Obìnrin kan dèrò ilé ìwòsàn lẹ́yìn tí ilé ẹru jálé e lórí nílu Eko

Oríṣun àwòrán, LASEMA
Obirin kan ti dero ile iwosan lẹyin ti ile ẹru ja lee lori lagbegbe Iyana Ipaja nipinlẹ Eko.
Ko pẹ ti iṣẹlẹ naa waye ti ajọ to n risi isẹlẹ pajawiri nipinlẹ naa, LASEMA, lọ si ojuko iṣẹlẹ ọhun lati doola ẹmi obirin naa.
Ile ẹru ọhun to ga to iwọn ẹsẹ bata ogoji lo ja le obinrin naa lori lati ori afara, ti obinrin ọhun si ha sabẹ ile ẹru naa.
- Wo ìdí tí Man U ṣe já Odion Ighalo sílẹ̀ nínú ìgbáradì rẹ̀ tí yóò wáyé ni Spain
- Àwọn olùfẹ̀hónúhàn "Occupy Lagos" ń fẹ́ kí ìjọba Eko dá Okada àti Maruwa padà
- 'Ẹ jọ̀ọ́, a ò fẹ́ gbọ́ òfófó ìròyìn mọ́ pé àbúrò mi gún bàbá àti ìyá mi pa, ó ti tó gẹ́!'
- 'Kìí ṣe 'ibà Lassa' ló padà wọ ìpínlẹ̀ Benue', mọ̀ nípa ààrùn tó ti pa èèyàn 15 ní Benue

Oríṣun àwòrán, LASEMA
Ọpọ awọn eeyan agbegbe ti iṣẹlẹ nmaa ti waye lo gbiyanju lati ran awọn oṣiṣẹ LASEMA lọwọ ko lee tete ri obinrin naa yọ labẹ ile ẹru ọhun.
Ọga agba ajọ LASEMA, Olufemi Damilola Oke-Osanyintolu sọ fun awọn oniroyin ninu atẹjade kan pe, awọn oṣiṣẹ ajọ naa ti doola ẹmi obirin naa.
Lẹyin naa ni wọn gbe obinrin ọhun lo si ile iwosan fun itọju.








