Sanusi Lamido Sanusi: Ashraf, ọmọ Lamido Sanusi ní ìṣọ̀kan ṣì wà nínú ẹbi Emir àná náà pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n là kọjá

Oríṣun àwòrán, Governor kaduna
Laipẹ yii ni iroyin kan wọ ilu ti gbogbo ilu si mi titi.
Iroyin naa ni ti irọloye Emir ti ilu Kano, Sanusi Lamido ti ijọba ipinlẹ Kano kede lẹyin ọpọlọpọ itaporogan pẹlu gomina ipinlẹ naa, Abdullahi Ganduje.
Amọṣa lọwọ yii iroyin ayọ ti wọle tọ gomina tẹlẹ fun banki apapọ orilẹede Naijiria ọhun pẹlu ọkan lara awọn iyawo rẹ, Saadatu to bi ọmọ tuntun bayii.
- Olorì Aláàfin, Memunat Adeyemi, fohùn ránṣẹ́ sí ikú bàbá yèyé
- Atẹ́gùn òjò rán ọ̀pọ̀ lóko àdánù nílùú Ìbàdàn, aráàlú gbarata
- Wo àwọn ǹkan tí a mọ̀ nípa àgbo tí orílẹ̀-èdè Madagascar ṣe fún Covid-19
- Ẹ yé tako ìjọba lórí iléèjọ́sìn títì pa, ẹ jọ̀wọ́ ṣọ́ọ̀ṣì yín fún ìtọ́jú àwọn tó lárùn coronavirus- Tunde Bakare
Ọkan lara awọn ọmọ ọkunrin Emir tẹlẹ fun ilu Kano naa, Ashraf to fi idi ibi naa mulẹ ṣalaye pe ọmọbinrin ni Mallam Sanusi Lamido Sanusi bi.
O fi kun un pe iyawo Sanusi Lamido keji torukọ rẹ n jẹ (Goggo) Mamie lo bẹ Emir ana naa pe ko sọ ọmọ ọhun ni orukọ iyawo rẹ akọkọ, iyẹn Yaya (Giwa) ti wọn ni o tọju Saadatu`nigba to wa ninu oyun.
Halimatu Saadiyya ni o kede pe wọn sọ ọmọ naa.
Ọba Gbadamọsi: Olúwòó, ọ̀pọ̀ ọmọ Naijiria fi ìkíni ránṣẹ́ si Ọlọ́fà fún ayẹyẹ ọdún mẹwàá lórí oyè

Oríṣun àwòrán, Facebook
Oluwo ilu Iwo Oba Abdulrasheed Akanbi ti darapọ mọ awọn ọmọ Yoruba to n fi ikini ransẹ si Ọlọfa ilu Offa Oba Mufutau Gbadamosi Oloyede to pe ọdun mẹwa lori apere.
Ninu ọrọ to fi ransẹ si ileesẹ BBC Yoruba, Oba Abdulrasheed sapejuwe Ọlọfa gẹgẹ bi ọba to se fi yangan lawujọ awọn ọba ilẹ Yoruba.
O ni gbogbo isesi ọba Mufutau lo safihan rẹ gẹgẹ bi awokọse daada ati ẹgbọn fun oun laarin awọn ọba ilẹ Yoruba.
- Iṣẹ́ amòfin tí mo kọ́ ni Fáṣítì kò mú owó wọlé fún mi bíi iṣẹ́ tíátà - Femi Adebayo
- Àjọ NCDC kéde ènìyàn 381 míràn tó ní ààrùn Covid-19 l'órílẹ̀-èdè Nàìjíríà
- Àwọn Dókítà fárígá ní ìpínlẹ̀ Ondo, wọ́n ní kí Gómìnà san owó oṣù mẹ́ta tó jẹ wọ́n!
- Gbajúmọ̀ agbábọ́ọ̀lù ni ǹ bá jẹ́, ká ní ń ko ṣeré tíátà - Bàbá Wande O wa se ladura ki ọba naa pẹ lori oye ninu ọla nla ati alaafia ti yoo ma fi dari awọn eeyan rẹ.

Oríṣun àwòrán, Oluwo/facebook
Arun Coronavirus sebi ẹni ké ayẹyẹ ọdun kẹwa Ọlọfa kuru sugbọn
Ni ọjọ Kẹjọ osu kaarun ọdun 2010 ni Oba Mufutau gun ori itẹ awọn baba rẹ gẹgẹ bi ọlọfa ikẹrinlelogun ilu Offa.
Lọpọ ibi ti iru nkan ayọ bayi ba ti waye ni awọn ara ilu ti ma n peju si aafin ọba lati ba ọba yọ ku orire.

