Yoruba Nation: Ẹgbẹ́ Ilana Omo Oodua gbé ìwé ìforúkọsílẹ̀ àti ìlànà àátọ̀ jáde fáwọn ajìjàgbara

Ẹgbẹ Ilana Ọmọ Oodua (IOY) to n se agbatẹru idasilẹ Yoruba Nation ti gbe atẹ kan kalẹ tawọn eeyan to ba darapọ mọ ijijagbara tabi lewaju rẹ, yoo ti maa fi orukọ silẹ.
Iwe oloju ewe mẹtadinlogoji naa, lo se akọsilẹ awọn ohun ti awọn ajijagbara ọhun gbọdọ se ati awọn eyi ti wọn ko gbọdọ se, pẹlu idi ti iwa ijijagbara naa fi n waye.
Iwe iforukọ silẹ naa ni asaaju ẹgbẹ IOY, Alagba Banji Akitoye fọwọsi, to si tun se alaye nipa awọn igbesẹ ti wọn gbọdọ gbe, ti iwọde ba n waye.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Mo kìlọ̀ fún Igboho kó má wá sí ilé mi ní Benin Republic, lẹ́yìn táwọn ọlọ́pàá ń ṣọ́ mi - Alábàṣiṣẹ́pọ̀
- Ìjọ́ mi kìí ṣe alágbé, kìí ṣe owó ló mú ká lé pásítọ̀ mọ́kànlélógójì - Oyedepo
- Wo bí ìgbẹ́jọ́ Sunday Igboho yóò ṣe lọ ní ìlú Cotonou, Benin Republic lónìí
- Benin Republic ló bẹ́gi dínà aáyan ìjọba àpapọ̀ láti kù gììrì gbé Igboho wá Naijiria - Amòfin
- Èpè Aole ló ṣì ń ja ìran Yoruba lórí ọ̀rọ̀ Sunday Igboho àti Yoruba Nation - Sokoti Alagbede
- Ọ̀rọ̀ tí Oluwo sọ ní Yidi Ileya pé ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Igboho kò kan òun, kò dára rárá - Olùwọ́de
Bakan naa ni iwe yii tun salaye idi ti ifọwọsowọpọ se gbọdọ wa laarin awọn ajijagbara fun Yoruba Nation atawọn ikọ miran to n wa ominira jakejado agbaye.
Gẹgẹ bi Kitoye ti wi, "iwe akọsilẹ yii ni yoo wulo fun awọn olootọ ọmọ Yoruba to n kopa ninu ijijagbara fun ilẹ Yoruba.
Iwe yii lo n salaye awọn iroyin ti wọn nilo lati sisẹ ijagudu wọn, to si tun n tọ wọn sọna fun ilana ti wọn yoo tọ ati ohun ti ijijagbara naa wa fun."
Ko tan sibẹ, iwe iforukọsilẹ naa, lo tun n sọ nipa idi ti wọn se n jijagbara, eyi ti wọn lo nii nnkan se pẹlu iriri buruku ti ẹya Yoruba n la kọja lorilẹede Naijiria.
- Igboho kò gbọdọ̀ padà sí Nàíjíríà, Benin Republic ẹ tú u sílẹ̀ kó lè lọ gbá ''Asylum" ní Germany- Joe Okei-Odumakin
- 'Sunday Igboho kò yojú sílé ẹjọ́ ní Cotonou, àtìmọ́lé ló ṣì wà'
- Sunday Igboho kìí ṣe ‘Terrorist’, ẹ fi sílẹ̀ ní àhámọ́ - Àwọn Olùwọ́de faraya
- "A kò sinmi lórí ọ̀rọ̀ Yoruba Nation, Sept 14 lá yọjú sí United Nation"
- Àjọ Anti Narcotic Cell ní India ti fẹ̀sùn kan Ndubuisi ọmọ Nàìjíríà kan pé ó gbé Cocaine wọ Mumbai

"A kò sinmi lórí ọ̀rọ̀ Yoruba Nation, Sept 14 lá yọjú sí United Nation"

