Adesanya UFC253: Wo ìlúmọ̀ọ́ká akànṣẹ́ mẹ́ta ọmọ Nàìjíríà tó ń ṣe bẹbẹ lágbàáyé

Oríṣun àwòrán, Instagram
Bi ọmọ ẹni ba daa, ẹ jẹ ki a wi, kii se pe a kuku fẹ fi ṣe aya ni.
Awọn ọmọ Naijiria to n ṣe bẹbẹ lagbo eṣẹ kikan lagbaaye lo bi ọrọ yii.
Mẹta ni wọn, awọn naa si ni, Anthony Joshua, Israel Adesanya ati Kamaru Usman.
Lootọọ oke okun ni awọn mẹtẹẹta fi ṣe ibugbe, amọ ko si ẹni to gbagbe orilẹede Naijiria gẹgẹ bi orirun wọn, ninu awọn mẹtẹẹta.
Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:
- Kí ló wà láàrin Olorì Badra àti Bobrisky, tí ọ̀rọ̀ wọn fi wọ̀?
- Ọ̀làjú sọ àṣà nù, wò ó báwọn obìnrin ṣe ń wà ọkọ kiri lórí ayélujára
- Wákàtí méjì àbọ̀ ní akẹ́kọ̀ọ́ yóò fi kẹ́kọ̀ọ́ lójúmọ́ - Ìjọba Oyo
- Bí pínpín owó ilù ṣe díjà sílẹ̀ láàrin àwa ìjòyè àti Oluwo rèé - Osa Iwo
- Ẹ wo àkọsílẹ̀ ọ̀pọ̀ ẹbùn tí ìkọ̀ọ̀kan olùdíje BB Naija tó kú nínú ilé, ti jẹ
- Kí ló mú kí ọkọ̀ kan tó jóná ráùráú lórí afárá Ojuelegba?
- Kíni 'Ẹ̀lẹ̀ daddy' Olorì Abbey Adeyemi ṣe tí ojú òpó ayélujára Instagram rẹ̀ fi ń yeruku lálá?
- Ìkébé mi tóbí ju ohun tí mo lè dọwọ́ bò lọ, n kìí fí ṣakọ- Nkechi Blessing
Ẹ jẹ ki a wo bẹbẹ tawọn ọmọluabi mẹtẹẹta ọmọ Naijiria yii ṣe lagbaaye:
Israel Adesanya - Igba ogun lo ti figa gbaga, ti ko si fidi rẹ́mi ninu ikankan

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Ko si ẹni to le kọ iyan Israel Adesanya kere lagbo ẹṣẹ kikan ti UFC, ti wọn tun maa n pe ni MMA.
Ilu Auckland lorilẹede New Zealand lo fi ṣe ibugbe, amọ ilu Eko ni wọn bi Israel si lọjọ kejilelogun oṣu keje ọdun 1989.
Igba ogun ni Adesanya ti fija pẹẹta pẹlu oriṣiiriṣii awọn alatako, ṣugbọn gbogbo wọn lo la lalubolẹ bi ilu bẹmbẹ.
Koda, o tun ṣẹṣẹ fakọyọ ninu ija to ja kẹyin ni, nibi to ti ṣe Paulo Costa bi ọsẹ ti n ṣe oju, ninu ija to waye niluu Abu Dhabi lorilẹede UAE laarọ lọjọ Aiku.
Ipele keje ni wọn ṣẹṣẹ de nigba ti Israel ti lu Costa, ti ori rẹ si bẹjẹ eyi to mu ki alakoso ija gbọwọ rẹ soke pe, o ti jawe olubori.
Lọwọ yii, Israel ni igbanu ''UFC Middleweight'' wa lọwọ rẹ lagbaaye.
Kamaru Usman - Ninu ija mẹtadinlogun, o fidi rẹmi ninu ẹyọ kan

Oríṣun àwòrán, Instagram/kamaru Usman
Kamaru Usman naa, tii ṣe ọmọbibi orilẹede Naijiria, jẹ akọni abẹṣẹ ku bi ojo lagbo ija MMA.
Orilẹede Amẹrika lo fi ṣe ibugbe, amọ ilu Auchi nipinlẹ Edo ni wọn ti bi Usman, lọjọ kọkanla oṣu karun un ọdun 1987.
Igba mejidinlogun ni Usman ti ja, mẹtadinlogun lo ti jawe olubori, ti o si fidi rẹmi ninu ọkan ṣoṣo ninu wọn.
Ọjọ kejila oṣu keje ọdun 2020 ni ija to kopa ninu rẹ kẹyin waye, ninu eyi to ti lu Jorge Masvidal niluu Abu Dhabi.
Usman ni igbanu ''UFC Welterweight'' wa lọwọ rẹ bayii.
Anthony Joshua - Igbanu mẹta lẹka ẹṣẹ kikan to lami laaka lo wa lo lọwọ rẹ nikan

