Osun Kidnap rescue: Àwọn ọlọ́pàá dóòlà ẹ̀mí arìnrìnàjò méje tí wọ́n jígbé ní Ibokun

Ọlọpa ilẹ Naijiria

Oríṣun àwòrán, AFP

Àkọlé àwòrán, Ìgbà àkọ́kọ́ kọ́ nìyí tí irú ìṣẹ̀lẹ̀ bẹ̀ yòó wáyé

Ileeṣẹ ọlọpaa nipinlẹ Osun ti kede pe awọn ti ribi doola arinrinajo meje lọwọ awọn ajinigbe.

Alukoro ileeṣẹ naa Yemisi Opalola lo lede ọrọ fun ileeṣẹ BBC ninu atẹjade kan lọjọ Abamẹta.

O ni awọn doola ẹmi awọn arinrinajo naa nipa ajọsepọ pẹlu awọn ẹsọ alaabo mii.

Yemisi ṣalaye pe loju ọna Ibokun / Osogbo lawọn ajinigbe wọn yi ti jin awọn arinrinajo naa gbe lọjọ Iṣẹgun.

Lasiko ikọlu yi, a gbọ pe eeyan kan ku ti awọn meji si farapa lasiko ti awọn ajinigbe yi ṣe ikọlu si wọn labule Ajebandele ni ijọba ibilẹ Ibokun.

Àkọlé fídíò, Oba Sunday Oyediran ṣàlàyé kíkún nípa ìṣẹ̀ṣe, ìgbàgbọ́ àti ẹ̀sìn tí kò dí ará wọn lọ́wọ́

Agbofinro Yemisi ko sọ boya awọn ri awọn ajinigbe ọhun mu ṣugbọn o ni niṣe ni wọn tu awọn arinrinajo naa silẹ nigba ti awọn fungun mọ wọn.

O tẹsiwaju pe awọn ti wọn doola ko ni pẹ darapọ mọ mọlẹbi wọn.