Awọn alatilẹyin idasilẹ Yoruba Nation ti jẹjẹ pe, awọn ko ni i sinmi lori ipolongo wọn fun idasilẹ orilẹ-ede naa, ti awọn si ti ṣetan lati gbe ọrọ awọn lọ siwaju ajọ United Nations ninu oṣu Kẹsan-an.
Ẹnikan lara awọn olori ẹgbẹ Ilana Oodua, Ọjọgbọn Wale Adeniran lo sisọ loju ọrọ yii ninu ijiroro kan to waye lori ayelujara Zoom lọjọ Iṣẹgun.
O ni pe iwaju ijoko Ajọ Agbaye yoo jẹ anfaani nla lati ṣalaye nipa Yoruba Nation fun awọn olori l'agbaye.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Ooni Ife àtàwọn èèkàn Yorùbá ṣèpàdé ìdákọ́nkọ̀ lórí ọ̀rọ̀ Sunday Igboho
- Wọn yóò tẹ ẹ̀tọ́ Sunday Igboho mọ́lẹ̀ tó bá padà sí Nàìjíríà - Afenifere Renewal Group
- Ìwọ́de ńlá yóò wáyé lónìí ní London lórí ọ̀rọ̀ Sunday Igboho
- Àwọn ajìjàgbara Yoruba Nation yóò ṣe iwọ́de tako bí wọ́n ṣe mú Sunday Igboho
- "Ẹ̀yìn ọba Yorùbá, ẹ dìde láti gbe Sunday Igboho níjà kó le jàré nílẹ̀ Benin"
- "Ìdí tí ìjọba Benin Republic kò ṣe ní le è fa Igboho lé Nàíjíríà lọ́wọ́ ree"
- Ìyàtọ̀ wà láàrin èsì àyẹ̀wò ikú Jumoke àti ohun tí ọlọ́pàá sọ
Ọjọ Kẹrinla, oṣu Kẹsan-an, ọdun 2021, ni ireti wa pe ipade kẹrindinlọgọrin ajọ UN yoo bẹrẹ nilu New York, orilẹ-ede America, ti yoo si pari ni ọgbọnjọ, oṣu Kẹsan-an.
Ọjọgbọn Adeniran sọ pe "anfaani nla ni yoo jẹ fun wa lati fi ipa sọ ọrọ wa niwaju gbogbo aye.
"Fun ọsẹ kan gbako, ki gbogbo ọmọ Yoruba kaakiri agbaye yabo New York, ati ile ipade ajọ UN."
O ni oun yoo sọ fun Ọjọgbọn Banji Akintoye, to jẹ adari ẹgbẹ Ilana Oodua pe awọn ni lati darapọ mọ eto naa ni ilẹ America.
Lori lẹta ti ẹgbẹ naa kọ si ile ẹjọ ẹsun iwa ọdaran ni agbaye, International Criminal Court (ICC), Adeniran sọ pe awọn ti fi lẹta naa jiṣẹ, o si ti de ibi to yẹ ko de.
"Ṣugbọn nkan to ku fun wa lati ṣe ni pe ka tẹra mọ ariwo pipa, ki ile ẹjọ ICC le gba ọrọ wa ro, nitori pe eniyan ni awọn naa."
- Inú ìrora ni Sunday Igboho wà pẹ̀lú ṣẹ́kẹ́-ṣẹkẹ̀ ní àhámọ́ - Agbẹjọ́rò
- Sé lóòtọ́ ni wọ́n ti fi Sunday Igboho sílẹ̀ ní Cotonou?
- Sunday Igboho àti aya rẹ́, Ropo ni ọlọ́pàá Interpol mu ní Cotonou - Agbẹjọ́rò
- Kìí ṣe tuntun pẹ ìjọba Buhari tí mú Sunday Igboho, àmọ́ ọ̀nà àbáyọ sí ìtúsílẹ̀ rẹ̀ rèé - Agbẹnusọ Sunday Igboho
- Buhari, tú Sunday Igboho sílẹ̀ bo ṣe tú Boko Haram tó ronúpíwàda sílẹ̀ - Ladoja




















