Wahab Adegbenro: Kọmíṣọ́nnà fún ètò ìlera ní ìpínlẹ̀ Ondo jáde láyé

Ondo

Oríṣun àwòrán, Akintomi Akin

Kọmisọnna fun eto ilẹra ni ipinlẹ Ondo, Wahab Adegbenro ti wọlẹ sun ni Ọjọ Ẹti.

Adegbenrọ ni wọn sin si ile rẹ to wa ni Ilara Mokin ni ijọba ibilẹ Ifẹdore ni deede aago mẹwaa owurọ gẹgẹ bi ẹsin Musulumi ṣe laa kalẹ.

Ondo

Oríṣun àwòrán, Adetomi Akin

Ile iwosan ijọba to wa ni Owo lo ku si lẹyin to lugbadi arun Coronavirus.

Amọ awọn aworan ti a ri fihan gbangba pe ọpọ awọn eniyan to wa si ibi isinku naa ni wọn ko lo ibomu, ti wọn ko si tẹle ofin yiyagofunraẹni.

Ondo

Oríṣun àwòrán, Adetomi Akin

Ẹbi, ara ati ọrẹ pẹlu ojulumọ lo peju pese si ibi isinku naa.

Ondo

Oríṣun àwòrán, Akintomi Akin

Àlàyé rèé lórí ikú tó pa Adegbenro, Kọmísánà l'Ondo

Iroyin to n tẹ wa lọwọ ni yajoyajo ti kede pe Kọmiṣọnna feto ilera nipinlẹ Ondo, Dokita Wahab Adegbenro ti jade laye.

Gẹgẹ baa se gbọ ibudo ti wọn ti n tọju awọn alarun Coronavirus nilu Akure ni Kọmiṣọnna naa dakẹ si.

Dokita Wahab Adegbenro

Oríṣun àwòrán, Ondo TV Twitter

Adegbenro, tii se ọmọ bibi ilu Ilaramọkin nipinlẹ Ondo, ni wọn kede iku rẹ lẹyin ọjọ meji ti gomina ipinlẹ naa, Rotimi Akeredolu kede pe oun naa ti lugbadi arun Coronavirus.

Ile Wahab Adegbenro

Oríṣun àwòrán, Ondo TV Twitter

Mọlẹbi oloogbe naa, Rasheed salaye pe Kọmisana naa se isẹ abẹ fun alaisan kan lọjọ Aje nile iwosan adani rẹ to wa ni Odo Ikoyi.

Amọ sadede lo subu lulẹ, to si daku lọ rangbọndan, ki wọn to gbe digba-digba re ile iwosan.

Àkọlé fídíò, Oríṣí ìjìyà ní àwọn bíi Gómìnà El Rufai àti Fayemi ń bèèrè f'àwọn afipábánilòpọ̀

Rasheed fikun pe "Lati ọjọ Aje naa la ti ri pe ilera wọn ko ji pepe rara titi di ọsan oni to sadede de lati ọọfisi lairoti , ti wọn si gbe lọ sile iwosan FMT, nibi to dakẹ si."

Ọpọ eeyan lo ti duro go go go sile oloogbe naa lati kẹdun, ti wọn si n sọkun lori iku aitọjọ to mu Kọmisana naa lọ.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí: