Oyo Tribunal: Ọjọ́ Ajé ní ìgbìmọ̀ olùgbẹ̀jọ́ ìbò gómìnà yóò gbé ìdájọ́ kalẹ̀

Seyi Makinde ati Adebayo Adelabu

Ta ba da ọjọ, ọjọ a pe, ta ba da igba, igba yoo ko, ọla ọjọ Aje ni ọjọ pe ti igbimọ olugbẹjọ ẹsun ibo gomina nipinlẹ Ọyọ yoo gbe idajọ rẹ kalẹ.

Idajọ naa si ni yoo kede ẹni to jawe olubori ninu ibo gomina laarin Gomina Seyi Makinde ti ẹgbẹ oselu PDP ati alatako rẹ latinu ẹgbẹ oselu APC, Adebayo Adelabu.

Bẹẹ ba gbagbe, oludije fun ẹgbẹ oselu APC naa lo morile iwaju igbimọ olugbẹjọ to n gbọ awuyewuye ibo lati tako esi ibo to gbe alatako rẹ latinu ẹgbẹ oselu PDP wọle.

Àwọn iròyin tì ẹ leè ní ìfẹ̀ síí:

Ajọ eleto idibo nipinlẹ Ọyọ, lo ti kede saaju lẹyin ibo gomina naa to waye lojọ Kẹsan osu Kẹta ọdun yii pe, Onimọẹrọ Seyi Makinde lo moke ninu ibo naa pẹlu ibo to le diẹ ni ẹgbẹrun lọna ẹẹdẹgbẹta (515,621) nigbati Adebayọ Adelabu si se ipo keji pẹlu ibo to le diẹ ni ẹgbẹrun lọna ọọdunrun ati aabọ (357,982).

Bakan naa ni ajọ Inec ni Makinde yege ibo ni ijọba ibilẹ mejidinlọgbọn ninu mẹtalelọgbọn to wa nipinlẹ naa, ti Adelabu si moke ni ijọba ibilẹ mọkanla pere.

Ile ẹjọ

Nibayii to ku wakati mẹrinlelogun ki idajọ naa waye, gbogbo eeyan lo n foju sọna lati mọ igun ti igi ọrọ naa yoo wo si, ti gbogbo eto si ti to niwaju igbimọ naa, ti Adajọ Suraju Muhammadu ko sodi lati gbe idajọ rẹ kalẹ.

Ibeere to si n tawọ tasẹ ninu awọn eeyan ni pe ta ni yoo moke ninu idajọ ọla yii?

Bi idajọ naa ba si se n waye, naa ni BBC Yoruba yoo maa mu iroyin naa wa fun yin lọla, ẹ ku oju lọna.