Fuel price hike: Wo iye ìgbà tí ẹgbẹ́ òṣìṣẹ́ àtàwọn ọmọ Nàìjíríà ti ṣèwọ́de lórí àfikún owó epo bẹntírò

Oríṣun àwòrán, Twitter/@ayemojubar
Ẹgbẹ apapọ awọn oṣiṣẹ ni Naijiria, Nigeria Labour Congress(NLC) ti kede pe ohun yoo gunle iwọde lọjọ Aje ọjọ kejidinlọgbọn, oṣu kẹsan an lati fi ẹhonu han lori afikun owo epo bẹntiro ati ina ọba.
Igbimọ alaṣẹ NLC buwọlu igbesẹ igbimọ amuṣẹya ẹgbẹ naa lati bẹrẹ iwọde kaakiri orilẹede Naijiria lọjọ Aje to n bọ.
Lẹyin ti ijọba apapọ yọ owo iranwọ ori epo tan lo ṣe afiukun owo epo bẹntiro lati N145 si N161 to wa bayii.
- Ọ̀wọ́ngógó oúnjẹ, epò, iná ọ̀ba ti sọ owó oṣù N30,000 da N9 nitórí náà kò ní sí ọjà, epo, iléèwòsàn láti Ọjọ́ Ajé - NLC
- Ẹ yé parọ́ kiri! Orílẹ̀èdè Amẹrika kò ṣọ́ wọlé-wọ̀de mi àti ìdílé mi- Atiku fèsì
- Iléẹjọ́ ní kí Yakubu lọ gé oko àgọ́ ọlọ́pàá fọ́jọ́ méjì lẹ́yìn tó jí fóònù N8,700
- Ìdùnnú subú layọ̀ nípìnlẹ̀ Ọyọ́, àwọn tó dé láti Lebanon sọ ọmọ wọn ní Seyi
- Akọ̀wé-owó wọ gàù ní iléẹjọ́ lórí ẹ̀sùn pé ó jí N500,000 lọ́wọ́ ọ̀gá rẹ̀
- Ọ̀rọ̀ Soyinka àti Obasanjo papọ̀ lórí pé Buhari n ṣe ìpínyà Nàìjíríà
Bakan naa ni ijọba kede afikun owo ina ọba lọna ilọpo meji eyi ti o mu ki ọpọ araalu ṣi maa ke pe inira nla lo jẹ fawọn.
Wọnyii ni iye igba ti ẹgbẹ oṣiṣẹ atawọn ọmọ Naijiria ti fẹhonuhan lori afikun owo epo bẹntiro lati ọdun 2003 ti Naijiria ti pada si ijọba awarawa.
Ifẹhonuhan lori afikun owo epo ọdun 2003
Ẹgbẹ apapọ oṣiṣẹ, NLC labẹ olori rẹ nigba naa, Adam Osiomole gunle iyanṣẹlodi pẹlu iwọde lẹyin ti ijọba aarẹ Naijiria tẹlẹ ri, Olusegun Obasanjo ṣe afikun owo epo bẹntiro lati N26 naira lọ si N40.
Ijọba Obasanjo ṣalaye pe afikun owo epo waye nitori ijọba ṣe adinku owo iranwọ to wa lori ero.
Ijọba sọ pe ohun yoo na owo to ba jade lati ibẹ sori ẹka eto ẹkọ ati ilera.
Awọn oṣiṣẹ bẹrẹ iyanṣẹlodi pẹlu iwọde kaakiri orilẹede Naijiria.
Lọjọ kẹjọ oṣu keje ọdun 2003 lẹgbẹ NLC kede pe ohun wọgile le iyanṣẹlodi to gunle lẹyin to faramọ igbesẹ ijọba lati gbe owo epo si N34 lati N40.

