Sowore: Ilé ẹjọ́ pàṣẹ kí ìjọba àpapọ̀ san ₦1m owó ẹ̀bẹ̀ fún ẹgbẹ́ ajijagbara Sowore, torí ìwọde wọn tí wọ́n dà rú

Oríṣun àwòrán, omoyele sowore
Ilé ẹjọ́ gíga tí ìjọba àpapọ̀ tó wà n'ilu Eko ti pàṣẹ fún ìjọba láti san mílíọ̀nù kan náírà fún ẹgbẹ́ ajijagbara Revolution Now, lórí bo se da ìwọde ẹgbẹ́ náà ru ni ọjọ́ Kàrún oṣù Kẹjọ ọdún 2019.
Agbẹjọro kan tó kopa ninu ìwọde náà, Olukoya Ogungbeje, ló wọ ìjọba lọ sílè ẹjọ́, lórí ẹ̀sùn pé àwọn òṣìṣẹ́ alaabo yín afẹ́fẹ́ tajú-tajú sì òun àti àwọn èèyàn yókù to ń ṣe ìwọde lójú.
Ilé ẹjọ́, tó ní Ogungbeje jàre ẹjọ́ ọhun, tún pàṣẹ fún ìjọba àpapọ̀ láti tọrọ aforijin lọ́wọ́ olupẹjọ náà, lójú ewé ìwé ìròyìn mẹta nilẹ wá.
Adajọ Maureen Onyetenu, tún kéde pé bí ijọba àpapọ̀, láti ipasẹ àwọn Ọlọpaa ṣe da ìwọde náà ru "kò bófin mú, ìwà ìjẹgàba ni, kò bá ìlànà ìjọba alagbada mú, tó sì tún tako àmúlò òfin ilẹ wa".

Oríṣun àwòrán, omoyele sowore
Bákan náà ni adajọ Onyetenu gbà pé, ìjọba fi ẹtọ Ogungbeje to pé ẹjọ́ ní orúkọ àwọn Oluwọde yoku dùn wọn, nítorí abala kejidinlogoji, ikokandinlogoji àti ogójì òfin ilẹ̀ wá ti ọdún 1999, tí fun wọn ní àǹfààní
láti ṣe bẹ́ẹ̀.
Adajọ náà tún korò ojú sì bí awọn agbofinro ṣe gbé àwọn oluwode náà lọpọ yanturu, tá àbùkù wọn, fín afẹ́fẹ́ tajú-tajú sì wọn lójú àti fífi wọn sínú túbú.
Obìnrin kan lu ọ̀gá ọlọ́pàá, ó tún gé ọmọ'ṣẹ́ ọlọ́pàá jẹ nítorí òfin ìséde ní Eruwa

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ọga patapata fun ileeṣẹ ọlọpaa lorilẹ€de Naijiria, Mohammed Adamu ti ke si araalu pe ẹnikẹni to ba ṣiwọ lu ọlọpaa to wa lẹnu iṣẹ rẹ yoo jẹ iyan rẹ niṣu ni.
Ọga ọlọpaaAdamu sọ ọrọ yii ninu esi rẹ lori arabinrin kan to kọlu ọga ọlọpaa kan ni ilu Eruwa ni ipinlẹ Ọyọ.
Ọga ọlọpaa naa ti wọn pe orukọ rẹ ni ASP Adeyẹmọ Ogunyẹmi lo lọ si agbegbe Gbọlaguntẹ Okeọola ni Eruwa iyẹn nijọba ibilẹ Ibarapa East ni ipinlẹ Ọyọ lati lọ fidi ofin konile o gbele mulẹ nibẹ.
- Wo àwọn òfin tí ìjọba ìpínlẹ̀ Eko gbé jáde fún àwọn tó n padà sẹ́nú iṣẹ́ lẹ́yìn k'ónílé o gbélé
- Ẹ bá mi dúpẹ́ lọ́wọ́ Sunday Igboho, Ajimobi, Seyi Makinde àti àwọn ọlọ́pàá fún iranwọ wọn láti rí ìbejì gbà padà
- Ènìyàn 170 tún ti ní ààrùn Covid-19 l'órílẹ̀-èdè Nàìjíríà
- Àwọn èèyàn kò fi bẹ́ ẹ̀ ní ìbálòpọ̀ lásìkò ìgbélé yìí - Iléèṣẹ́ kọ́ńdọ́ọ́mù Durex
Nibẹ ni arabinrin kan ti orukọ rẹ n jẹ Kẹhinde Afolakẹ ti kọluu to si soo laṣọ mu. Igbaju igbamu ni arabinrin naa fi ṣe ọga ọlọpaa naa lọjọ.
Ẹ wo fidio naa:
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Ọga ọlọpaa lorilẹede Naijiria tun ṣalaye siwaju sii pe nigba ti wọn tun ranṣẹ pe arabinrin yii ni ọjọ keji pe ko wa wi tẹnu rẹ lori bi o ṣe kọlu ọga ọlọpaa naa, nṣe lo tun mu awọn ọlọpaa obinrin mejeeji Ripẹtọ Ojola Abiola ati Queen Eguaje ti wọn ran sii lu, koda o tun ge ọkan ninu wọn jẹ pẹlu.

