Mali transitional leaders: Bah Ndaw àti Assimi Goita ni wọ́n ní kó máa wa ọkọ̀ orílẹ̀-èdè Mali báyìí

Oríṣun àwòrán, @Lima
Minista to wa fun eto aabo lorilẹ-ede Mali tẹlẹ, Bah Ndaw ni wọn ti yan lati wa ọkọ orilẹ-ede naa fun ọdun kan ati aabọ gẹgẹ bi aarẹ to maa da eto iṣejọba pada sipo nibẹ.
Lọjọ Aje ni wọn fẹnuko pe ki oun ati Assimi Goita wa ọkọ orilẹ-ede naa de ibi oge nipa eto iṣelu.
Ogagunfẹyinti ni N'Daw jẹ ko to gba ipo yii ni Mali.
- Àwọn ọmọ orílẹ̀èdè Mali ń fò fáyọ̀ pé ológun gba ìjọba mọ́ alágbádá lọ́wọ́
- Àwọn orílẹ̀-èdè tí ààrẹ Buhari ti lọ láàrin ọdún márun
- Ìkọlù agbébọn tó ṣékú pá ọmọ ogún Niger 89, iṣẹ́ bọ lọ́wọ́ Ọgágun àgbà
- Ọmọ ogun ilẹ̀ mẹ́tàléláàdọ́ta ni wọ́n ti pa nínú ìkọlù Mali
- Bàbá ọmọ tí Mammadou Gassama dóòlà ẹ̀mí rẹ̀ lọ ẹ́wọ̀n
- Ọwọ́ tẹ arúfin ogun Timbuktu
- Ẹgbẹ́ alákatakítí ẹ̀sìn Al-Qaeda fẹ́ da ìbò Mali rú
Assimi Goita naa jẹ ọgagun, oun naa lo wa nidi bi awọn ologun ṣe gba ijọba loṣu to kọja ni Mali.
Assimi ni wọn ni ko jẹ igba keji Ogagunfeyinti Bah N'Daw bayii.
Awọn mejeeji ni amuyẹ lati tukọ orilẹ-ede Mali ni asiko yii.
Diẹ lara amuyẹ naa ni pe adari asiko yii gbọdọ wa lati Mali, ko jẹ ẹni ọdun marundinlogoji si aadọrin ọdun, to maa ni iwa ọmọluwabi ti kii si fi ẹtna ṣe lawujọ.
Koda, amuyẹ miran ni pe ẹni naa ko gbọdọ ni ẹjọ iwa ọdaran nile ẹjọ.
- Ọ̀wọ́ngógó búrẹ́dì gbòde kàn lẹ́yìn tí àwọn oníbúrẹ́dì da iṣẹ́ sílẹ̀
- Èèyàn mẹ́jọ jónà ráúráú nínú ìjàmbá ọkọ̀ akérò tó ṣẹlẹ̀ ní mọ́rosẹ̀ Eko sí Ibadan
- Ọlọ́jọ́ Festival 2020:Ọ̀ọ̀ni ti Ilé Ifẹ̀ tí wọ ìléèdí ọlọjọ méje tí kò ní rí ẹnikẹ́ni sójú
- Ìjọba Kaduna kéde ọjọ́ mẹ́ta fún ìdárò Emir Zazzau, Buhari, Tinubu, Babangida náà ń ṣèdárò
- Wo àwọn báńkì tó wà lẹ́yìn àwọn olówó èlé bí MMM
Awọn amuyẹ yii naa ni ofin to de awọn minista ati awọn to ku ti wón maa yan sipo lati jọ ṣiṣẹ papọ.
Lasiko ipade ajọ ile Afirika, ECOWAS ni wọn ti fun awọn ọmọ ogun to gbajọba ni orilẹ-ede Mali ni gbendeke ọjọ kẹẹdogun, oṣu késan an yii lati gbe ijọba silẹ fawọn alagbada.
















