Sunday Igboho Arrest: Ìbéèrè tí ọpọ ń bèèrè ni pe sé wọn ti fi Sunday Igboho sílẹẹ ni?

Sunday Igboho

Oríṣun àwòrán, Others

Ni kete ti ileesẹ iroyin BBC gbọ iroyin to n tan kaakiri ayelujara pe wọn ti fi Oloye Sunday Igboho silẹ ni ilu Cotonuo ni orillẹ-ede Benin Republic ni BBC ti kan si agbejọro Sunday Igboho.

Amofin Yomi Aliu to n soju Oloye Sunday Igboho so fun BBC Yoruba pe irọ to jina si ootọ ni iroyin itusilẹ naa.

Amofin Yomi Aliu ni pe ijọba ilẹ Benin Republic ko tii fi ajijagbara Sunday Igboho naa silẹ.

O ni gbogbo igbese to yẹ naa ni awon ti n gbe lati rii pe wọn fi ajijangbara naa sile laipẹ laijinna.

Saaju ni iroyin naa ni Omooba Adeolu Atayero Olamijulo ti dupe lọwọ awọn eeyan to gbadura fun Igboho ati awọn to satilẹyin fun un paapaa ni Cotonou.

Ko pe ti iroyin yii n tan naa ni enikan tun fi soju opo Facebook re pe iwa ipa ti awon ọtẹlẹmuyẹ DSS Naijiria hu sile Sunday Igboho ko dara to ati pe awọn agbofinro Benin Republic kọ lati fi Sunday Igboho sill fun wọn

Àwọn agbẹjọ́rò tó dáńtọ́ ti wà ní Cotonou láti gba ìdáǹdé Sunday Igboho - Akitoye

Aṣaaju ẹgbẹ ọmọ Yoruba, ọjọgbọn Banji Akintoye ti sọ pe lootọ ni wọn ti fi ṣikun ofin mu Sunday Igboho lorilẹ-ede Benin ṣugbọn iṣẹ ti bẹrẹ lati gba itusilẹ rẹ.

Akintoye and Igboho

Oríṣun àwòrán, cowrynews

Akintoye lo sọ ọrọ naa ninu atẹjade kan ti agbẹnusọ rẹ, Maxwell Adeleye buwọlu, eyii to fi ṣọwọ si awọn akọroyin.

O ni bo tilẹ jẹ pe wọn ti mu Igboho, oun atawọn ojulowo ọmọ Yoruba kan ti n sa ipa lati ri pe wọn ko faye gba ijọba Naijiria lati gbe Sunday Igboho wa si Naijiria lati Benin.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Akintoyin ke si gbogbo ọmọ Yoruba lati fọwọsowọpọ lati gba ilẹ abinibi wọn silẹ lọwọ awọn to n kogun ja wọn.

O ni "Alẹ ana ni mo gbọ iroyin pe wọn ti fi pampẹ ofin mu oloye Sunday Igboho ni papakọ ofurufu kan niluu Cotonou."

Àkọlé fídíò, Philosophy of Ori: Olatunji ní orí ẹni ló ń dúró ti ní lọ́jọ́ ìṣòro àti lójú ikú

"Lẹsẹ kan naa ni emi atawọn agbagba kan bẹrẹ iṣẹ lati ri pe wọn ko ṣe ohunkohun to lodi si ofin si, ati lati dena ijọba apapọ lati gbe wa si Naijiria."

Ọjọgbọn Akintoye sọ pe inu oun dun pe orilẹ-ede to bọwọ fun ofin ni Benin Republic jẹ, awọn si ti ke si agbẹjọro to dantọ lati bẹrẹ iṣẹ lori ọrọ naa.

O ni ohun to kan bayii ki gbogbo ọmọ ilẹ Yoruba nile ati loke okun parapọ lati ri daju pe ko si ọmọ Oduduwa kankan ti ijọba Naijiria fi iya jẹ lọna ti ko ba ofin mu.

Aṣaaju ẹgbẹ ọmọ Yoruba naa ni "Awa ọmọ Yoruba jẹ ẹya kan to ni akinkanju to si lagbara, a ni lati ji giri bayii lati ṣe ọkan akin."

Àkọlé fídíò, Olagunsoye Oyinlola: Kí Olorun dáríjì wá lórí ọ̀rọ̀ yíi, a ti kùnà ìlérí wa fún ìran Yorùb

Gẹgẹ bii ohun ti Akintoye sọ, igbesẹ akọkọ ni lati ri pe Sunday Igboho kuro ni ahamọ nitori kii ṣe ọdaran.

Akintoye sọ pe awọn eeyan kan lo n gbiyanju lati mọọmọ fi iya jẹ Igboho niroti pe o dide lati gba awọn eeyan rẹ silẹ lọwọ awọn amunisin.

Ọjọgbọn Akintoye pari ọrọ rẹ pe awọn ko ni sinmi titi ti Sunday Igboho yoo fo bọ ni ahamọ.