaju ni ipinlẹ Kano fun ọsẹ meji gbako, gẹgẹ bi ijọba ipinlẹ naa ti ṣe gbe e kalẹ
- Awọn gomina ipinlẹ kọọkan lee wa ṣe eto bi awọn aṣẹ wọnyii yoo ṣe ba awọn eeyan wọn lara mu ati aṣẹ miran ti ko gbọdọ tako eyi ti aarẹ la kalẹ wọnyii.

- Coronavirus: Àwọn ohun tí a kò tíì mọ̀ nípa àrùn Covid-19
- Kí lo mọ̀ nípa fẹntilétọ̀, ohun èlò aṣèrànwọ́ èémí
- Ṣé òògùn Chloroquine lè dènà ààrùn Coronavirus bí?
- Coronavirus tún ti ṣe ọṣẹ́ lórí iṣẹ́ líla ojú ọ̀nà relùwe láti Eko sí Ibadan - Ìjọba àpapọ̀
- Àrùn Coronavirus fa'lẹ̀ya láwọn ìletò aláwọ̀dúdú ní Amẹ́ríkà

Corornavirus: Òfin kónílé-ógbélé yoo dínku láti ọjọ kẹrin ọsù tó n bọ̀

Oríṣun àwòrán, others
Aarẹ Muhammadu Buhari ti kede pé láti ọjọ keji oṣu kaarun ọdun yii adinku yoo ba ofin konileogbele diẹ ni ipinlẹ Eko, Ogun àti Abuja.
Aarẹ ni ìgbesẹ yìí ko ṣẹyin ọna láti ri dáju pé àwọn agbẹ àti awọn oníṣẹ oojọ ko padanu ọna ati jẹ wọn, bákan náà ni ijọba ti ṣepade pọ pẹlu awon to n ri si eto ọ̀rọ̀ aje naijiria ti wọn si ti pese awọn imọran yìí.
Ẹwẹ, aarẹ ni gbigbe ofin yii wálẹ ko tunmọ si pe ki awọn eniyan pa ofin ọwọ fifọ ti, pàápàá jùlọ láti tẹle gbogbo ofin ti àjọ to n gbogun ti àjakalẹ ààrun lórílẹ̀-èdè Naijiria.
Láti aago mẹsan ọjọ keji osù kaarun, àwọn ọmọ le pada si ilé iwe nígba ti awọn ọlọkọ eero naa le pada si oju popo.
Ààrẹ Muhammadu Buhari ni àwọn alasilẹ ti ijọba yoo gunle ree lasiko yii
a. Ààgo mẹjọ alẹ si si aago mẹfa aarọ, eyi tumọ si pe ko ni si igbokegbodo eniyan ati ọkọ laaarin asiko yii.
b. Ko ni si aaye fun ọkọ ti ko ba ko àwọn ǹkan bii oogun tabi ounjẹ láti kọja ni ilú kan si omiran
kò ni si aaye irin aajo láti ipinlẹ kan si omiran, bakan naa ni gbogbo eniyan gbọdọ maa lo ibomu-bẹnu ni ìgbà gbogbo.
Bakan naa ni aarẹ fi kun pe ìjọba yoo fi alaalẹ sita lori igbesẹ ti awon ile iṣẹ yoo gbe ni asiko yii.
Ẹwẹ, aarẹ ni gbogbo awon alaalẹ yii ko kan ipinlẹ Kano
Aarẹ Muhammadu Buhari rọ àwọn ọmọ Naijiria lati tubọ ni maa fọwọsowọpọ pẹlu ijọba àti àwọn eleto abo láti tubọ tẹsiwaju ninu gbigbogun ti aarun coronavirus
O dupẹ lọwọ awọn osiṣẹ ilera, ajọ NCDC gbogbo ile iṣẹ ati aladani ti wọn nawọ iranwọ si ijọba àti awọn Naijiria
Ààrẹ Buhari yóò bá àwọn ọmọ Nàìjíríà sọ̀rọ̀ lónìí
Buhari to address the nation: Kí ni Ààrẹ Buhari yóò bá àwọn ọmọ Nàìjíríà sọ̀rọ̀ lónìí?