Oríṣun àwòrán, Instagram/anthonyjoshua
Ti a ba n sọrọ awọn afi ẹṣẹ ku bi ojo lagbaaye, ọrọ ko tii tan ti a ko ba darukọ Anthony Oluwafemi Joshua.
Niluu Watford lorilẹede England, ni wọn ti bi Joshua lọjọ kẹẹdogun oṣu kẹwaa ọdun 1989, amọ bi iṣu lo maa jẹ orilẹede Naijiria lẹnu.
Koda, o ti figba kan gbe ilu Eko ri nigba to n dagba.
Joshua ti gba oriṣiiriṣii ami ẹyẹ ninu ẹṣẹ kikan lagbaaye, to fi mọ ami ẹyẹ wura ninu idije ''Olympics'' ọdun 2012.
Joshua ti fẹṣẹ yanju awọn ilumọọka akanṣẹ bi Wladimir Klitschko, Charles Martin, Joseph Parker, Alexander Povetkin ati Andy Ruiz Jr.
Igbanu mẹta lẹka ẹṣẹ kikan to lami laaka lo wa lo lọwọ AJ nikan.
Oun ni igbanu IBF, IBO, WBA ati WBO ''heavyweight'' wa lọwọ rẹ bayii.
Káre akọni ọmọ Yoruba! Israel Adesanya fi ẹ̀ṣẹ́ fọ́ Paulo Costa lójú
'Misita Alagidi, emi leleyi!' ni gbolohun ti Israel Adesanya fi da awọn alatako rẹ lohun lẹyin to da bantẹ iya fun Paulo Costa ninu ija wọn to waye ni Dubai.
Isọri keji ija naa ni Adesanyta ti rọjo ẹsẹ lu Costa ti adari ija naa si bọ si aarin wọn lati pari rẹ ni kiakia.
Ni bayi, Adesanya ṣi ni o jẹ olubori Middle Weight Champion of the World.
Loju opo Twitter awọn ọmọ Naijiria to fi mọ Minisita feto ọdọ ati idaraya Sunday Dare ti n ki ku orire ija naa
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 1
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 2
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 3

Oríṣun àwòrán, Getty Images
Mo ṣetán láti ṣe Paulo Costa bí ọṣẹ sẹ ń ṣojú lọ́la- Israel Adesanya
Ọjọ nii pẹ, ipade kii jian. Ọjọ Aiku tii ṣe ọjọ kẹtadinlọgbọn oṣu kẹsan an ọdun 2020 ni ajijakandi ọmọbibi orilẹede Naijiria to jẹ aṣaaju ninu ija UFC, Israel Adesanya to yoo koju Paulo Costa ọmọ ilẹ Brazil.
Faabada! Ẹyin ologinni ko gbọdọ balẹ. Adesanya ko ti fidi rẹmi ri lati igba to ti di agbaọjẹ lagbo UFC.
Ija MMA mọkandinlogun ni Adesanya ti kopa ninu rẹ ti o si jawe olubori ninu gbogbo wọn, nigba ti alako rẹ, Costa ko tii fidi rẹmi ninu ija MMA mẹtala to ti ja.
- Israel Adesanya ti fi ẹ̀ṣẹ́ yanjú Romero
- Àwọn tó fẹ́ kí ọba máa ta ilẹ̀ ilú ló fẹ́ yọ Oluwo lóyè- Ẹgbẹ̀ Baálẹ̀ Iwo.
- Nǹkan yan, àwọn aṣẹ́wó fẹ́ daṣẹ́ sílẹ̀ nítorí ẹ̀kúnwó epo ní Nàìjíríà
- Ìbúgbàmù gbogbo ìgbà nílù ú Èkó, kí ló ń ṣokùnfà rẹ̀?
- Ẹ wá ná, kí ló ń ṣẹlẹ̀ pẹ̀lú APC àti Kayode Fayemi ní Ekiti gan an?
Ilu Abu Dhabi, United Arab Emirates lawọn mejeeji yoo ti waako lọjọ Aiku.
Nigba ti wọn n tahun si ara ṣaaju ija ọjọ Aiku, Costa oun yoo gbe Israel tọrọ ba doju rẹ tan nitori ko lara.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 4
Amọ ile lo kuku ba Adesanya naa, oun naa sọ pe oorun ti ko si Costa loju ohun lo si n ṣakoba fun un.
Adesanya ni ti oun ba le ki Costa lọrun mọlẹ pẹrẹ, o ni ọrun naa ko tun jẹ tirẹ mọ.
This article contains content provided by X. We ask for your permission before anything is loaded, as they may be using cookies and other technologies. You may want to read X cookie policy and privacy policy before accepting. To view this content choose 'accept and continue'.
End of X post, 5
Israel sọ pe o ṣe oun bi ki ija naa ti bẹrẹ nitori oun ko le duro mọ lati da ẹṣẹ bo Costa lori.
Igba mẹrinla ni Adesanya ti lu alatako rẹ lalubami ti wọn maa n pe ni TKO ninu ija mọkandinlogun to ti ja.
- Kò sí iléẹjọ́ tó le dá wa dúró, ìyanṣẹ́lódì yóò bẹ̀rẹ̀ ní Ọjọ́ Ajé - NLC
- Wo iye ìgbà tí ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́ àtàwọn ọmọ Nàìjíríà ti ṣèwọ́de lórí àfikún owó epo bẹntírò
- Èkúté tó sàwárí bọ́mbù ilẹ̀ gbàmi ẹ̀ye wúrà fún iṣẹ́ takuntakun
- Ẹ gbọ́ òhun tí àwọn olùdíjé sípò gómìnà nípínlẹ̀ Ondo sọ nípa Bàbá ìsàlẹ̀...
- Nǹkan yan, àwọn aṣẹ́wó fẹ́ daṣẹ́ sílẹ̀ nítorí ẹ̀kúnwó epo ní Nàìjíríà















