OPC láwọn mú afurasí agbébọn ajínigbé mẹ́rin l'Oyo, ọlọ́pàá ní àpapọ̀ òṣìṣẹ́ elétò aàbò ló ṣiṣẹ́ náa

Gani Adams

Oríṣun àwòrán, Gani Adams/facebook

Ẹgbẹ Oodua People's Congress, OPC ti kede pe awọn ti mu awọn agbebọn afurasi ajinigbe mẹrin lapa Oke Ogun nipinlẹ Oyo.

Oluṣakoso ẹgbẹ OPC nipinlẹ Oyo, Ọgbẹni Rotimi Olumo to fidi ọrọ yii mulẹ ṣalaye pe ibọn AK-47 mẹrin lawọn gba lọwọ awọn afurasi ọhun.

Ọgbẹni Olumo sọ pe awọn ti fi awọn afurasi ọhun le ileeṣẹ ọlọpaa ẹkun Igbeti lọwọ.

Ṣugbọn alukoro ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Oyo, Olugbenga Fadeyi ṣalaye fun BBC Yoruba pe apapọ awọn oṣiṣẹ eleto aabo pẹlu awọn fijilante lo jọ ṣiṣẹ pọ mu awọn afurasi mẹrin naa.

Nigba ti BBC Yoruba beere boya awọn ọmọ ẹgbẹ OPC wa ninu awọn to mu awọn agbebọn naa, alukoro ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Oyo ko le fidi rẹ mulẹ.

Àkọlé fídíò, Akomolede àti Aṣa: Ọ̀rọ̀ Ẹ̀yán ni Bunmi Femi Amao ń kọ́ wa lórí ètò Akọ́mọlédè àti Àṣà lóri BBC Yoruba

''Ni nkan bii aago meje alẹ ogunjọ oṣu kẹsan an ọdun 2020 yii ni apapọ awọn oṣiṣẹ eleto aabo pẹlu awọn fijilante mu awọn afurasi mẹrin ọhun ninu igbo Igbeti lagbegbe Kisi,'' alukoro ọlọpaa lo sọ bẹẹ.

O ni mẹta lọwọ ba ninu wọn nigba ti awọn to ku sa lọ pẹlu ọgbẹ ibọn lara wọn.

Agbẹnusọ ileeṣẹ ọlọpaa ni awọn agbofinro ti fọn sinu igbo naa lati wa awọn yoku to sa lọ atawọn mii to ba tun wa ninu igbo naa.