Èèyàn méjì tó ṣẹ̀ṣẹ̀ gba Jesu gún pasítọ̀ ìjọ RCCG pa nínú ṣọ́ọ́ṣì l'Eko

Oríṣun àwòrán, Babatunde dada
Awọn afurasi ọmọ ita ti pa pasitọ ijọ Redeemed Christian Church of God kan to wa ni Festac Town, nijọba ibilẹ Amuwo-Odofin, nipinlẹ Eko.
Iroyin sọ pe inu ṣọọṣi RCCG Chapel of Resurrection ọhun ni wọn pa Pasitọ Babatunde Dada si, lọjọ keji, oṣu Kejila, ọdun 2021.
Gẹgẹ bi iwe iroyin The Punch ṣe sọ, awọn meji kan to ṣẹṣẹ fi aye wọn fun Jesu ninu ijọ naa lo pa a .
- Ìjọ Redeem gbé ojú òpó olólùfẹ́ kalẹ̀ sórí ayélujára fáwọn ọ̀dọ́ láti pàdé ọkọ tàbí aya
- Ìjọba ti iléẹ̀kọ́ Ojodu pa, Ó ní àlàyé ohun tó ṣókùnkùn nípa ìjàmbà tírélà tó pa akẹ̀kọ̀ọ́ níbẹ̀ ńbọ̀ láipẹ̀
- Ọkùnrin kan pokùn so lẹ́yìn tó pàdánù N150,000 owó iléèṣẹ́ sórí tẹ́tẹ́
- Fadeyi Oloro wà ní ìdúbúlẹ̀ àìsàn, ẹ jọ́wọ́ ẹ rànwá lọ́wọ́ - Foluke Daramola
- Ọmọ ogun méjì rí ẹ̀wọ̀n he lẹ́yìn tí wọ́n yìnbọn pa olùfẹ̀hónúhàn lọ́dún 2020
- Ilé ẹjọ́ ti pàṣẹ tuntun fún ọ̀ga ọlọ́pàá Nàìjíríà lórí Rahmon Adedoyin tí Timothy Adegoke kú sí ilé ìtura rẹ̀
Iroyin sọ pe ọjọ Aiku to ṣaaju ọjọ naa, ni awọn ọdọ mejeeji jade sita lasiko ti ijọsin n lọ lọwọ pe awọn fi aye awọn fun Jesu.
Koda, ọjọ ni ọjọ akọkọ ti wọn lọ si ṣọọṣi naa.
Lẹyin ti wọn jade, ti wọn fi aye wọn fun Jesu, ni awọn alaṣẹ ile ijọsin naa fun wọn ni ile gbigbe ninu ọgba ile ijọsin ọhun, nitori wọn ni awọn ko ni ibi ti awọn n gbe.
Ko si ti i to ọsẹ kan ti wọn ti n gbe inu ọgba ile ijọsin, ni iroyin sọ pe wọn gún pasitọ pa.
Aya oloogbe naa, Bose Dada sọ fun awọn akọroyin pe ọkọ oun ni oluṣiro owo ati alamojuto ni ọfiisi ile ijọsin naa, to si tun jẹ oluṣọ agutan ni ṣọọṣi RCCG miran, Chapel of Glory, to wa ni Agboju.
Ko ti i pẹ ti tọkọtaya naa ṣe igbeyawo, ti iyawo si wa ninu oyun.
Bakan naa ni mọlẹbi rẹ kan, Abolarinwa Olatunbosun sọ fun iwe iroyin Punch pe lẹyin ti Pasitọ Dada gba owo ni banki ni wọn pa a.
O ni o lọ gba owo ni banki, to si pada si ile ijọsin naa.
Nibi to ti n sinmi ni aja kinni ṣọọṣi, ni wọn sọ pe awọn meji to ṣẹṣẹ fi aye wọn fun Jesu ọhun wọle lọ ọ ba loke, ti wọn si fọ ni ori, gun ni nkan pa ki wọn o to gbe owo lọ.
Aburo oloogbe to ba BBC sọrọ, Akin Dada, ni ẹgbọn oun ni ṣọọbu kan nitosi ṣọọbu naa, nibi to tun ti n ṣe iṣẹ agbafọ aṣọ.
O ni koda o tun gba awọn ọkunrin meji ọhun sibẹ lati ma a ba ṣiṣẹ.
Bakan naa lo ni ọwọ ti tẹ ẹnikan lara awọn afurasi naa nilu Ilorin to salọ.
Ọkan lara awọn foonu oloogbe ti wọn mu, ni awọn ọlọpaa fi tọpasẹ rẹ.
Agbẹnusọ ọlọpaa nipinlẹ Eko, Adekunle Ajisebutu to fidi isẹlẹ naa mulẹ fun BBC sọ pe iwadii ti n lọ lori iṣẹlẹ naa.



