Oríṣun àwòrán, Garba Shehu
Aarẹ Muhammadu Buhari yoo ba awọn ọmọ orilẹede Naijiria sọrọ ni agogo mẹjọ ọjọ Aje.
Atẹjade kan eyi ti olubdamọran agba lori ọrọ iroyin, Fẹmi Adeṣina fi sita leyi ti jẹyọ.
Atẹjade ọhun fi kun un pe gbogbo awọn ileeṣẹ iroyin, edio, tẹlifiṣan and awọn ileeṣẹ iroyin miran to ba nifẹ sii lee darapọ mọ aarẹ.
- Ọwọ́ àwọn alásẹ ọgbà ẹ̀wọn ní ọ̀daràn to ni Corornavirus wà báyìí-Kọmísọ́nà ìlera Ondo
- Sunday Igboho dá sí ọ̀rọ̀ ìbejì Akeugbagold tí wọ́n jí gbé
- Ìjọba àpapọ̀ mọ̀ sí bí wàhálà àjàkálẹ̀ àrùn Coronavirus ṣe ń búrẹ́kẹ́ síi ní ìpínlẹ̀ Kano-Ganduje
- Kí ló fà ogun Ìjàyè àti ìṣubú Kurunmi, ìfẹ́ ìlú ni àbí orí kunkun?
Ni ọsẹ meji sẹyin ni aarẹ ba awọn ọmọ orilẹede Naijiria sọ irufẹ ọrọ bayii kẹyin nigba to kede afikun iye ọjọ igbele lati dena arun Coronavirus ni ipinlẹ Ogun, Eko ati Abuja tii ṣe olu ilu orilẹede Naijiria.
Ireti awọn eeyan ni pe aarẹ yoo ṣi aṣọ loju eegun fun araalu lati ms igbesẹ to kan lori aṣẹ konile-o-gbele jakejado orilẹede Naijiria.
Coronavirus extension in Nigeria: Ààrẹ Buhari leè pàṣẹ kónílé-ó'gbélé jákèjádò Nàìjíríà lọ́jọ́ Ajé-Kọmíṣọ́nà fétò ìlera ní ìpínlẹ̀ Ondo

Oríṣun àwòrán, Twitter/Muhammadu Buhari
O ṣeeṣe ki aarẹ orilẹede Naijiria o kede itẹsiwaju aṣẹ konileogbele to wa nilẹ ni awọn ipinlẹ bii Ogun, Eko ati Abuja.
Amọṣa iyatọ ti o ṣeeṣe ko de baa ni pe aarẹ Buhari lee fẹ aṣẹ naa loju ko ka gbogbo orilẹede Naijiria lai da ipinlẹ kọkan si.
Kọmiṣọna fun eto ilera ni ipinlẹ Ondo, Dokita Wahab Adegbenro lo sọ eyi di mimọ fun BBC News Yoruba.
Dokita Adegbenro ni awọn gomina ipinlẹ gbogbo lorilẹede Naijiria ti fi ero wọn han fun Aarẹ pe ohun ti wọn fẹ ni ki ijọba apapọ o ti gbogbo ipinlẹ pa lorilẹede Naijiria.
Bakan naa lo ni awọn kọmiṣọna ipinlẹ naa ti fi ọrọ to aarẹ leti gẹgẹ bi awọn onimọ pe ohun ti orilẹede Naijiria nilo bayii lati koju itankalẹ Coronavirus.
Ni aṣalẹ oni ni ireti wa pe Aarẹ Muhammadu Buhari yoo bun awọn ọmọ orilẹede Naijiria sori lori ohun to kan gẹgẹ bi igbesẹ lori aṣẹ konileogbele.
Kí lawn ọmọ Naijiria n reti lẹnu Aarẹ?
Lọwọ yii, iye awọn eeyan to laarun Coronavirus lorilẹede Naijiria ti le ni ẹgbẹrun bayii ti ijọba apapọ ti kede.
Titi di aṣalẹ ọjọ Aiku tii ṣe ọjọ kẹrindinlọgbọn oṣu kẹrin ọdun 2020, ipinlẹ mejilelọgbọn lo ti ni aarun Coronavirus lorilẹede Naijira pẹlu olu ilu ilẹẹwa, Abuja.
Bi iye awọn eeyan to n ko aarun yii ṣe n fojojumọ goke sii, paapaajulọ ni awọn ipinlẹ bii Eko, Kano ati Abuja, Aarẹ Buhari kede ofin konile-o-gbele ọlọjọ mẹrinla lawọn ipinlẹ bii Eko, Ogun ati Abuja. Nigba ti eyi pari ni aarẹ ba tun kede konile-o-gbele ọlọjọ mẹrinla miran eleyi tii yoo pari ni agogo mọkanla ọjọ Aje, ọjọ kẹtadinlọgbọn oṣu kẹrin ọdun 2020 lati dena itankalẹ arun yii.

