Ṣé lóòtọ́ ni Ààrẹ ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin, Akpabio ṣubú tó sì dákú níbi ayẹyẹ ọjọ́ ìbí rẹ̀?

Godswill Obot Akpabio

Oríṣun àwòrán, Godswill Obot Akpabio

Aarẹ ile igbimọ aṣofin, Godswill Akpabio, ti sọrọ soke lẹyin iroyin to ni o ṣubu lulẹ nibi ayẹyẹ ọjọ ibi rẹ.

Akpabio ni ṣe lo rẹ oun, ati pe oun ti n ba aisan iba finra ṣaaju iṣẹlẹ naa.

Ṣaaju ni iroyin ti kọkọ sọ pe Akpabio ṣubu, to si daku lasiko to n sin Aarẹ Bola Tinubu jade ninu gbọngan ile itura Transcorp Hilton to wa nillu Abuja, nibi ti ayẹyẹ naa ti waye.

Nigba to n ba awọn akọroyin sọrọ nile igbimọ aṣofin Abuja lọjọ Ẹti, Akpabio ko sọ boya lootọ ni oun ṣubu tabi daku.

Amọ o fidi rẹ mulẹ pe aisan iba ba oun finra, aisan naa si ti wọ oun lara latari wahala ti oun n ṣe.

O ni “ohun to ṣẹlẹ lẹyin ayẹyẹ naa ṣafihan ifẹ ti a ni si ara wa gẹgẹ bii ọmọniyan.

“Mo lọ sile, mo pe dokita mi, o si jẹ ko ye mi pe mo ni aisan iba lara, pẹlu gbogbo wahala ti mo ti ṣe.

“Ko si ẹni ti ko le ṣaarẹ, ẹ jọwọ ẹ maa mu omi lojojumọ ko ma ba a rẹ agọ ara yin.

“Eyii n tumọ si pe a o tẹsiwaju lati maa ṣe iṣẹ wa.

“Mo fẹ fi akoko yii da awọn ọmọ Naijiria loju pe digbi ni ile igbimọ aṣofin wa, a o si maa tẹsiwaju ninu iṣẹ wa gẹgẹ bii aṣofin.”