Ammended Terrorism prevention Act: Ẹ̀wọ̀n gbére tàbíì dájọ́ ikú fún ajínigbé títí ẹ̀mí yóò fi bọ́ ni àbájadé òfin túntun lórí ìjínigbé

Oríṣun àwòrán, Senate Nigeria
Ilé aṣòfin Nàìjíríà buwọ́lu ẹ̀wọ̀n ọdún 15 fún ẹnikẹ́ni tó bá san owó fún ìtúsílẹ̀ ẹnikẹ́ni láhámọ́ ajínigbé tàbí agbésùnmọ̀mí
Ilé aṣòfin Nàìjíríà buwọ́lù ìyípadà òfin tó dé ijinigbe, kókó pàtàkì rèé nínú rẹ̀Bí o bá san owó fún ìtúsílẹ̀ ẹnikẹ́ni láhámọ́ ajínigbé, ẹ̀wọ̀n ọdún 15 wà níkàlẹ̀ fún ọ
Ijinigbe ti di ọgbẹ ọkan nla fawọn araalu ni Naijiria sugbọn sisan owo lati doola awọn ti wọn ji gbe ti wa tun dakun isoro araalu.
Fawọn alaburu ajinigbe pawo yi, ọna kan gbogi leleyi jẹ lati ri owo lọna aitọ.
- Ìgbẹ́jọ́ Ilànà Ọmọ oodua àti Náìjíríà ti bẹ̀rẹ̀ nílé ẹjọ́ ní Ekiti
- Látàri ìjà Russia àti Ukraine, Bí a ṣe fẹ́ dènà ìyàn oúnjẹ ní Naijiria rè é- Buhari
- Kìí ṣe nǹkan abàmì bí Alaafin, Soun àti Olubadan ṣe papòdà lèralèra - Elebuibon
- NDLEA sàmì sí ilé Abba Kyari mẹ́fà àti ilé ìtàjà tó ní ṣọ́ọ̀bù 100 ní Maiduguri fún ìwádìí
- Bí o bá san owó fún ìtúsílẹ̀ ẹnikẹ́ni láhámọ́ ajínigbé, ẹ̀wọ̀n ọdún 15 wà níkàlẹ̀ fún ọ
- 'Ètò ayẹ́yẹ́ ìsìnkú Oba Lamidi Adeyemi kòí tíì wáyé, àfọ̀mọ́ Aàfin ń lọ lọ́wọ́'
Eleyi jẹ nkan to kan awọn asofin lominu ti wọn si kede atunse ofin to dena iwa igbesunmọmi taa mọ si Terrorism (Prevention) Act, 2013.
Eyi to jẹ iyipada tuntun ninu ofin yi ni fifofin de ki eeyan san owo fawọn ajinigbe.

Oríṣun àwòrán, others
Ki ni ohun to wa ninu iyipada ofin yi?
Igbimọ ile asofin agba to n ri si ọrọ ẹka idajọ ẹtọmọniyan ati ọrọ to ni se pelu ofin lo daba iyipada lori ofin to wa lori ijinigbe tẹlẹ.
Sẹnẹtọ Opeyemi Bamidele si lo lewaju igbimọ yi to si ni:
"Idi ta fi mu iyipada ba ofin yi ni lati dẹkun ọwọja ijinigbe ati sisan owo fawọn ajinigbe ni Naijiria''.
Lẹyin ti igbimọ se agbekalẹ iwadii wọn niwaju ile asofin agba,ile buwọlu atunto ofin yi lọjọru.
Awọn koko pataki to wa ninu iyipada ofin yi:
•ẹwọn gbere fun ajinigbe ti ile ẹjọ ba da lẹbi
•bi ẹni ti wọn jigbe ba ku, idajọ iku ni fun ajinigbe
•ofin yi gbe aba ẹwọn ọdun mẹẹdogun silẹ fun ẹnikẹni to ba san owo idoola fun ajinigbe
Ninu gbogbo iyipada si ofin yi taa ka silẹ eleyi to mu iriwisi wa ni ti ẹwọn ọdun mẹẹdogun fun ẹni to san owo lati fi doola mọlẹbi tabi ọrẹ lọwọ ajinigbe.
Eleyi n waye pẹlu bawọn eeyan kan se n sọ pe sisọ sisan owo idoola di ẹsẹ labẹ ofin yoo tunbọ mu inira ba awọn ti eeyan wọn ba wa lahamọ ajinigbe.
