Lagos-Ibadan Train: Iléeṣẹ́ Rélùwéè ní ìgbà 16 ní àwọn ọkọ̀ ojú irin náà yóò máa rìn lójúmọ́

Oríṣun àwòrán, @Official_NRC
Igba ọtun ati eto idẹrun ti de fun awọn arinrin ajo lati ilu Eko si Ibadan, pẹlu ọkọ oju irin reluwe ti yoo bẹrẹ isẹ losu to n bọ.
Atẹjade kan ti ileesẹ Reluwe nilẹ wa fisita loju opo Twitter rẹ lọjọ Ẹti kede pe ọkọ reluwe mẹrindinlogun lo ti de bayii.
Ileesẹ reluwe ilẹ wa ni awọn ọkọ reluwe naa, ti yoo maa na Eko si Ibadan, ni yoo maa rin ni igba mẹrindinlogun lojoojumọ.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post
Atẹjade naa fikun pe osu Kẹsan to n bọ ni wọn yoo si eto irinna reluwe lati ilu Eko si Ibadan, ti ara yoo si tu awọn arinrinajo to fẹ lọ silu Ibadan lati Eko.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Géńdé agbébọn yabo àgọ́ ọlọ́pàá n‘Ibadan, ẹ̀mí ọlọ́pàá kan bọ́
- Ọba Ilorin ló pàṣẹ pé kí ń padà sọ́dọ̀ ọkọ mi - Risikat olójú búlúù
- A fí ara mọ́ ìdájọ́ ikú Sharia tó tọ́ sí Olórin Yahaya- ẹgbẹ́ Amòfin Mùsùlùmí ẹ̀ka ìpínlẹ̀ Kano
- Wo bí ọkùnrin ọmọ òrukàn yìí ṣe ń ran àwọn opó tí ọkọ wọn kú sójú ogun lọ́wọ́
- Deji Akure pàṣẹ kí wọ́n ti gbogbo ọjà pa fún ọjọ́ méjì, ohun tó fàá nìyí
- Wo ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Saka, Sunkanmi Omobolanle àtàwọn òṣèré sinimá míràn lọ́sẹ̀ yìí
Bakan naa ni eto irinna oju irin yoo tun bẹrẹ lati ilu Itakpe lọ si Warri de Ore, laipẹ laijinna si ni wsn yoo si eto naa.








