Abba Kyari: NDLEA sàmì sí ilé Abba Kyari mẹ́fà àti ilé ìtàjà tó ní ṣọ́ọ̀bù 100 ní Maiduguri fún ìwádìí

Abba Kyari

Oríṣun àwòrán, @Abba Kyari

Iléẹjọ́ ti sún ìdájọ́ Ọ̀gá Ọlọ́pàá Abba Kyari si iwaju

Oṣù Kẹfà ni Abba Kyari yóò gba ìdájọ́ lórí ẹ̀sun gbájuẹ̀

Ijọba Ilẹ Amerika fi ẹsun kan an pe alabaṣiṣẹ Abbas Ramon, Hushpuppi ti wọn fi ẹsun alọnilọwọgba ati iwa jibiti kan ni.

Ileẹjọ giga ti sun igbejọ Abba Kyari di Ọjọ Keji, Oṣu Kẹfa, ọdun yii lori ẹsun gbajuẹ ti wọn fi kan an lati orilẹede Amẹrika.

Ileẹjọ yoo sọ boya Kyari le lọ jẹ ẹjọ ni Amerika gẹgẹ bi aṣẹ ti ẹka idajọ ni orilẹede ọhun beere lọwọ Naijiria.

Àkọlé fídíò, Basorun Akinade Ayoola Yusuf: Ìsìnkú Aláàfin Oyo àti Ooni Ile Ife yàtọ̀ nílẹ̀ Oodua

Adajọ ileẹjọ giga naa, Inyang Ekwo ni oun sun igbẹjọ naa lati fi aye silẹ fun agbẹjọro ti ijọba lati tun ile re to lọna ati mu itẹsiwaju ba igbẹjọ naa.

Kyari ti wọn ni ko lọ rọkun nile fun igba diẹ ni igbakeji kọmisọnna ọlọpaa ni Naijiria ati Ọga Agba Ọlọpaa to n risi ikọ ọtẹlẹmuyẹ.

Ẹsun wo ni wọn fi kan Abba Kyari?

Ijọba Ilẹ Amẹrika fi ẹsun kan an pe alabaṣiṣẹ Abbas Ramon, Hushpuppi ti wọn fi ẹsun alọnilọwọgba ati iwa jibiti kan ni.

Olotu ijọba ati minisita fun eto idajọ ni Naijiria, Abubakar Malami ni ijọba ilẹ Amẹrika n bere ki wọn yọnda Kyari fun wọn ni ọrọ naa ṣe de ile ẹjọ.

Amọ, agbẹjọro Kyari, Nuremi Jimoh ni wọn ko tii fi iwe ipẹjọ ranṣẹ si oun ki gbogbo eto le to.

Bakan naa ni igbẹjọ ko le e tẹsiwaju nitori awọn agbẹjọro naa ko le e fi gbogbo iwe igbẹjọ to yẹ lede, eleyii to mu u sun si iwaju di Ọjọ Keji, Oṣu Kẹfa, ọdun 2022.

NDLEA sàmì sí ilé Abba Kyari mẹ́fà àti ilé ìtàjà tó ní ṣọ́ọ̀bù 100 ní Maiduguri fún ìwádìí

NDLEA bẹ̀rẹ̀ ìwádìí lórí ilé Abba Kyari mẹ́fà àti ilé ìtàjà tó ní ṣọ́ọ̀bù 100 ní Maiduguri.

Ajọ to n gbogun ti tita ati lilo egboogi oloro ni Naijiria, NDLEA, ti sami si awọn dukia kan to jẹ ti ọga ọlọpaa tẹlẹ, Abba Kyari.

Lara awọn dukia naa ni ileegbe mẹfa, ati ile itaja nla kan niluu Maiduguri wa.

Ile itaja nla naa to jẹ alaja meji, Asurance Plaza, to wa loju ọna ileegbe Giwa Barracks, lo ni ṣọọbu bii ọgọrun un.

Yati si eyii, NDLEA tun sami si awọn ileegbe mẹfa mii to wa ni New GRA, eyi ti wọn ni o jẹ ti Kyari.

Igbesẹ yii lo n waye lẹyin ọjọ meji ti ọwọ NDLEA tẹ baba olowo ti wọn fẹsun kan pe oun lo ni oogun Tramadol ti iye rẹ to biliọnu mẹtala naira ti ikọ Kyari gbẹsẹle ṣaaju.

Àkọlé fídíò, Ijinigbe: BBC ṣe ìwádìí bí ikọ̀ IRT ṣe ń gbéjà ko awọn ajinigbe lójú

Ọjọ oṣù kejì, ọdún 2022 ni NDLEA ti nawọ́ gán Abba Kyari lẹ́yìn tí wọ́n kéde rẹ̀ bí ẹni tí wọ́n ń wá fun ẹsun pé ó lọ́wọ́ nínú gbígbé egbòogi olóró wọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láti orílẹ̀ èdè Brazil àti Singapore.

Láti ìgbà náà ni Kyari ti ń kojú ẹ̀sùn lílọ́wọ́ nínú gbígbé egbògi olóró wọ orílẹ̀ èdè yìí tó sì ti ń jẹ́jọ́ nílé ẹjọ́.

Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Abba Kyari ní òun kò jẹ̀bi gbogbo ẹ̀sùn tí wọ́n fi kan òun, ilé ẹjọ́ kọ̀ láti fún-un ní ìdáǹdè.

Kyari jẹ ogboju ọdẹ ninu igbo irunmọlẹ laarin awọn akẹgbẹ rẹ, o si ti gba oniruru ami ẹyẹ fun iṣẹ takun-takun rẹ nidi iṣẹ ọlọpaa ki aṣiri awọn ohun to ṣe ni ikọ to tu si gbangba.

Àkọlé fídíò, Adewole Quyum: Ọdún10 ni mo ti ń kọ́ 'welder' mo ti ṣe ọ̀kadà tó ń lo 'generator'