Ibagbọ ọpọ ni pe ijọba ko se ohun to yẹ lati jẹ ki ijinigbe ma tiẹ waye rara depo pe mọlẹbi yoo ni lati san owo idoola.
Lọpọ igba awọn eeyan a maa woju ijọba ati awọn ragbofinro lati doola wọn lọwọ ajinigbe sugbọn wọn kii ri iranlọwọ kankan.
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ tọkọtaya tó gbé ẹ̀yà ara ènìyàn pamọ́ sínú yàrá l'Ogun
- Wo àwòràn ohun tó ṣẹlẹ̀ ní Abeokuta lásìkò ikú Rofiat tí Soliu àti Mustaqim pa
- Àlè kun abilékọ bíi ẹran ọ̀yà láti fi ṣe òògùn owó, ọ̀rọ̀ bẹ́yìn yọ
- Ẹni tó gé orí olóri fi ṣe ògùn owó náá ṣán kú nínú àtìmọ́lé ọlọ́pàá l'Ondo
- Àlè kun abilékọ bíi ẹran ọ̀yà láti fi ṣe òògùn owó, ọ̀rọ̀ bẹ́yìn yọ
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ afurasí tó gé ojú-ara ọmọdébìnrin ọdún mẹ́fà fún ètùtù ọlà
- Adájọ́ ní kí wọ́n fi Tọkọtayà tí wọ́n ka ẹ̀yà ara mọ́ lọ́wọ́ sí ọ̀gbà ẹ̀wọ̀n ní Obafemi Owode
- "Ariwo tí Sofiat pa ló fu ará àdúgbò lára, tí ọwọ́ fi tẹ̀ wá"
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ afurasí ọkùnrin tó gé akẹ́kọ̀ọ́ ọ̀rẹ́bìnrin rẹ̀ wẹ́lẹ́ wẹ́lẹ́ fún òògùn owó ní Ikorodu
Ijinigbe ni Naijiria,ọjọ ti pẹ
Naijiria ko sẹsẹ maa koju ipenija ijinigbe ki bayi .
Lara ohun to n dẹru ba ọpọ bayi ni ki eeyan wọn ko si ọwọ ajinigbe ki wọn si nilo lati san owo idoola.
Ọkẹ aimọye eeyan lawọn ajinigbe ti gbe ti wọn a si maa beere owo idoola lọpọ igba.
Pẹlu bi nkan se ri ni Naijiria bayi, isẹ ajinigbe ti wa pawo taara bayi ti ko si yọ awọn agbegbe kankan silẹ.
Ọrọ naa ti wa n dabi ẹni pe ipa awọn agbofinro ijọba ko ka nkan to wa nilẹ yi.
- Ìjọba àpapọ̀ kéde ọjọ́ Ajé àti ọjọ́ Ìṣẹ́gun fún ìsinmi ọdún àti àyájọ́ ọjọ́ Òṣìṣẹ́
- Indonesia fòfin de títa epo pupa rẹ̀ sílẹ̀ òkèèrè, wo ipa tí yóò ní lára Naijiria àti Africa lápapọ̀
- Ìj̀à tó bẹ́ sílẹ̀ ní Sudan ti gbẹ̀mí ènìyàn 200 lára àwọn tó sá àsálà fún ẹ̀mí wọn kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ ogun Janjaweed
- Ọwọ́ tẹ ọmọ ológun Nàìjíríà tó ń lẹ̀dí àpò pọ̀ pẹ̀lú ISWAP, wo bí o ṣé gbà ẹ̀mí ará rẹ̀
- Látàri ìjà Russia àti Ukraine, Bí a ṣe fẹ́ dènà ìyàn oúnjẹ ní Naijiria rè é- Buhari
- Kìí ṣe nǹkan abàmì bí Alaafin, Soun àti Olubadan ṣe papòdà lèralèra - Elebuibon
- Iléẹjọ́ sún ìdájọ́ Ọ̀gá ọ̀lọ́pàá Abba Kyari síwájú, ìgbà wo ni wọ́n n gbée lọ jẹ́jọ́ Hushpuppi ní America ní ọ̀pọ̀ ń béèrè
- 'Ètò ayẹ́yẹ́ ìsìnkú Oba Lamidi Adeyemi kòí tíì wáyé, àfọ̀mọ́ Aàfin ń lọ lọ́wọ́'
Lati Guusu titi to fi de Ariwa Naijiria ipenija nla ni ijinigbe jẹ.
