Osun Accident: Èèyàn méjì pàdánù ẹ̀mí wọn nínú ìjàmbá ọkọ̀ tó wáyé ni Osun

Oríṣun àwòrán, @FedfireC
Ko din ni eeyan meji to jẹ Ọlọrun nipe ninu ijamba ọkọ to waye lẹyin ti ọkọ agbepo kan fori sọ ọkọ to ko ẹja ni ipinlẹ Osun.
Iṣẹlẹ ọhun waye ni ni nnkan bi aago mọkanla owurọ lọjọ Ẹti loju ọna marosẹ Gbogan si Ife, ni ijọba ibilẹ Ayedaade, ni ipinlẹ ọhun.
Iroyin ni iṣẹlẹ naa da sunkẹrẹ-fakẹre ọkọ silẹ loju ọna naa nigba ti ina ọhun bẹrẹ si n jo.
Gẹgẹ bi ohun ti awọn oṣoju mi koro sọ, awakọ epo naa ati ẹnikeji rẹ gbẹmi mi nigba ti awakọ ẹja ti wọn fori sọra moribọ.

Oríṣun àwòrán, @FedfireC
Agbẹnusọ ileeṣẹ panapana to wa ni ilu Osogbo, Adijat Basiri, sọ fun awọn akọroyin pe, ni kete ti awọn ara ilu fi ọrọ naa to wọn leti ni awọn oṣiṣẹ ileeṣẹ ọhun lọ sojuko naa ti wọn si pa ina ọhun.
- Géńdé agbébọn yabo àgọ́ ọlọ́pàá n‘Ibadan, ẹ̀mí ọlọ́pàá kan bọ́
- Ọba Ilorin ló pàṣẹ pé kí ń padà sọ́dọ̀ ọkọ mi - Risikat olójú búlúù
- NCDC kéde èèyàn 340 míràn tó ṣẹ̀ṣẹ̀ lùgbàdì Covid-19 ní Nàìjíríà
- A fí ara mọ́ ìdájọ́ ikú Sharia tó tọ́ sí Olórin Yahaya- ẹgbẹ́ Amòfin Mùsùlùmí ẹ̀ka ìpínlẹ̀ Kano
- Coronavirus bí èso rere nílẹ̀ Adúláwọ̀, wo díẹ̀ lára èso náà...
Basiri sọ pe bi awọn awọn ọkọ memeji ṣe fori sọra lo fa ṣababi ina to ṣeyọ.
O ni "Eeyan meji lo padanu ẹmi wọn ninu iṣẹlẹ naa ṣugbọn a ko tii le sọ awọn ileeṣẹ to ni awọn ọkọ mejeji."