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ọga ọlọpaa lorilẹ-ede Naijiria wa ke si kọmiṣọna ọlọpaa lati ṣe iwadii si iṣẹlẹ naa lati lee gbe igbesẹ to ba ts ni ibamu pẹlu ofin.
Bakan naa lo kan sara si ọga ọlọpaa Adeyẹmọ fun iwa ọmọluabi ati ikora-ẹni-ni-ijanu to hu pẹlu bi obinrin yii ṣe n luu to lọjọ naa.
O ni eyi jẹ apẹrẹ oniruru ikọlu ti awọn ọlọpaa n dojukọ lẹnu iṣẹ wọn
Amọṣa ọga ọlọpaa patapata lorilẹ€de Naijiria ni ko si ẹnikẹni to ba tun ṣiwọ lu ọlọpaa to n ṣe iṣẹ rẹ mọ lorilẹede Naijiria ti ko ni jẹ iyan rẹ ni iṣu.
O ni ko din ni ọlọpaa mẹtadinlọgbọn tawọn eeyan bii arabinrin Afọlakẹ ti kọlu lati igba ti ajakalẹ arun COVID-19 yii ti bẹrẹ, ọpọlọpọ ninu wọn lo si ti di ero ileewosan ninu eyi ti wọn ko tii bọ di bi a ṣe n sọrọ yii.
Laarin asiko ti a n sọrọ rẹ yii naa, ọkọ ọlọpaa bii marundinlogun ni awọn eeyan kan ti bajẹ, pẹlu ileeṣẹ ọẹọpaa meji ni Katsina ati Abia ni awọn eeyan kan ti dana sun.
Òrìṣà ni ìyá mi, kìí ṣe ènìyàn, òun sì ni alátìlẹ́yìn mi - Wòlíì Àrólé