Ko si ẹni ti ko le ko sọwọ ajinigbe .Ati akẹkọọ ni kilasi tabi ni ile igbe wọn, ọmọ kekere ni ile, agbalagba, arinrinajo ati bẹẹbẹẹ lo wa ninu ewu ijinigbe.
Bi a ko ba gbagbe, laipẹ yi ni awọn ajinigbe gbe arinrnajo reluwee gbe losu Kẹrin ni Kaduna.
Eeyan mejidinlaadọsan la gbọ pe o wa ninu reluwee.
Koda, awọn ajinigbe yi tun fi aworan awọn to wa ni ahamọ wọn sita lai bikita boya awọn agbofinro yoo mu awọn.
Ileesẹ reluwee fidi ọrọ yi mulẹ ti wọn si ni eeyan mejileniọgọta lo wa ni ahamọ ajinigbe.
Titi di asiko yi,ijọba lawọn n gbiyanju lati tu awọn eeyan yi silẹ ni.
Bí o bá san owó fún ìtúsílẹ̀ ẹnikẹ́ni láhámọ́ ajínigbé, ẹ̀wọ̀n ọdún 15 wà níkàlẹ̀ fún ọ
Ileegbimọ aṣofin agba ni Naijiria ti buwọlu atunṣe abadofin igbesunmọmi ni Naijiria Terrorism (Prevention) Act, 2013 eleyi to sọ sisanwo itusilẹ fun awọn ajinigbe di ẹṣẹ si ofin lorilẹede Naijiria.
Ileegbimọ aṣofin agba fọwọsi abadofin naa lẹyin ti igbimọ kokari lori ọrọ eto idajọ, ẹtọ ọmọniyan ati ọrọ gbogbo to nii ṣe pẹlu ofin gbe e yẹwo ti wọn si gbe wa siwaju ile.
Abadofin naa, gẹgẹ bi ohun ti alaga igbimọ naa, Ọpẹyẹmi Bamidele, ṣe lalaye niwaju ile lọjọru, yoo sọ sisanwo itusilẹ fun awọn ajinigbe lati tu ẹnikẹni ti wọn ba ji gbe silẹ di ẹṣẹ si ofin lorilẹede Naijiria.
- 'Ètò ayẹ́yẹ́ ìsìnkú Oba Lamidi Adeyemi kòí tíì wáyé, àfọ̀mọ́ Aàfin ń lọ lọ́wọ́'
- Ọlọ́pàá Eko kéde orúkọ ọlọ́pàá tó ṣíná ìbọn bolẹ̀ nílé ọtí, téèyàn méjì fi kú
- Mọ̀ nípa Baṣọ̀run ìlú Oyo, Oloye Yusuf Akinade Ayoola tí yóò delé de Aláàfin tuntun
- Wọ́n ti ṣe ìsìnkú àpapọ̀ fún èèyàn 50 lára àwọn tó jóná níbúdò ìfọpo tó gbiná ní Imo
Gẹgẹ bi o ṣe sọ, pataki ofin yii ni lati dẹkun ọwọja ijinigbe eleyi to ti n fẹju tantan gẹgẹ bii owo nla lorilẹede Naijiria.
O ni gbigbe awọn ofin ti yoo koju ija si sisanwo fawọn agbesunmọmi yoo dẹkun gulegule owo ijinigbe lorilẹede Naijiria.
Ninu ọrọ rẹ, aarẹ ile aṣofin agba lorilẹede Naijiria, Ahmad Lawan ni abadofin naa yoo kun ijọba apapọ lọwọ ninu ilakaka rẹ lati gbogun ti eto abo to mẹhẹ lorilẹede Naijiria bi aarẹ Buhari ba le buwọlu abadofin naa.
Bi aarẹ Buhari ba lee buwọlu abadofin yii, yoo jẹ wi pe, ẹwọn ọdun marundinlogun ni ẹnikẹnu to ba lufin abadofin yii yoo fi gbara.
Abala ikẹrinla ofin naa sọ wi pe "Ẹnikẹni to ba fi owo ranṣẹ, tabi san owo fun ajinigbe tabi agbesunmọmi kankan lati gba itusilẹ ẹnikẹni ti wọn gbe pamọ lọna aitọ, tabi jigbe jẹbi iwa ọdaran labẹ ofin yii bi ile ẹjọ ba si da a lẹbi yoo fi ẹwọn ti ko din ni ọdun marundinlogun gbara."



















