Pastor Adeboye ṣáájú ìwọ́de àdúrà lòdí sí ìpànìyàn ní Nàìjíríà

Awọn ọmọ ijọ Redeem

Oríṣun àwòrán, @rccg_pr

Jakejado orilẹede Naijiria lowurọ yii ni ijọ irapada ti gbogbo eniyan mọ si Redeemed Christian Church of God ṣe iwọde ifẹhonu han lodi si iṣekupani to n di lemolemo lorilede Naijiria.

Laipẹ yii ni awọn ajinigbe ṣekupa alaga ẹgbẹ awọn ọmọlẹyin Kristi ni iha Guusu Naijiria. Eyi ati ọpọlọpọ awọn ọmọ Naijira to n la ijinigbe ati iṣekupani kọja lo mu ki ẹgbẹ ọmọlẹyin Kristi lapapọ lorilede Naijira kede iwọde yii.

Ijọ Redeem

Oríṣun àwòrán, Isaac Jeremiah

Àkọlé àwòrán, Ijọ Redeem, Chapel of Life, Abuja
Awọn ọmọ ijọ Redeem
Àkọlé àwòrán, Ijọ Reedeem, Ọgba Eko

Pasitọ ijọ Redeem, Enoch Adejare Adeboye nibi isin idupẹ oṣu keji ọdun eyi to waye ni iya ijọ Redeem to wa ni Ebute Meta, ipinlẹ Eko sọ wi pe "gbogbo ẹni ti wọn pa lorilẹede Naijiria yala Kristẹni tabi Musulumi gbudọ ṣe pataki si wa".

Àkọlé fídíò, Prophecy 2020: Adeboye àti Ayọdele sọ nípa ọjọ́ ìwájú 2020
Awọn ọmọ ijọ Redeem

Oríṣun àwòrán, @yemility007

Àkọlé àwòrán, Ijọ Redeem, King's Court, Eko

Lẹyin ti Adeboye le adura fun aabo, ipamọ ati alafia fun orilẹede Naijiria ninu isin naa tan lo mẹnu ba ọrọ awọn ti wọn n ṣekupa lorilẹede yii.

Latari eyi oni ẹgbẹ CAN ti kede pe ki gbogbo Kristẹni ṣe iwọde lodi si i eyi to pe ni "irin adura(prayer walk)".

Ninu iwọde ọhun, Pasitọ Adeboye lo ṣaaju awọn ọmọ ijọ rẹ pẹlu patako ti wọn gbe lọwọ pẹlu akọle to sọ wi pe "Gbogbo kan se iyebiye si Ọlọrun".

Ijọ RCCG Abba Father, Ado Ekiti

Oríṣun àwòrán, RCCG Abba Father, Ado Ekiti

Awọn ọmọ ijọ Redeem

Oríṣun àwòrán, Isaac Jeremaih

Àkọlé àwòrán, Ijọ Redeem, Chapel of Life Area 1, Abuja
Awọn ọmọ ijọ Redeem

Oríṣun àwòrán, RCCG Jesus House

Àkọlé àwòrán, Ijọ Redeem, Jesus House Parish, Eko
RCCG TEAP, Abuja

Oríṣun àwòrán, RCCG TEAP, Abuja