Oríṣun àwòrán, Twitter/@ayemojubar
Ifẹhonuhan lori afikun owo epo ọdun 2004
Iyansẹlodi ati ifẹhonu han tun bẹrẹ lọdun 2004 lẹyin ti ijọba Obasanjo tun ṣe afikun owo epo bẹntiro lati N40 si N45.
Awọn ileewe, banki, ọfiisi ati ọpọlọpọ okoowo lo di titi pa lẹyin ti ẹgbẹ oṣiṣẹ NLC bẹrẹ iyaṣẹlodi kaakiri Naijiria.
Niluu Eko fun apẹẹrẹ, awọn olufẹhonukan bọ si oju titi ṣugbọn awọn ọlọpaa yin tajutaju soke lati tu wọn ka.
Awọn olori ẹgbẹ oṣiṣẹ sẹ ipade pẹlu ijọba Obasanjo, ṣugbọn ijọba fi aake kọri pe igbesẹ ohun ṣe pataki lati mu atunṣe ba ẹka eto ifọpo ni Naijiria.
- Tí ìjọba bá gbé òfin kónílé-ó-gbélé ọlọ́jọ́ pípẹ́ míì kalẹ̀ nítori Covid-19, ǹkan yóò bàjẹ́ ní Naijiria- Dokita
- OPC láwọn mú afurasí agbébọn ajínigbé mẹ́rin l'Oyo, ọlọ́pàá ní àpapọ̀ òṣìṣẹ́ elétò aàbò ló ṣiṣẹ́ náa
- INEC fún Obaseki ní ìwé-ẹ̀rí moyege gẹ́gẹ́ bí gómìnà tí wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ dìbò yàn
- Wo bí ìwọ náà ṣe lè rí gbà nínú owó ìrànwọ́ tí ìjọba Nàìjíríà fẹ́ pín
- WASSCE: Ìpínlẹ̀ Delta fòfin de olùkọ́ 41 tó ṣe màgòmágó nínú ìdánwò
Ifẹhonuhan lori afikun owo epo ọdun 2007
Ijọba Obasanjọ tun ṣe afikun owo epo bẹntiro lati N45 lọ si N70.
Eyi lo fa iyanṣẹlodi pẹlu iwọde kaakiri orilẹede Naijiria lọdun 2007.

Oríṣun àwòrán, Twitter/Omoyele Sowore
Gbogbo ileeṣẹ nla nla lo kogba sile, awọn oṣiṣẹ banki atawọn oṣiṣẹ ijọba ko lọ di ibi iṣẹ.
Lawọn agbegbe kan, awọn ọdọ n gba bọọlu loju titi lẹyin toju popo da paro paro.
Ijọba dunkoko mawọn ẹgbẹ oṣisẹ pe iyanṣẹlodi tawọn ẹgbẹ oṣiṣẹ gunle lodi si ofin, amọ wọn ni awọn ko ni wọgile iyanṣẹlodi ọhun ayafi ti ijọba ba mu afikun owo epo naa kuro.
Ijọba aarẹ ana to ti di oloogbe, Umar Yar'Adua lo pada ṣe adinku owo epo naa, to si gbe lọ si N65.
Ifẹhonuhan lori afikun owo epo ọdun 2012
Ọjọ kinni oṣu kinni ọdun 2012 ni ijọba Good luck Jonathan kede pe ohun ti mu owo iranwọ ori epo(subsidy) kuro.
Eyi lo mu ki ijọba gbe owo epo bẹntiro lọ si N141 lati N65, lẹyin naa lawọn eeyan bẹ sita ti wọn si bẹrẹ ifẹhonuhan kaakiri orilẹede Naijiria.

Oríṣun àwòrán, Twitter/@Ayemojubar
Ọjọta lawọn olufẹhonuhan fi ipade si niluu Eko, oniruuru awọn ajafẹtọ lo pade nibẹ nibi ti wọn ti n kọrin a ko nii gba si ijọba Jonathan leti.
Awọn sọja ni ijọba da sita lati le awọn olufẹhonuhan kuro loju titi kaakiri Naijiria.
O kere tan. akọsilẹ fihan pe eeyan mẹẹdogun lo ba iwọde naa lọ lọdun 2012.
- Wọ́n ti yìnbọn pa ọkùnrin ẹni ọgbọ̀n ọdún tó ń jà sí ogún ilẹ̀ bàbá rẹ̀
- Ẹgbẹ́ NULGE Oyo dìbò yan olóyè ẹgbẹ́ tuntun èyí tó tako àṣẹ iléẹjọ́
- Ilé iṣẹ́ ọmọogun òfurufú sọ orúkọTolulope Arotiba di málegbàgbé lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà
- Ìdùnnú subú layọ̀ nípìnlẹ̀ Ọyọ́, àwọn tó dé láti Lebanon sọ ọmọ wọn ní Seyi
- Wo ọ̀nà tí o fi lè dáàbò bo ọmọ rẹ lọ́wọ́ COVID-19 níléèwé
- Ẹ yé parọ́ kiri! Orílẹ̀-èdè Amẹrika kò ṣọ́ wọlé-wọ̀de mi àti ìdílé mi- Atiku fèsì
















