Kò kàn mí, mi ò ní dá sí aáwọ̀ láàrin Gómìnà Kano àti Emir Kano - Buhari

Oríṣun àwòrán, OTHER
Aarẹ orilẹede Naijiria, Muhammadu Buhari ti ni ayafi tọrọ naa ba fẹ la ẹmi lọ lo ku, loun to le da si aawọ to n waye laarin Gomina Abdullahi Ganduje ati Muhammadu Sanusi keji tii ṣe Emir ilu Kano.
Ọpọlọpọ ipe lo ti n lọ sọdọ aarẹ lati wa ọna bu omi pa'na aawọ hun. Laipẹ yii lọjọbọ ọsẹ ni Emir ilu Ningi bẹ aarẹ Buhari lati gba iṣelu ibilẹ ẹkun ariwa Naijiria kalẹ nipa pe ko tete da si ohun to n ṣẹlẹ laarin Emir ati Gomina.
O ti fi Allah bẹ Buhari tori ki iṣelu ibilẹ ma baa gba itiju lawujọ.
Si ọ̀rọ̀ yii ni oluranlọwọ pataki si aarẹ, Garba Shehu lori iroyin ati r to kan ara ilu fesi wi pe aarẹ Buhari ni"Mo m ipo mi gẹgẹ bi aarẹ".
- 'Ẹ jọ̀ọ́, a ò fẹ́ gbọ́ òfófó ìròyìn mọ́ pé àbúrò mi gún bàbá àti ìyá mi pa' ó ti tó gẹ́!
- Àdó olóró tí wọ́n fi ń pa iná àdó olóró míì ló gbiná l'Ekiti - Ọlọ́pàá Ekiti
- Tinubu kò ṣékú, kò ṣé ẹyẹ, o n dibọn ní lórí ọ̀rọ̀ ikọ̀ Amotekun - Fani Kayode
- Ohun tó ti yá kan kìí pẹ́ mọ́, fọ́ọ̀mù ìgbaniṣíṣẹ́ fún Àmọ̀tẹ́kùn dé!
- Ìsọkúsọ ni Olúbàdàn ń sọ, àwa la lè yọ́ lóyè. òun kò le è yọ́ wá - Lekan Balogun
- Iléẹjọ́ gíga Akure kọ̀ láti gba onídùróó olórí ìjọ Sotitobire
Aarẹ tẹsiwaju pe nipa ti ofin orilẹede Naijiria, Gomina ipinl Kano naa ni iṣẹ tirẹ tori pe bi ọr ba ti wa ni ile igbimọ aṣofin ipinlẹ (bi eyi to wa ni Kano lọwọlọwọ yii), aarẹ ko lagbara labẹ ofin lati da si i.
Nitori naa, aarẹ ni "nipa ofin ni mo fi wa nibi, ofin ni mo fi ṣe ibura bẹẹ si ni n o duro ti i digbi digbi.
Ẹwẹ, aarẹ fi aridaju han pe nitori alafia ati aabo ọmọ Naijiria ṣe pataki bi o ba si ri ibi ti wọn ti n tẹ ẹtọ araalu loju mọlẹ ni oun yoo lo agbara oun gẹgẹ bi ofin.
- Ẹ wo "Bíríkilà" obìnrin tó sì ń bọ́ ẹnu èèyàn mẹ́ẹ̀dógún
- Ìjọba Eko sọ pé ká má tọrọ bárà mọ́, wọ́n tún fòfin de kẹ̀ẹ̀kẹ́ tá a fi n ṣiṣẹ́ - Àwọn àkàndá ẹ̀dá
- Mí ò bẹ̀bẹ̀ fún oyè igbákejì alága APC kí wọ́n tó ó fún mi - Abiola Ajimobi
- Saheed àti Fathia Balogun dìjọ ń ṣe ọjọ́ ìbí lónìí, ẹ wo àjọṣepọ̀ tó wà láàrin wọn








