Sunday Igboho: Amòfin rẹ̀ ní yóò f'ojú balé ẹjọ́ lónìí lórí ìgbésẹ̀ láti gbé wá sí Naijiria

Oríṣun àwòrán, others
Agbẹjọro Sunday Igboho, Yomi Aliyu, ti sọ pe inu irora ni onibara oun wa lẹyin ti wọn fi panpẹ ofin mu lorilẹ-ede Benin republic.
O ni irora naa pọ nitori ṣẹkẹṣẹkẹ ni wọn fi de ninu ahamọ to wa niluu Cotonou.
Gẹgẹ bii ohun to sọ, wọn ko ṣe itọju onibara oun daadaa nitori awọn to wa ni ikawọ rẹ ti gba aṣẹ kan lati oke wa, ati pe yoo foju bale ẹjọ lonii yii.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- "Ìdí tí ìjọba Benin Republic kò ṣe ní lè fa Igboho lé Naijria lọ́wọ́ ree"
- Sé lóòtọ́ ni wọ́n ti fi Sunday Igboho sílẹ̀ ní Cotonou?
- Mo kìlọ tó fún àwọn ọmọ Nàìjíríà pé kí wọn má dìbò fún Buhari ní 2015 sùgbọn wọn kò gbọ- Pásítọ̀ Oyedepo
- Sunday Igboho àti aya rẹ́, Ropo ni ọlọ́pàá Interpol mu ní Cotonou - Agbẹjọ́rò
- Kìí ṣe tuntun pẹ ìjọba Buhari tí mú Sunday Igboho, àmọ́ ọ̀nà àbáyọ sí ìtúsílẹ̀ rẹ̀ rèé - Agbẹnusọ Sunday Igboho
- Buhari, tú Sunday Igboho sílẹ̀ bo ṣe tú Boko Haram tó ronúpíwàda sílẹ̀ - Ladoja
Yom Aliyu lo fi ọrọ naa lede lasiko to n fesi lori ọrọ to n ja rain ṣaaju lori ayelujara pe wọn ti gbe onibara rẹ naa wa si Naijiria lati Benin.
Nigba ti BBC Yoruba kan si Aliyu, o ṣalaye pe lootọ ni wọn ko ṣẹkẹṣẹkẹ si Igboho lọwọ.
O ni "Iroyin to tẹ mi lọwọ ni pe wọn ko ṣẹkẹṣẹkẹ si Sunday Igboho lọwọ, o si wa ninu irora ti ko ṣe fẹnusọ nitori o ti kọkọ fi ọwọ naa ṣeṣe lasiko ti wọn n gbiyanju lati mu ni papakọ ofurufu."
Aliyu ṣalaye siwaju si pe lootọ ni Igboho yoo foju bale ẹjọ lori igbesẹ lati gbe wa si Naijiria, amọ irufẹ ẹsun ti wọn ba fi kan an ni yoo sọ ibi ti ọrọ naa yoo dojukọ.
Bo tilẹ jẹ pe ko darukọ boya agọ awọn ọlọpaa ni Igboho wa, ṣugbọn o ni wọn fi to ohun leti pe ipo ti Igboho wa ko ṣe e gbọ seti nitori inu ṣẹkẹṣẹkẹ lo wa lọwọ ati lẹsẹ ni ahamọ.
Agbẹjọro naa ṣalaye pe "Wọn fi to mi leti pe aṣẹ kan lo wa lati oke wa pe ki wọn de tọwọ-tẹsẹ, inu irora nla lo si wa."
O ni o ṣeeṣe ki gbogbo igbiyanju ijọba lati gbe Igboho wa si Naijiria ja si pabo nitori ẹsun to rọ mọ ọrọ oṣelu ni wọn fi kan Igboho.
Aliyu ṣalaye siwaju si pe "Mo mọ pe wọn maa gbe oloye Sunday Igboho lọ sile ẹjọ lọjọru, nitori awọn ti wọn mu ati ijọba Najiiria yoo gbiyanju lati gba aṣẹ ile ẹjọ lati gbe wa si Naijiria,"
"Ṣugbọn o ṣeeṣe ki wọn ma ri aṣẹ naa gba niroti irufẹ ẹsun ti wọn yoo fi kan, eyii ti ko fi aye gba ijọba apapọ lati gbe wa si Naijiria."
"Gẹgẹ bi mo ṣe sọ ṣaaju ninu atẹjade kan, ọna ti wọn gba mu gan ko ba ofin mu nitori iwe idehun ti wa laarin ijọba Naijiria, Togo, Ghana ati Benin lori bi wọn yoo ṣe yanju irufẹ ọrọ yii."
Aliyu pari ọrọ rẹ pe, iwe adehun ti awọn orilẹ-de mẹrẹrin naa tọwọ bọ lọdun lọdun 1984 ko faye gba ijọba Naijiria lati gbe Sunday Ighoho wọle si Naijiria nitori irufẹ ẹṣẹ ti wọn ni o ṣẹ.


