- Coronavirus: Àwọn ohun tí a kò tíì mọ̀ nípa àrùn Covid-19
- Kí lo mọ̀ nípa fẹntilétọ̀, ohun èlò aṣèrànwọ́ èémí
- A fẹ́ lo ẹ̀jẹ̀ àwọn èèyàn tó ye àrùn Coronavirus láti fi ṣe ìwòsàn fún àwọn tó wà lórí àárẹ- UK
- Coronavirus: Kíni àwọn àmì tuntun tó n fihàn?
- Ọjoọ́ mélòó ni Coronavirus ń lò lára kí ènìyàn tó gba ìwòsàn?

Lawọn ipinlẹ bii Ogun, Eko ati Abuja, igbele oṣu kan gbako lawọn araalu ti wa bayii, eleyii to n mu ki ọpọ maa beere nigba wo ni igbele awọn yoo pari?
Ni bi a ṣe n sọrọ yii, ariwo to n ls loju opo ayelujara gbogbo bayii ni ibeere boya aarẹ yoo ṣi tun sun aṣẹ igbele tipatipa naa siwaju sii ni labẹ #lockdownextension
Coronavirus Update: Ìséde káàkiri Nàìjíríà lọ̀nà àbayọ sí ìtànkálẹ̀ ààrùn coronavirus
Onimọ nipa ajakalẹ aarun to ba BBC Yoruba ṣalaye pe iṣede kaakiri orilẹede Naijiria yoo ṣe iranwọ nipa gbogbogun ti itankalẹ aarun coronavirus.
Lai jẹ bẹẹ, aarun coronavirus maa ran ni kiakia de awọn ipinlẹ ti ko tii de ti ko ba si iṣede kaakiri orilẹede Naijiria.
O ni otitọ nipe iṣede kaakiri orilẹede Naijiria yoo mu idiwọ ba awọn onimọtọ atawọn mii ti iṣẹ wọn jọ mọ ki wọn maa rinrin ajo.
- Ewu ń bẹ! Coronavirus lè tara òkú Abba Kyari ran àwọn tó péjú síbi ìsìnkú rẹ̀- Ààrẹ ẹgbẹ́ dókítà ní Nàìjíríà
- Ìyàn ń bọ̀ ní Nàìjíríà lẹ́yìn coronavirus àyàfi... - Ẹgbẹ́ àgbẹ̀ kìlọ̀
- Iléèwé Chrisland yóò wọlé padà lọ́jọ́ Ajé, wọ́n ní òfin ìgbélé coronavirus kò mú ìgbẹ̀kọ́ orí ayélujára
- Nàìjíríà yóò wo tí aráàlú bá bínú lórí àfikún igbele Covid-19 - Dele Momoodu
O rọ awọn ọmọ Naijiria lati fi ara daa fun ọsẹ meji nitori anfaani gbogbo ọmọ Naijiria naa ni.
Ni ipinlẹ Osun, agbẹnusọ gomina, sọ pe awọn ti di gbogbo ọna to wọ ipinlẹ Osun lati awọn ipinlẹ miran. To si jẹ pe niṣe ni awọn ọlọpaa n da ọkọ ati eero to ba fẹ ẹ wọ ipinlẹ naa pada si ibi ti wọn ba ti n bọ.Ni ti akọwe ikede fun gomina Ondo, sọ fun BBC pe lootọ ni ofin de awọn ọkọ lati ipinlẹ miran si Ondo, aaye gba awọn ọlọkọ eero laarin ipinlẹ Ondo, kiki pe wọn ko gbọdọ gbe ju eero meji lọ.
Lori ẹsun pe awọn oṣiṣẹ alaabo n gba owo lọwọ awọn awakọ lati wọ ipinlẹ naa, o sọ pe lootọ ni iru nkan bẹ ẹ waye, ṣugbọn "a ti mojuto, o ti dawọ duro. Gomina ṣepade pẹlu awsn eleto aabo ni kete to mọ pe wọn n ṣe bẹ, ko si si iru ẹ mọ".