Oríṣun àwòrán, Oluwo/facebook
Sugbọn pẹlu bi arun Coronavirus ti se gbode kan bayi,apejọ ko ni le waye bi yoo ti se wu Ọlọfa tabi awọn ara ilu naa.
Amọ sa loju opo ayelujara ati lori ẹrọ redio nise ni awọn ọmọ ilu naa n gbe orisirisi ikini ati eto kalẹ lati fi ba ọba yọ.
Ni ọjọ Kẹjọ osu kaarun ọdun 2010 ni wọn jawe oye fun ọba Mufutau ti Gomina igba naa nipinlẹ Kwara Bukola Saraki si gbe ọpa asẹ fun un ni ọjọ Kẹsan osu kaarun ọdun 2010.
Òṣìṣẹ́ ààfin mi tí kò bá lo ìbòmú yóò pàdánù isẹ́ rẹ̀-Oluwo
Oluwo pàṣẹ fáwọn òṣìṣẹ́ ààfin rẹ̀ láti lo ìbòmú tàbí kí wọ́n pàdánù iṣẹ́ wọn

Oríṣun àwòrán, Emperor Abdulrasheed Adewale Akanbi Telu 1
Oluwo ti ilu iwo, Ọba Abdulrasheed Akanbi ti leri leka pe lile loun yoo le oṣiṣẹ aafin rẹ ti ko ba lo ibomu gẹgẹ bi ijọba ipinlẹ Ọṣun ti ṣe paa laṣẹ.
Ninu Atẹjade, Oluwo ṣalaye pe lilo ibomu yoo pinwọ itankalẹ arun Coronavirus ni ipinlẹ Ọṣun ati jakejado orilẹede NAijiria.
- N kò ni nkan kan sọ lórí fídíò to gba ayélujára kan pé mo ń we igbó, ẹ mú ẹnu kúrò nibẹ - Oluwo
- Ẹ wo àwọn gbajúmọ̀ òṣèré tíátà tó jogún eré ṣíṣe lọ́dọ̀ òbí wọn
- Owó gọbọi wá nídìí oko-owo igbó gbingbin, Ìpínlẹ̀ Ondo kò ní pẹ gba àṣẹ láti gbin - Akeredolu
- Gómìnà Ṣèyí Mákindé ó ní ìdí tí òun kò fi leè ti ìpínlẹ̀ Ọ̀yọ́ pa nítorí COVID-19
Oluwo ni, "Arun Coronavirus kii ṣe arun ti eeyan n fi ṣere rara. Tootọ ni, o si n pani bi ọgan ni."
Kabiyesi Oluwo fi kun un pe, gbogbo awọn oloye, ọmọọba atawọn oṣiṣẹ laafin ni wọn gbọdọ maa lo ibomu atipe eyikeyi ninu awọn oṣiṣẹ laafin ti oun ba ri nigboro tabi to wa laafin lai wọ ibomu facemask yoo dagbere fun iṣẹ rẹ.
Bakan naa lo tun ke sawọn eeyan ilu Iwo lati mu lilo ibomu lọkunkundun pẹlu arọwa sawọn to n ni afihan awọn aisan to rọ mọọ lati lọ ṣe ayẹwo ara wọn nitori arun naa kii ṣe opin ẹmi.

- Coronavirus: Àwọn ohun tí a kò tíì mọ̀ nípa àrùn Covid-19
- Kí lo mọ̀ nípa fẹntilétọ̀, ohun èlò aṣèrànwọ́ èémí
- Ṣé òògùn Chloroquine lè dènà ààrùn Coronavirus bí?
- Coronavirus tún ti ṣe ọṣẹ́ lórí iṣẹ́ líla ojú ọ̀nà relùwe láti Eko sí Ibadan - Ìjọba àpapọ̀
- Àrùn Coronavirus fa'lẹ̀ya láwọn ìletò aláwọ̀dúdú ní Amẹ́ríkà

Oluwo: Ọ̀pọ̀ òjò lo ti rọ láàrin èmi àti Olúwòó, olorì Chanel sọ̀rọ̀ ǹkan ti oju rẹ ri ni Iwo

O tun ti n rugbo bọ o. Laarin Olori ana ni aafin Iwo, Olori Chanel Chin
Ninu ifọrọwerọ kan to ṣe eleyi to n ja ranyinranyin lori afẹfẹ bayii, olori ana naa ni oun ti ba oluwo lori obinrin ọmọ ọdun mẹtala kan ri ti wọn n lajọṣepọ lori ibusun toun ati Oluwo n sun.
Olori Channel ni awijare ti Kabiyesi Oluwo fun oun ni pe Ọbalaye loun, gẹgẹ bi aṣa ati iṣẹṣe, oun lanfani lati fẹ iye obinrin to ba wu oun.

Oríṣun àwòrán, Oluwo/instagram
Bi o tilẹ jẹ wi pe ileeṣẹ BBC News Yoruba ti ṣaaju bi Kabiyesi Oluwo, Ọba Abdulrasheed Akanbi leere ọrọ nipa aawọ aarin oun ati Olori rẹ ana, ti Kabiyesi si fesi pe oun ko ṣetan lati sọ ohunkohun lori rẹ.
Ninu ifọrọwerọ to n kiri lori ayelujara naa, Olori Chanel Chin ṣalaye pe ọpọ igba ni oun ati Kabiyesi Oluwo ti fa wahala lori ọrọ yii ṣugbọn to jẹ pe lilu ati igbaju igbamu lo maa n kẹyin irufẹ edeaiyede bẹẹ fun oun.
Ni oṣu kejila ọdun 2019 ni Kabiyesi Oluwo, Ọba Abdulrasheed Akanbi kede pe ipinya ti de laarin oun ati Olori oun, Channel ti igbeyawo awọn si ti tuka.












