Hannah Olateju: Nigba miiran, ọkan awọn eeyan kii balẹ lati wa pẹlu mi
Ninu fidio oke yii, ọmọ ogún ọdún ni Hannah Olateju to jẹ ẹni to ge lapa ati ẹṣẹ ṣugbọn irinisi rẹ ko lee fun un yin lanfani ati foju tẹmbẹlu rẹ tabi wo o tika tẹ̀gbin.
Hannah ni nigba toun wa lọmọ ọdun meji ni oun ti kọkọ ni aisan yinrunyinrun ṣugbọn nigba yẹn gan oun a maa jẹ ọmọ oninu didun.
"Mo rántí bí mo ṣe máa ń sá kiri bí adìyẹ ní kékeré, mo ní ìgboyà mo sì dá ara mi lójú".
Gbajugbaja ni Hannah jẹ́ lori ayelujara eyi tumọ si wi pe ko tilẹ tiju ipo to wa rara debi ti yoo jẹ ko di i lọwọ ohun to lee da laye.
"Àwọn èèyàn kìí mọ ọ̀rọ̀ọ́ sọ sí ẹni tó gé lápá, lẹ́sẹ̀ bí èmi. Bí mo tilẹ̀ gé lápá àti ẹsẹ, èmi ni mo máa ń kí àwọn èèyàn láti fihàn pé ǹkan ń lọ dáadáa".
Hannah fọwọ sọya sọ wi pe "ìyàtọ̀ tó kàn wà láàrin èmi àtiyín ni pé ẹsẹ̀ àti ọwọ́ tiyín ju tèmi lọ".
- Ọ̀rọ̀ di bóò lọ yà á mi l'Abuja lẹ́yìn táwọn kan ní àwọn ti lùgbàdì áárùn Coronavirus
- Báyìí ni ìgboro Eko ṣe rí lẹ́yìn tí ìjọba fòfin de Keke àti Okada
- Ìdí tí Ààrẹ Trump fi dínà mọ́ Nàìjíríà àtí orílẹ̀èdè márùn ún míì láti má wọ Amẹ́ríkà
- Corovavirus: Àjọ WHO tí bẹ̀rẹ̀ ètò láti ran àwọn orílẹ́-èdè Afrika lọ́wọ́
- Femi Adebayo, Bimbo Akinsanya sọ ìdí tí wọ́n ṣe fi ìgbéyàwó wọn àkọ́kọ́ sílẹ̀ kó tó bọ́ sórí
- RCCG: Pásítọ̀ Adeboye ṣáájú ìwọ́de àdúrà CAN lòdí sí ìpànìyàn ní Nàìjíríà
- Ọmọ ìjọ 20 kú bí wọ́n ṣe tẹ̀ wọ́n pa níbi ìsọjí ìtagbangba










