Alaafin Oyo: Wo ohun tí o kò mọ̀ nípa Morenikeji Lasisi, olórí ẹrú tó ti bá Aláàfin mẹ́ta ṣiṣẹ́

Baba Kekere

Morenikeji Lasisi olori gbogbo eru ni afin oba Oyo ti sin Oba meta.

O ti ń sìn gẹ́gẹ́ bí ẹrú láti ọdún 1945 títí di àkókò yìí

Lasisi ti sìn fún ọdún mẹ́tàdínlọ́gọ́rin.

Àkọlé fídíò, Èmi nìkan ni ikú Alaafin dùn jù ní gbogbo ayé yìí torí èmi nìkàn ṣoṣo ni mo mọ̀ ǹkan ... - Baba Kekere

Kini a mọ́ nipa Lasisi Morenikeji?

Ohun ti BBC ri kojọ nipa Lasisi ni pe baba agba yii ti lè ni ẹni ọgọ́fà ọdún bo tilè jẹ wí pé a ko tii le fidi ọjọ ori rẹ ni pato mulẹ lasiko ti a n kọ iroyin yii.

Sugbon Lasisi ni wọn n pe ni Baba Kekere laafin Oyo.

Àkọlé fídíò, Basorun Akinade Ayoola Yusuf: Ìsìnkú Aláàfin Oyo àti Ooni Ile Ife yàtọ̀ nílẹ̀ Oodua

Awọn Alaafin wo ni Lasisi ti ba ṣisẹ ni Aafin Oyo?

Baba Kekere Aafin Oyo ni ọpọ maa n pe Lasisi Morenikeji.

O ti ba Oba Adeniran Adeyemi keji ṣiṣẹ laarin ọdun 1945 si ọdun 1956

Àkọlé fídíò, Alaafin Oyo's burial: Oba Lamidi Adeymi darapọ̀ mọ́ àwọn àgbà ìṣáájú, ọ̀pọ̀ ń dárò Kábíèsí

Bakan naa ni Lasisi ba Oba Gbadegeshin Ladigbolu keji ṣiṣẹ laarin ọdun 1956 si ọdun 1968 sise.

Leyin naa lo tun jẹ olori gbogbo ẹru ni aafin ni asiko Oba Lamidi Adeyemi keta laarin ọdun 1970 si ọdun 2022.

Baba Kekere

Iru iwa wo ni Lasisi ni l'Aafin Oyo?

Lasisi Baba Kekere ni ọpọ ni aafin Oyo sapejuwe gẹgẹ bi oniwa tutu eeyan

Opọ sọ pe onirẹle ti awọn olugbe aafin maa n finu tan ni Lasisi jẹ.

Àkọlé fídíò, Cancer: Àṣe ara mi ni iso ti n run gbogbo bí mo ṣe n ṣèrànwọ́ lórí jẹjẹrẹ

Ati pe nitori pe kii ṣe ẹni to tobi tabi sanra, ọpọ kii tete mọ nipa rẹ ni eyi to mu orukọ inagijẹ Baba Kekere fun un.

Wọn ni Baba kekere kii binu nitori pe o gab pe, agba ti ko binu ni ọmọ rẹ n pọ.

Àkọlé fídíò, Sogidi Lake: Kòṣẹja-kòṣèèyàn lá bá nínú adágún odò náà -Ojedele

Wọn ni pe ko si ẹni to le sọ ọjọ ori Lasisi ni pato ṣugbọn ọpọlọ rẹ kun fun imó itan aafin ati awọn ori ade gbogbo ni Oyo.

Iwadii BBC fihan pe Lasisi ti le ni ọgọrun un ọdun.

Àkọlé fídíò, Epe Fish Market: Wá wo oríṣi ẹja tí o rírí lọ́jà ẹja tó tóbi jùlọ ní Nàíjíríà