Oríṣun àwòrán, Wolii arole
Ilumọọka adẹrinposonu lórí ayelujara, Oluwatoyin Bayegun, tí ọ̀pọ̀ èèyàn mọ si Wòlíì Arole, tí ṣàlàyé pé ore-ọ̀fẹ́ àti àánú Ọlọ́run ló gbé òun sókè.
O sọ nipa irinajo rẹ láti ilé ẹ̀kọ́ Fáṣítì ti òun ti bẹ̀rẹ̀ awada lórí ayelujara.
Wòlíì Arole, lásìkò to ń bá BBC Yoruba sọ̀rọ̀ ṣàlàyé pé, isẹ awada sise tí gbé òun de ibi gíga, tí òun kò lérò pé òun leè de rí, tí òun ṣi tún mọ àwọn èèyàn ńlá-ńlá pẹ̀lú.
"Mo ti lọ sí ilé aarẹ Nàìjíríà, Aso Rock ni ẹẹmeji, ìyàwó Buhari gan tí fun mi ni àmì ẹyẹ rí, mo sì máa ń lọ silu oyinbo loore koore, láti ipasẹ awada yìí náà ni."
Wòlíì Arole ni "ọpọ ni kò fẹ́ kọ́kọ́ tẹ́wọ́ gba mi nígbà tí mo bẹ̀rẹ̀, wọn ní èdè Yorùbá ni mo ń sọ àmọ́ nígbà tí kìí se àwọn ni Ọlọ́run, mo rí ọ̀nà àbáyọ."
Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ lórí àwọn ìpènijà tó ti là kọjá sẹ́yìn, Wòlíì Arole ni ọjọ́ kan wà tí wọn gba òun sì ẹgbẹ́ níbi ayẹyẹ kan torí pé òun kò tíì ní òkìkí nígbà náà àmọ́ òun dúpẹ́ fún ibi tí Ọlọ́run mú òun de lónìí.
" Ẹ̀jẹ̀ mi ni Jésù, n kò sì tíì dé ibi tó ń mú mi lọ.
Mo sì ń rọ àwọn èèyàn láti mase ro ara wọn pín, tàbí mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá ọkàn wọn nitori ohun tí àwọn ènìyàn ba n sọ.
Ọlọ́run ní kẹ gbé ọkàn yín lé, torí ohun ènìyàn kọ ni ohùn Ọlọ́run."
O wa ṣàlàyé pé "Ọlọ́run ran iya mi sì mi. Òrìṣà ni ìyá mi, kii se ènìyàn. Mo fẹ́ràn ìyá mi gan-an ni,
Kò sì sí Wòlíì Arole lai si ọwọ màmá mi nibẹ.
Ó mọ mi denudenu, to sì fẹ́ràn mi tọkàntọkàn, tí ọkàn mi bá sì rẹ̀wẹ̀sì, ìyá mi lo máa ń tú mi nínú."
Wòlíì Arole ni, ẹ̀bùn ni awada òun, tí ayé fi ń ko o jẹ, òun kii sì roo awada ti tẹ́lẹ̀, kí òun tó sọ síta, èyí tó máa ń jẹ ìtẹ́wọ́gbà lọdọ aráyé.
Arole ni òun kò tíì ní ìyàwó nílé, àmọ́ ẹ̀mí Ọlọ́run ni yóò dárí òun lati darí isẹ àti ìdílé òun, lásìkò ti oun bá ní ìdílé.

