Ọkùnrin kan pokùn so lẹ́yìn tó pàdánù N150,000 owó iléèṣẹ́ sórí tẹ́tẹ́

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ọkunrin kan ti gbẹmi ara rẹ nilu Abuja, lẹyin to padanu ẹgbẹrun lọna aadọjọ Naira sori tẹtẹ.
Iroyin sọ pe ni agbegbe Pegi, nijọba ibilẹ Kuje ni Arakunrin Adegbite ti pa ara rẹ.
- Ọmọ ogun méjì rí ẹ̀wọ̀n he lẹ́yìn tí wọ́n yìnbọn pa olùfẹ̀hónúhàn lọ́dún 2020
- Wo orílẹ́èdè tó fẹ́ fi òfin de sìgá mímú fún ìran ọmọ wọn tó ń bọ̀
- "Àwọn agbésùmọ́mí ló ń ṣe ìjọba lé wa lórí, kìí ṣe ìjọba Nàìjíríà tí Buhari ń darí"
- Ilé ẹjọ́ ti pàṣẹ tuntun fún ọ̀ga ọlọ́pàá Nàìjíríà lórí Rahmon Adedoyin tí Timothy Adegoke kú sí ilé ìtura rẹ̀
- Sunday Ìgbòho Yóò Padà Sílé Láyọ̀ àti Àlááfíà- Akeredolu
A gbọ pe ọga rẹ nibi to ti n ṣiṣẹ lo ko owo naa fun lati san fun awọn oṣiṣẹ akẹẹgbẹ rẹ, ṣugbọn o fi owo naa ta tẹtẹ nireti pe oun yoo jere rẹpẹtẹ, ko to o fi owo ṣe nkan ti wọn ran.
Amọ, o padanu gbogbo owo naa sinu tẹtẹ to ta.
Ọrẹ oloogbe to ba iwe iroyin Punch sọ pe iyalẹnu lo jẹ fun oun lati gbọ pe Adegbite pa ara rẹ.
O ni lootọ, ọga rẹ lo ko owo naa fun, amọ o fi ta tẹtẹ ni ṣọọbu kan ti wsn ti n ta tẹtẹ lori bọọlu.
"Awọn ifẹsẹwọnsẹ to ta tẹtẹ le lori ko lọ bo sẹ lero."
"Ni owurọ ọjọ keji, awọn alajọgbele rẹ ko ri ko jade. Wọn ṣakiyesi pe o wa ninu ile.
Eyi si lo mu ki wọn o ja ilẹkun rẹ, ti wọn fi ba to ti pokunso lara faanu."















