Yoruba Nation: Ọ̀pọ̀ ọmọ Nàíjíríà ló ń fi ìbẹ̀rù hàn lórí ìwọ́de Yoruba Nation tí yóò wáyé ní Eko lónìí

Awọn oluwọde Yoruba Nation

Ọjọ pe, ọjọ ko ti iwọde Yoruba Nation ti ọpọ eeyan ti n fi oju sọna fun yoo waye.

Awọn ajijagbara to n pe fun idasilẹ orilẹede Yoruba Nation si lo n se agbatẹru iwọde naa, ti Oloye Sunday Igboho ati alagba banji Akintoye si n lewaju wọn.

Ọjọ Satide, ọjọ Kẹta osu keje ọdun 2021 ti wọn ti kede saaju pe iwọde naa yoo waye nilu Eko ti wa ko bayii amọ ọpọ eeyan lo ti n kaya soke pe ki ni yoo sẹlẹ loni.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Lati ọjọ ti ikede ti waye pe iwọde naa n bọ nilu Eko, ni awọn oniruuru iroyin ti ko fẹsẹ mulẹ ti n lọ lori ayelujara pe awọn eeyan kan ti n dunkoko lati kọlu awọn oluwọde naa.

Bi o tilẹ jẹ pe awọn oluwọde yii ti n lọgun tẹlẹ pe iwọde alaafia ni awọn n gbe kiri, sibẹ ileesẹ ọlọpaa nipinlẹ Eko ti sepade awọn akọroyin pe oun ko faaye gba iwọde naa lati waye.

Àkọlé fídíò, Olowo: Bí ìjọba bá ṣe àtúntò tún yẹ, Sunday Igboho yóò fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú wọn

Gẹgẹ bi Akeem Odumosu, tii se Kọmisana ọlọpaa nipinlẹ Eko se wi, ileesẹ oun ti hu gbọ pe awọn janduku kan ti n palẹmọ lati ja iwọde naa gba mọ awọn ajijagbara Yoruba Nation lọwọ.

O ni oun ko le la oju ohun silẹ, ki wọn da ilu Eko ru mọ oun lori gẹgẹ bo se waye lasiko iwọde Endsars eyi to mu ẹmi lọ, ti ọpọ dukia si tun bajẹ.

Sugbọn awọn ajijagbara naa ti wa fesi pada fun ọga ọlọpaa naa pe bo fẹ, bo kọ awọn n bọ nilu Eko lati wa se iwọde naa lọjọ Satide oni.

Ẹgbẹ Ilana Omo Oodua ti alagba Banji Akitoye ko sodi si ti fi ikede kan sọwọ sawọn akọroyin pe ẹgbẹ naa yoo tẹsiwaju pẹlu iwọde Yoruba Nation lọjọ Satide.

Bakan naa ni igun Sunday Igboho ti kede pe bi ikun lo ni oko ni, bi Pakute ni, ipade di ilu Eko lonii nibi tawọn yoo ti se iwọde.

Àkọlé fídíò, Kunle Olajide, Akọ̀wé ìgbìmọ̀: Ẹ̀yin ọ̀dọ́, ọjọ́ ọ̀la yin kò ṣe e fọ́wọ́ ẹ sọ̀yà, ẹ díde

Gẹgẹ bi agbẹnusọ fun Sunday Igboho, Olayomi Koiki ti kede loju opo Facebook rẹ, asiko iwọde naa ni gbogbo agbaye yoo mọ ẹni to ni ilu Eko.

O ni aala yoo fi oko ọlẹ han laarin awọn ọlọpaa, Gomina Sanwo-Olu ati awọn ọmọ Yoruba to n bọ wa se iwọde.

Kaakiri ilẹ Yoruba ni awọn ajijagbara naa ti n lọ kaakiri lati se ipolongo fun idasilẹ orilẹede Yoruba Nation naa.

Lara awọn ilu ti wọn ti de ni Ibadan, Abeokuta, Osogbo, Akure, Ado Ekiti, Offa, Ilorin ati bẹẹ bẹẹ lọ

Amọ ibeere ti ọpọ ọmọ Yoruba n beere ni pe se nnkan yoo fara rọ nilu Eko loni, tii awọn ajijagbara naa ba yọju fun iwọde Yoruba Nation?