Ọlọ́pàá ti kó àwọn afurasí tí wọ́n bá òkú Demilade nínú 'cooler' nílé wọ́n ni Ekiti lọ sílé ẹjọ́

Ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ ti ko awọn afurasi to pa ọmọ ọdun meje, Demilade Fadare nilu Ado Ekiti.
Ọjọ Iṣẹgun ni iroyin jade pe wọn ba oku Demilade ninu cooler, ninu ile awọn afurasi naa ni agbegbe Adehun.
Iroyin sọ pe ọjọ Aje, ọjọ kẹfa, oṣu Kejila, ni wọn ran ọmọ naa niṣẹ, amọ ko pada sile.
Gbogbo igbiyanju wọn lati ri lo ja si ofo, ko to o di pe wọn ri oku rẹ ti wọn ti ge ẹya ara rẹ ninu nkan amounjẹ gbona, ninu ile pasitọ kan lẹgbẹ ile wọn.
Kia si ni ọlọpaa mu awọn to ni ile naa.
- Ọwọ́ ọlọ́pàá tẹ afurasí tí wọ́n fẹ̀sùn ikú Demilade, ọmọ ọdún méje tí wọ́n bá òkú rẹ̀ nínú 'cooler' lẹ́yìn tó dàwátì ní Ado-Ekiti
- Èèyàn méjì tó ṣẹ̀ṣẹ̀ gba Jesu gún pasítọ̀ ìjọ RCCG pa nínú ṣọ́ọ́ṣì l'Eko
- Ọkùnrin kan pokùn so lẹ́yìn tó pàdánù N150,000 owó iléèṣẹ́ sórí tẹ́tẹ́
- "Àwọn agbésùmọ́mí ló ń ṣe ìjọba lé wa lórí, kìí ṣe ìjọba Nàìjíríà tí Buhari ń darí"
- Ilé ẹjọ́ ti pàṣẹ tuntun fún ọ̀ga ọlọ́pàá Nàìjíríà lórí Rahmon Adedoyin tí Timothy Adegoke kú sí ilé ìtura rẹ̀
Amọ iroyin sọ pe ọmọ pasitọ naa kan to jẹ alarun ọpọlọ lo pa ọmọdebinrin naa, ṣugbọn ti awọn obi rẹ ba a tọju oku naa.
Lẹyin iṣẹlẹ naa ni awọn ara adugbo dana sun ile naa.