Oríṣun àwòrán, Wolii arole
"O wu mi kì ń ṣe sinima àti show tèmi, kí n sì ni studio tèmi náà,
Bẹ́ẹ̀ si ni èdè òyìnbó yọ lẹ́nu mi pẹ̀lú, bí mo ṣe leè ṣe awada ni ojúlówó èdè Yoruba náà ni awada tún dùn lẹ́nu mi ni èdè gẹ̀ẹ́sì, mo sì ni eto fún méjèèjì pẹ̀lú ni ọjọ́ iwájú."
Arole wá rọ àwọn olólùfẹ́ rẹ láti jókòó sínú ilé wọn lásìkò igbele Coronavirus yìí, kí wọn sì mú gbogbo ìmọ̀ràn àti arọwa tí ìjọba ń pa fún wọn lọ nítorí ẹ̀mí kò ní ààrọ̀.
Gbenga Adeboye: Ó tẹ́ bàbá mi lọ́rùn pé ká mu gàárì nílé ju kí ebi pa ará ìta lọ - Ọmọ Gbenga Adeboye
Oluwadamilola Adeboye, tíì ṣe ọmọbìnrin gbajugbaja adẹrinposonu nnì, Gbenga Adeboye, tí sọ àwọn ìrírí tó sì rántí nípa bàbá rẹ̀ tó ti di olóògbé.
Bẹẹ bá gbàgbé, Gbenga Adeboye lo jáde láyé ni ọgbọnjọ oṣù kẹrin ọdún 2003, èyí tó pé ọdún mẹtadinlogun lonii Ọjọ́bọ.
Nígbà tó ń bá BBC Yoruba sọ̀rọ̀ láti sàmì ayajọ ìrántí ikú olóògbé náà, Oluwadamilola ni bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun kéré pupọ nígbà tí bàbá òun kú, àmọ́ òun leè ṣe àpèjúwe rẹ bíi ẹni tó gbé aye ṣe rere.
- Àwọn tó jí ìbejì mi gbé ti pè mí ṣùgbọ́n N50 mílíọ̀nù tí wọ́n ń béèrè pọ̀ ju agbára mi lọ-Akeugbagold
- Yorùbá rẹwà, kọ́ nípa àwọn ọ̀rọ̀ tí ìró ẹnu wọn jọra àmọ́ tí ìtumọ̀ wọn yàtọ̀
- TB Joshua, Apostle Suleman, Odumeje, D.K Odukoya 'ń gun orí òkè àdúrà nítorí COVID-19'-Wò báwọn èèyàn fi wò wọ́n
- Ọwọ́ tẹ̀ èèyàn 65 tó tàpá sí òfin gbéléẹ níbi ayaẹyẹ ọjọ́ ìbí
Oluwadamilola ni òun kò mọ ibi tí bàbá òun ti rí ẹ̀bùn tó ni àmọ́ ó fikùn pé, àwọn ẹ̀bùn rẹ náà kasiara, tó sì tún ya ní lẹ́nu pupọ.
O ṣàlàyé pé nígbà tí bàbá òun wà láyé, ojoojumọ ni ile àwọn máa ń kùn, tí àwọn èèyàn máa ń wa, táwọn yóò sì gba àlejò, tí bàbá òun yóò sì máa ń ṣe awada pẹlu wọn, tí inú àwọn èèyàn yóò sì máa dùn, tí
wọn kò sì ní fẹ́ kúrò nínú ilé àwọn.
"Mo sì lee rántí pé Baba mi jẹ́ èèyàn rere, kò si ẹni ti kii se oore fún, kò si mọ bá ṣe ń kọ láti ṣe nkan fún èèyàn, tí onitọun bá nílò iranlọwọ."
Nígbà miran ti bàbà mi bá dé sílè láti ibi tó ti lọ dá ẹrin posonu, tí a kò si ni oúnjẹ nílé, bí màmá mi bá béèrè pé owó tó mú bọ dà, yóò dáhùn pé òun ti pín owó náà fún àwọn tí ebi ń pá, tí yóò sì ní ká lọ mu
gàárì, òun yóò fún wa lowo lọ́la láti fi ṣe irẹsi."
Ọmọbìnrin Gbenga Adeboye náà fikùn pé, Baba òun ni ifẹ gbogbo ènìyàn bíi ọmọ àti àbúrò rẹ ni, ó sì tẹ bàbá òun lọrun pé ki awọn ẹbi rẹ mu gàárì kí àwọn ará ìta leè rí oúnjẹ jẹ, tàbí rí owó fún àwọn èèyàn.
Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ nípa ohun tí àwọn ẹbí fẹ́ máa fi ṣe irántí Gbenga Adeboye, Oluwadamilola ni "èmi àti màmá pẹ̀lú àwọn àbúrò mi ti pinnu láti máa ṣe atilẹyin fún àwọn osere tó ṣẹ̀ṣẹ̀ ń dìde nilẹ láti ìpilẹ̀ṣẹ̀, ní
kété tí ajakalẹ àrùn Coronavirus bá ti tan."
O fikùn pé, àwọn yóò ṣe iranwọ fún àwọn osere tíátà lobinrin àti àwọn aláìní pẹ̀lú nítorí ohun tó máa ń mú inú bàbá òun dùn nìyẹn, èyí tíì ṣe fífún àwọn aláìní ni oúnjẹ.Bákan náà lo fikun pé ní ọjọ́ iwájú, tí àwọn bá tún ní erongba miran ti àwọn fẹ́ ṣe fún ìrántí Adeboye, àwọn yóò kéte síta.

- Coronavirus: Àwọn ohun tí a kò tíì mọ̀ nípa àrùn Covid-19
- Kí lo mọ̀ nípa fẹntilétọ̀, ohun èlò aṣèrànwọ́ èémí
- Ṣé òògùn Chloroquine lè dènà ààrùn Coronavirus bí?
- Coronavirus tún ti ṣe ọṣẹ́ lórí iṣẹ́ líla ojú ọ̀nà relùwe láti Eko sí Ibadan - Ìjọba àpapọ̀
- Àrùn Coronavirus fa'lẹ̀ya láwọn ìletò aláwọ̀dúdú ní Amẹ́ríkà

