Bàbá ìyàwó ní ìfẹ́ wà láàrin ọmọ́ òun àti ọkọ rẹ̀, inú àwọn sì dùn sí ìgbeyàwó náà

Ọwọ ọkọ ati iyawo

Oríṣun àwòrán, Getty Images

Ọdọmọbinrin ọmọ ọdun mẹrindinlogun kan, Fatima Abubakar ti padanu ẹmi rẹ lẹyin to re sinu kanga omi nigba ti igbeyawo rẹ ku ọla.

Iṣẹlẹ naa la gbọ wi pe o waye ni ilu Gajaja, ijọba ibilẹ Danbatta, nipinlẹ Kano.

Baba Fatima, Ọgbẹni Abubakar sọ fun BBC pe, iṣẹlẹ buruku naa waye lasiko ti ọmọbinrin naa ati awọn ọrẹ rẹ nlọ fun ayẹyẹ alẹ omidan nile anti rẹ kan l'ọjọru.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

"Niṣe lo duro l'ẹgbẹ kanga naa, ko to o di wi pe o fi ẹsẹ kọ, to si ṣubu sinu kanga.

Ọjọ keji, to jẹ Ọjọbọ lo yẹ ki ayẹyẹ igbeyawo laarin oun ati ọkọ afẹsọna rẹ o waye.

Baba Fatima ṣalaye pe, inu ọmọ oun dun si igbeyawo naa, ati pe ifẹ wa laarin oun ati ọkọ afẹsọna rẹ.

O sọ pe amọ o ṣeni laanu pe inu ibanujẹ ni awọn alejo to yẹ ko wa ba oun yọ ayọ igbeyawo ọmọ oun wa bayii.

Inu ibanujẹ ni ọkọ afẹsọna naa wa, ti ko si le ba ẹnikẹni sọrọ lori ẹrọ ibaraẹnisọrọ.