Oríṣun àwòrán, Ekiti state government
Fun ipinlẹ Oyo, Agbẹnusọ Gomina, Taiwo Adisa sọ pe awọn ti fi ofin de ọkọ lati ipinlẹ miran si ipinlẹ Oyo ko tiẹ to o dipe ẹgbẹ awọn gomina ṣe bẹ ẹ.
Ṣugbọn o, o ni awọn kẹẹfin pe awọn ọkọ maa n yọ ọ wọle ni alẹ, awọn si ti dawọ rẹ duro.
Koda, o sọ pe ọwọ tẹ awọn ọkọ ileeṣẹ nla kan mẹfa, to yẹ ko ko ounjẹ, ṣugbọn wsn tun fi ko awọn eeyan lọna aitọ.
Lọwọlọwọ, wọn ti n dawọn pada si ibikibi ti wọn ba wa.
Ìséde ń bọ̀ káàkiri Nàìjíríà, àwọn gómìnà ìpínlẹ̀ fẹ́nukò
Awọn gomina ipinlẹ gbogbo lorilẹede Naijiria ti fẹnu kolori titit gbogbo ẹnubode ipinlẹ si ipinlẹ pa jakejado orilẹede Naijiria fun ọsẹ meji bayii lati pinwọ itankalẹ ajakalẹ arun Coronavirus lorilẹede Naijiria.
Alaga igbims awọn gomina ipinlẹ lorilẹede Naijiria to tun jẹ gomina ipinlẹ Ekiti, Ọmọwe Kayọde Fayẹmi lo sọ eyi di mimọ lẹyin ipade ori ayelujara tawọn gomina naa ṣe lọjọru.
- Báwo lọ̀rọ̀ Tafsir, ìdanilẹ́kọ̀ọ́ lásìkò Ramadan yóò ṣe jẹ́ pẹ̀lúu Coronavirus tó gbòde yìí?
- Ìyàn ń bọ̀ ní Nàìjíríà lẹ́yìn coronavirus àyàfi... - Ẹgbẹ́ àgbẹ̀ kìlọ̀
- Ọ̀nà àbáyọ fún olóyún lásìkò àjàkálẹ̀ ààrùn Covid-19
- Ẹnìkan ṣoṣo nínú ìdílé kan ni yóò gbà N20, 000 owó ìdẹ̀rùn igbele Covid-19 - ìjọba àpapọ̀
O 'salaye pe awọn eeyan ti iṣẹ wọn jẹ koṣemaani nikan ni aaye yoo wa fun lati maa rin lasiko naa.
O ni wọn fi ọrọ to awọn gomina ipinlẹ gbogbo leti nibi ipade naa lori bi nnkan ṣe n fojojumọ yii sii lori ija gbigbogun tarun COVID-19 pẹlu ipa ti awọn ẹka aladani nko pẹlu idasilẹ eto CACOVID ti wọn gbe kalẹ lati ṣe iranwọ to ba yẹ.
O ni pẹlu bi arun naa ti ṣe tan kalẹ de awọn ipinlẹ marundinlọgbọn bayii, awọn gomina ti fọwọ si pinpin eto idojukọ arun COVID-19 kakiri awọn ipinlẹ lorilẹede yii.