Lockdown: Ká ní kò sí kónílé ó gbélé, èmi àti Chioma ì bá ti dàgboro rú- Davido

Oríṣun àwòrán, davido/instagram
Ilumọọka olorin takasufe Davido ti kọ iwe ifẹ kan ṣọwọ si afẹsọna rẹ ati ọmọ wọn ni ọjọ ibi Chioma to n waye lọjọbọ
Eyi wa loju opo Instagram rẹ.
- Wòlíì TB Joshua, Apostle Suleman, Wòlíì Odumeje, Pásítọ̀ D.K Odukoya 'ń gun orí òkè àdúrà nítorí COVID-19'-Wò báwọn èèyàn fi wò wọ́n
- Iléeṣẹ́ aṣọ́bodè yarí, kò gba ìrẹsì tó bàjẹ́ padà lọ́wọ́ Ṣeyi Makinde
- Ọwọ́ tẹ̀ èèyàn 65 tó tàpá sí òfin gbéléẹ níbi ayaẹyẹ ọjọ́ ìbí
- Èèyàn 196 míràn tún ti ní àrùn Coronavirus ní Nàíjírìa
Mo ki obinrin to lagbara kulọ lara awọn ti mo mọ ku ọjọ ibi. Ka ni ko si ofin konile o gbele ni, awa mejeeji o ba ti jaye ori wa daada kaakiri igboro loni
Iyawo mi tootọ, ayẹyẹ ọjọ ibi rẹ yoo larinrin bi iwọ pẹlu ti ṣe mu ọpọlọpọ ayọ wọ inu aye mi.
O ti le ni ọdun meji bayii ti Davido ati Chioma ti bẹrẹ irinajo ifẹ wọn ti Eleduwa si ti fi ọmọkunrin kan tawọn lọrẹ.
Laipẹ yii ni Chioma bọ lọwọ arun Coronavirus lẹyin ọpọlọpọ ọjọ ti aisan naa fi daa wolẹ.

- Coronavirus: Àwọn ohun tí a kò tíì mọ̀ nípa àrùn Covid-19
- Kí lo mọ̀ nípa fẹntilétọ̀, ohun èlò aṣèrànwọ́ èémí
- Ṣé òògùn Chloroquine lè dènà ààrùn Coronavirus bí?
- Coronavirus tún ti ṣe ọṣẹ́ lórí iṣẹ́ líla ojú ọ̀nà relùwe láti Eko sí Ibadan - Ìjọba àpapọ̀
- Àrùn Coronavirus fa'lẹ̀ya láwọn ìletò aláwọ̀dúdú ní Amẹ́ríkà

Coronavirus in Osun: Iṣẹ́ labiyamọ ń ṣe o, Davido pariwo síta lórí bó ṣe ń tọ́jú ọmọ tí Chioma fi sílẹ̀ fún

Oríṣun àwòrán, davido
Gbajugbaja akọrin takasufe ni, David Adeleke ti ọpọlọpọ mọ si Davido ti pariwo sita pe nnkan ko rẹrin lori titọju ọmọ ti oun ti iyawo rẹ Chioma bi fun latigba ti iya rẹ ti wa ni igbele iyasọtọ.
Chioma, iyawo Davido ko arun Coronavirus eleyi ti ọkọ rẹ, Davido kede faye ni ọsẹ to kọja.
Ninu ọrọ kan to fi sita loju opo twitter rẹ Davido lọgun pe iṣẹ l'abiyamọ n ṣe.
Lẹyin ti ayẹwo fihan pe Chioma ti ko arun Coronavirus, igba meji ọtọọtọ ni Davido ni oun ti ṣe ayẹwo lati lee mọ boya oun ni arun naa tabi oun ko ni.
Àwọn olùgbé ìlúu Abidjan ló kò àrùn Coronavirus wọ Ọ̀ṣun-Gómìnà Oyètọ́lá
Gomina ipinlẹ Ọṣun, Alaaji Adegboyega Oyetọla ti ke gbajare sita pe awọn abọde lati orilẹede Côte d'Ivoire ni wọn jẹ ki ajakalẹ arun Coronavirus tubọ gogo sii ni ipinlẹ naa.
Ninu ọrọ to ba BBC News Yoruba sọ lori ẹrọ ibanisọrọ lẹyin ti ajọ to n gbogun ti ajakalẹ arun tun kede eeyan mẹsan miran pẹlu arun Korona ni ipinlẹ Ọṣun lọjọru, Gomina Oyetọla ṣalaye pe arun Korona ki ba ti burẹkẹ to bayii kani ijọba apapọ tete ti gbogbo ẹnuibode ni ki wọn si paṣẹ konileogbele fun gbogbo ọmọ orilẹede Naijiria.
Gomina Oyetọla ṣalaye siwaju sii pe, awọn ọmọ ipinlẹ naa ti wọn n ti orilẹede Côte d'Ivoire bọ wa sile ni wọn ko arun naa dani to fi di pe o tubọ peleke sii nipinlẹ naa.
O wa rọ awsn eeyan ipinlẹ Ọṣun lati fidimọle gẹgẹ bi aṣẹ ti ijọba pa lati lee wagbo dẹkun si wahala yii.
Bakan naa ni o fi to wa leti pe lọna ati lee dẹkun ọwọja ebi ati inira lasiko aṣẹ konileogbele naa, ijọba oun ti gbe awọn igbesẹ ti yoo bu omi tu araalu lara bii sisanwo oṣu fun awọn oṣiṣẹ ki wọn to gbe aṣẹ naa kalẹ ati idasilẹ igbims majẹobajẹ kan lori ọna ati gbogun ti arun naa ati lati mu irọrun ba araalu lasiko ti wọn ba fi n baa wọ iyaaja.
Ẹkunrẹrẹ wa ninu ohun ti a ka silẹ loke yii.

Coronavirus in Nigeria: Davido ní àyẹ̀wò kejì fún àrùn Coronavirus fihàn pé ṣáká lara le

Oríṣun àwòrán, Davido/instagram
Gbajugbaja akọrin takasufe, Divid Adeleke ti ọpọ eeyan mọ si Davido tun ti wẹ yan kainkain lọwọ arun coronavirus.
Ọpọ ẹnu lo ti n kun Davido lẹyin ti iroyin jade pe ọpọ awọn eeyan to sun mọọ lo ti n ni arun yi lara.
Ni ọjọ diẹ sẹyin ni Davido funrarẹ gbe iroyin jade pe iyawo oun, Chioma ti ko arun Coronavirus, bakan naa si ni gomina Seyi Makinde pẹlu kede pe oun pẹlu ti ni arun naa lẹyin ọjọ diẹ to gbalejo Davido ni ile ijọba nilu Ibadan.
Ninu atẹjade kan to fi sita loju opo twitter rẹ ni ọsan ọjọ Ọjọru, Davido ni oun ti tun ayẹwo arun Coronavirus ṣe o, ṣaka bayii si ni ara oun ya.

Coronavirus in Nigeria: Wo àwọn ìrìnàjò tí gómìnà Makinde rìn kí èsì àyẹ̀wò rẹ̀ tó jáde

Oríṣun àwòrán, SEYI MAKINDE
Gomina ipinlẹ Ọyọ, Onimọẹrọ Ṣeyi Makinde kede ni aṣalẹ ọjọ Aje pe oun ti ko arun Coronavirus ti o n ja kale-ka'ko bayii.
O fi si oju opo twitter rẹ pe esi ayẹwo oun ti de ko si si ẹja n bakan kankan lori rẹ nitori ẹja lo ba de.
Lẹyin eyi ni o ṣalaye pe gbogbo awọn to ti ni nnkan n ba oun ṣe laarin asiko ti oun fi lọ sibi ipade igbimọ ọrọ aje orilẹede Naijiria si ọjọ ti oun bẹrẹ igbele ni wọn ti n wa; koda iroyin kan tilẹ ss pe gbogbo awọn to baa da nnkan pọ laarin asiko naa, paapaa awọn kọmiṣọna atawọn amugbalẹgbẹ rẹ gbogbo ni wọn ti wa ni igbele bayii lati lee mọ boya awọn naa ko abi rara.

Oríṣun àwòrán, SEYI MAKINDE
Nibayii, BBC News Yoruba ṣe atupalẹ bi irinajo Gomina Seyi Makinde ṣe lọ laarin akoko naa ati awọn eeyan to ṣeeṣe ki wọn ti ko arun yii lati ara rẹ.
Ẹ maa gbagbe pe eyi ko tumọ si pe gbogbo awọn eeyan to wa nibi eto wọnyii lo ti koo, ṣugbọn iwadi ati ayẹwo to gbọngbọn nikan lo lee fi idi eyi mulẹ.
Fun apẹrẹ, gomina Makinde ṣalaye ninu atẹjade to fi sita pe asiko kan naa ni esi ayẹwo oun ati ti akọwe ijọba ipinlẹ naa, arabinrin Olubamiwo Adeosun de. Esi ti gomina lo jasi bẹẹni ti ti akọwe ijọba ipinlẹ naa si ja si bẹẹkọ.
Idi ti awọn onimọ maa fi n ṣe ato irinajo ẹni to ba ni arun yii ni lati mọ ibi ti wọn lee wa awọn to lee ti koo lati ara wọn si.

















